-
Jeremáyà 50:13Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
Ẹnikẹ́ni tó bá ń kọjá lọ lẹ́gbẹ̀ẹ́ Bábílónì á wò ó, ẹ̀rù á bà á
Á sì súfèé nítorí gbogbo ìyọnu rẹ̀.+
-
-
Jeremáyà 50:39, 40Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
39 Nítorí náà, àwọn ẹranko tó ń gbé ní aṣálẹ̀ á máa gbé pẹ̀lú àwọn ẹranko tó ń hu,
Inú rẹ̀ sì ni ògòǹgò á máa gbé.+
Ẹnikẹ́ni ò sì ní gbé ibẹ̀ mọ́ láé,
Bẹ́ẹ̀ ni kò ní jẹ́ ibi tí àwọn èèyàn á máa gbé láti ìran dé ìran.”+
40 “Bí Ọlọ́run ṣe pa Sódómù àti Gòmórà+ àti àwọn ìlú tó yí wọn ká run,”+ ni Jèhófà wí, “kò ní sí ẹnì kankan tí á máa gbé ibẹ̀, kò sì ní sí èèyàn kankan tó máa tẹ̀ dó síbẹ̀.+
-