26 Àwọn èèyàn á sì wá láti àwọn ìlú Júdà àti láti àyíká Jerúsálẹ́mù àti láti ilẹ̀ Bẹ́ńjámínì+ àti láti pẹ̀tẹ́lẹ̀ + àti láti àwọn agbègbè olókè àti láti Négébù.* Wọ́n á máa mú odindi ẹbọ sísun + àti ẹbọ+ àti ọrẹ ọkà+ àti oje igi tùràrí wá, wọ́n á sì máa mú ẹbọ ìdúpẹ́ wá sínú ilé Jèhófà.+
13 “‘Ní àwọn ìlú tó wà ní agbègbè olókè àti ní àwọn ìlú tó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, ní àwọn ìlú tó wà ní gúúsù àti ní ilẹ̀ Bẹ́ńjámínì, ní agbègbè Jerúsálẹ́mù+ àti ní àwọn ìlú Júdà,+ agbo ẹran yóò tún pa dà kọjá lábẹ́ ọwọ́ ẹni tó ń kà wọ́n,’ ni Jèhófà wí.”