“Mo dá ọ lóhùn ní àkókò ojúure,+
Mo sì ràn ọ́ lọ́wọ́ ní ọjọ́ ìgbàlà;+
Mò ń ṣọ́ ọ kí n lè fi ọ́ ṣe májẹ̀mú fún àwọn èèyàn náà,+
Láti tún ilẹ̀ náà ṣe,
Láti mú kí wọ́n gba àwọn ohun ìní wọn tó ti di ahoro,+
-
Àìsáyà 51:3
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
3 Torí Jèhófà máa tu Síónì nínú.+
Ó máa tu gbogbo àwókù rẹ̀ nínú,+
Ó máa mú kí aginjù rẹ̀ rí bí Édẹ́nì,+
Ó sì máa mú kí aṣálẹ̀ rẹ̀ tó tẹ́jú rí bí ọgbà Jèhófà.+
Ìdùnnú àti ayọ̀ máa wà níbẹ̀,
Ìdúpẹ́ àti orin tó dùn.+