-
Jeremáyà 50:44-46Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
44 “Wò ó! Ẹnì kan máa wá gbéjà ko àwọn ibi ìjẹko Bábílónì tó wà ní ààbò bíi kìnnìún tó jáde látinú igbó kìjikìji lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jọ́dánì, ṣùgbọ́n ní ìṣẹ́jú kan, màá mú kí wọ́n sá kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀. Màá sì yan àyànfẹ́ lé e lórí.+ Nítorí ta ló dà bí èmi, ta ló lè sọ pé kí ni mò ń ṣe? Olùṣọ́ àgùntàn wo ló sì lè dúró níwájú mi?+ 45 Nítorí náà, ẹ gbọ́ ìpinnu* tí Jèhófà ṣe lórí Bábílónì + àti ohun tí ó ti rò nípa àwọn tó ń gbé ní Kálídíà.
Ó dájú pé, a ó wọ́ àwọn ẹran kéékèèké inú agbo ẹran lọ.
Ó máa sọ ibùgbé wọn di ahoro nítorí wọn.+
46 Nígbà tí wọ́n bá gba Bábílónì, ìró rẹ̀ á mú kí ilẹ̀ mì tìtì,
A ó sì gbọ́ igbe ẹkún láàárín àwọn orílẹ̀-èdè.”+
-