- 
	                        
            
            Jeremáyà 49:19-21Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
- 
                            - 
                                        19 “Wò ó! Ẹnì kan máa wá gbéjà ko àwọn ibi ìjẹko Édómù tó wà ní ààbò bíi kìnnìún+ tó jáde látinú igbó kìjikìji lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jọ́dánì, ṣùgbọ́n ní ìṣẹ́jú kan, màá mú kí ó sá kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀. Màá sì yan àyànfẹ́ lé e lórí. Nítorí ta ló dà bí èmi, ta ló lè sọ pé kí ni mò ń ṣe? Olùṣọ́ àgùntàn wo ló sì lè dúró níwájú mi?+ 20 Nítorí náà, ẹ gbọ́ ìpinnu* tí Jèhófà ṣe lórí Édómù àti ohun tí ó ti rò nípa àwọn tó ń gbé ní Témánì:+ Ó dájú pé, a ó wọ́ àwọn ẹran kéékèèké inú agbo ẹran lọ. Ó máa sọ ibùgbé wọn di ahoro nítorí wọn.+ 21 Nígbà tí wọ́n ṣubú, ìró wọn mú kí ilẹ̀ mì tìtì. Igbe ẹkún wà! A gbọ́ ìró wọn títí dé Òkun Pupa.+ 
 
-