ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Sámúẹ́lì 7:16, 17
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 16 Ilé rẹ àti ìjọba rẹ máa fẹsẹ̀ múlẹ̀ títí láé níwájú rẹ; ìtẹ́ rẹ á sì fìdí múlẹ̀ títí láé.”’”+

      17 Nátánì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ yìí àti gbogbo ìran tó rí+ fún Dáfídì.

  • 1 Àwọn Ọba 2:4
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 4 Jèhófà á sì mú ìlérí tó ṣe nípa mi ṣẹ, pé: ‘Bí àwọn ọmọ rẹ bá fiyè sí ọ̀nà wọn, láti fi òtítọ́ rìn níwájú mi pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn àti gbogbo ara* wọn,+ kò ní ṣàìsí ọkùnrin kan láti ìlà ìdílé rẹ* tí yóò máa jókòó sórí ìtẹ́ Ísírẹ́lì.’+

  • Sáàmù 89:20
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 20 Mo ti rí Dáfídì ìránṣẹ́ mi;+

      Mo ti fi òróró mímọ́ mi yàn án.+

  • Sáàmù 89:29
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 29 Màá fìdí àwọn ọmọ* rẹ̀ múlẹ̀ títí láé,

      Màá sì mú kí ìtẹ́ rẹ̀ wà títí lọ bí ọ̀run.+

  • Àìsáyà 9:7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  7 Àkóso* rẹ̀ á máa gbilẹ̀ títí lọ,

      Àlàáfíà kò sì ní lópin,+

      Lórí ìtẹ́ Dáfídì+ àti lórí ìjọba rẹ̀,

      Kó lè fìdí rẹ̀ múlẹ̀ gbọn-in,+ kó sì gbé e ró,

      Nípasẹ̀ ìdájọ́+ tí ó tọ́ àti òdodo,+

      Láti ìsinsìnyí lọ àti títí láé.

      Ìtara Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun máa ṣe èyí.

  • Lúùkù 1:32, 33
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 32 Ẹni yìí máa jẹ́ ẹni ńlá,+ wọ́n á máa pè é ní Ọmọ Ẹni Gíga Jù Lọ,+ Jèhófà* Ọlọ́run sì máa fún un ní ìtẹ́ Dáfídì bàbá rẹ̀,+ 33 ó máa jẹ Ọba lórí ilé Jékọ́bù títí láé, Ìjọba rẹ̀ ò sì ní lópin.”+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́