ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Mátíù 22:41-46
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 41 Nígbà tí àwọn Farisí kóra jọ, Jésù bi wọ́n pé:+ 42 “Kí lèrò yín nípa Kristi? Ọmọ ta ni?” Wọ́n sọ fún un pé: “Ọmọ Dáfídì ni.”+ 43 Ó bi wọ́n pé: “Kí wá nìdí tí Dáfídì fi pè é ní Olúwa nípasẹ̀ ìmísí,+ tó sọ pé, 44 ‘Jèhófà* sọ fún Olúwa mi pé: “Jókòó sí ọwọ́ ọ̀tún mi, títí màá fi fi àwọn ọ̀tá rẹ sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ”’?+ 45 Tí Dáfídì bá pè é ní Olúwa, báwo ló ṣe jẹ́ ọmọ rẹ̀?”+ 46 Kò sẹ́ni tó lè dá a lóhùn rárá, láti ọjọ́ yẹn lọ, kò sẹ́ni tó jẹ́ bi í ní ìbéèrè mọ́.

  • Máàkù 12:35-37
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 35 Bí Jésù ṣe ń kọ́ni nínú tẹ́ńpìlì, ó sọ pé: “Kí nìdí tí àwọn akọ̀wé òfin fi sọ pé ọmọ Dáfídì ni Kristi?+ 36 Nípasẹ̀ ẹ̀mí mímọ́,+ Dáfídì fúnra rẹ̀ sọ pé, ‘Jèhófà* sọ fún Olúwa mi pé: “Jókòó sí ọwọ́ ọ̀tún mi, títí màá fi fi àwọn ọ̀tá rẹ sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ.”’+ 37 Dáfídì fúnra rẹ̀ pè é ní Olúwa, báwo ló ṣe wá jẹ́ ọmọ rẹ̀?”+

      Èrò rẹpẹtẹ náà ń gbádùn ọ̀rọ̀ rẹ̀.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́