ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Léfítíkù 9:23, 24
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 23 Níkẹyìn, Mósè àti Áárónì lọ sínú àgọ́ ìpàdé, wọ́n jáde wá, wọ́n sì súre fún àwọn èèyàn náà.+

      Jèhófà wá fi ògo rẹ̀ han gbogbo àwọn èèyàn náà,+ 24 iná sì bọ́ láti ọ̀dọ̀ Jèhófà,+ ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í jó ẹbọ sísun àti àwọn ọ̀rá tó wà lórí pẹpẹ. Nígbà tí gbogbo àwọn èèyàn náà rí i, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í kígbe, wọ́n sì dojú bolẹ̀.+

  • Diutarónómì 4:24
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 24 Torí iná tó ń jóni run ni Jèhófà Ọlọ́run yín,+ Ọlọ́run tó fẹ́ kí ẹ máa jọ́sìn òun nìkan ṣoṣo.+

  • Àwọn Onídàájọ́ 6:21
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 21 Áńgẹ́lì Jèhófà wá na orí ọ̀pá ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi kan ẹran àti búrẹ́dì aláìwú náà, iná sọ níbi àpáta náà, ó sì jó ẹran àti búrẹ́dì aláìwú+ náà run. Ni áńgẹ́lì Jèhófà bá pòórá mọ́ ọn lójú.

  • 1 Kíróníkà 21:26
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 26 Dáfídì mọ pẹpẹ kan+ síbẹ̀ fún Jèhófà, ó sì rú àwọn ẹbọ sísun àti àwọn ẹbọ ìrẹ́pọ̀, ó ké pe Jèhófà, ẹni tó wá fi iná dá a lóhùn+ láti ọ̀run sórí pẹpẹ ẹbọ sísun náà.

  • 2 Kíróníkà 7:1
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 7 Gbàrà tí Sólómọ́nì parí àdúrà rẹ̀,+ iná bọ́ láti ọ̀run,+ ó jó ẹbọ sísun àti àwọn ẹbọ náà, ògo Jèhófà sì kún ilé náà.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́