-
Mátíù 22:41-46Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
41 Nígbà tí àwọn Farisí kóra jọ, Jésù bi wọ́n pé:+ 42 “Kí lèrò yín nípa Kristi? Ọmọ ta ni?” Wọ́n sọ fún un pé: “Ọmọ Dáfídì ni.”+ 43 Ó bi wọ́n pé: “Kí wá nìdí tí Dáfídì fi pè é ní Olúwa nípasẹ̀ ìmísí,+ tó sọ pé, 44 ‘Jèhófà* sọ fún Olúwa mi pé: “Jókòó sí ọwọ́ ọ̀tún mi, títí màá fi fi àwọn ọ̀tá rẹ sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ”’?+ 45 Tí Dáfídì bá pè é ní Olúwa, báwo ló ṣe jẹ́ ọmọ rẹ̀?”+ 46 Kò sẹ́ni tó lè dá a lóhùn rárá, láti ọjọ́ yẹn lọ, kò sẹ́ni tó jẹ́ bi í ní ìbéèrè mọ́.
-
-
Máàkù 12:35-37Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
35 Bí Jésù ṣe ń kọ́ni nínú tẹ́ńpìlì, ó sọ pé: “Kí nìdí tí àwọn akọ̀wé òfin fi sọ pé ọmọ Dáfídì ni Kristi?+ 36 Nípasẹ̀ ẹ̀mí mímọ́,+ Dáfídì fúnra rẹ̀ sọ pé, ‘Jèhófà* sọ fún Olúwa mi pé: “Jókòó sí ọwọ́ ọ̀tún mi, títí màá fi fi àwọn ọ̀tá rẹ sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ.”’+ 37 Dáfídì fúnra rẹ̀ pè é ní Olúwa, báwo ló ṣe wá jẹ́ ọmọ rẹ̀?”+
Èrò rẹpẹtẹ náà ń gbádùn ọ̀rọ̀ rẹ̀.
-