HÁBÁKÚKÙ
1 Ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run sọ fún wòlíì Hábákúkù* nínú ìran pé kó kéde nìyí:
2 Jèhófà, báwo ló ṣe máa pẹ́ tó tí màá fi ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́ àmọ́ tí o kò gbọ́?+
Báwo ló ṣe máa pẹ́ tó tí màá fi ké pè ọ́ pé kí o gbà mí lọ́wọ́ ìwà ipá àmọ́ tí o kò dá sí i?*+
3 Kí nìdí tí o fi ń jẹ́ kí ohun búburú ṣẹlẹ̀ níṣojú mi?
Kí sì nìdí tí o fi fàyè gba ìnilára?
Kí nìdí tí ìparun àti ìwà ipá fi ń ṣẹlẹ̀ níṣojú mi?
Kí sì nìdí tí ìjà àti aáwọ̀ fi wà káàkiri?
4 Òfin kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ mọ́,
Kò sì sí ìdájọ́ òdodo rárá.
Torí àwọn ẹni ibi yí olódodo ká;
Ìdí nìyẹn tí wọ́n fi ń yí ìdájọ́ po.+
5 “Ẹ wo àwọn orílẹ̀-èdè kí ẹ sì kíyè sí i!
Kí ẹnu yà yín bí ẹ ṣe ń wò wọ́n, kí ó sì jọ yín lójú;
Torí ohun kan máa ṣẹlẹ̀ lásìkò yín,
Tí ẹ ò ní gbà gbọ́ tí wọ́n bá tiẹ̀ sọ ọ́ fún yín.+
Wọ́n yára bolẹ̀ káàkiri ayé
Láti gba àwọn ilé tí kì í ṣe tiwọn.+
7 Wọ́n ń dẹ́rù bani, wọ́n sì ń kóni láyà jẹ.
Wọ́n ń gbé ìdájọ́ àti àṣẹ* tiwọn kalẹ̀.+
Àwọn ẹṣin ogun wọn ń bẹ́ gìjàgìjà;
Ọ̀nà jíjìn làwọn ẹṣin wọn ti wá.
Wọ́n já ṣòòrò wálẹ̀ bí ẹyẹ idì tó fẹ́ yára gbé oúnjẹ.+
9 Torí wọ́n fẹ́ hùwà ipá ni wọ́n ṣe wá.+
Gbogbo wọn kọjú síbì kan náà bí afẹ́fẹ́ tó ń fẹ́ bọ̀ láti ìlà oòrùn,+
Wọ́n sì ń kó àwọn èèyàn lẹ́rú bí ẹni ń kó iyanrìn.
Wọ́n ń fi gbogbo ibi olódi rẹ́rìn-ín;+
Wọ́n fi iyẹ̀pẹ̀ mọ òkìtì, wọ́n sì gbà á.
12 Jèhófà, ṣebí láti ayérayé ni ìwọ ti wà?+
Ọlọ́run mi, Ẹni Mímọ́ mi, ìwọ kì í kú.*+
Kí ló wá dé tí o fi fàyè gba àwọn ọ̀dàlẹ̀,+
Tí o sì dákẹ́ títí ẹni burúkú fi gbé ẹni tó jẹ́ olódodo jù ú lọ mì?+
14 Kí nìdí tí o fi jẹ́ kí àwọn èèyàn dà bí ẹja inú òkun,
Bí àwọn ohun tó ń rákò, tí wọn ò ní olórí?
15 Ó* fi ìwọ̀ kó gbogbo wọn sókè.
Ó fi àwọ̀n rẹ̀ kó wọn,
Ó sì fi àwọ̀n ìpẹja rẹ̀ kó wọn jọ.
Ìdí nìyẹn tí inú rẹ̀ fi ń dùn ṣìnkìn.+
16 Ìdí nìyẹn tó fi ń rúbọ sí àwọ̀n rẹ̀,
Tó sì ń rú ẹbọ* sí àwọ̀n ìpẹja rẹ̀;
Torí wọ́n ń mú kí nǹkan ṣẹnuure fún un,*
Oúnjẹ tó dára jù ló sì ń jẹ.
17 Ṣé gbogbo ìgbà ni yóò máa kó nǹkan jáde nínú àwọ̀n rẹ̀ ni?*
Ṣé bí á ṣe máa pa àwọn orílẹ̀-èdè lọ láì ṣàánú wọn nìyí?+
Èmi yóò máa ṣọ́nà kí n lè mọ ohun tí yóò sọ nípasẹ̀ mi
Àti ohun tí èmi yóò sọ nígbà tó bá bá mi wí.
2 Jèhófà wá dá mi lóhùn pé:
“Kọ ìran náà sílẹ̀, kí o sì kọ ọ́ sára wàláà,+ kó hàn kedere,
Tó bá tiẹ̀ falẹ̀,* ṣáà máa retí rẹ̀!*+
Torí yóò ṣẹ láìkùnà.
Kò ní pẹ́ rárá!
Àmọ́ ìṣòtítọ́* yóò mú kí olódodo wà láàyè.+
5 Torí pé wáìnì ń tanni jẹ lóòótọ́,
Ọwọ́ ẹni tó jọ ara rẹ̀ lójú kò ní tẹ àfojúsùn rẹ̀.
Ó ń kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ,
Ó sì ń kó gbogbo èèyàn sọ́dọ̀ ara rẹ̀.+
6 Ṣé kì í ṣe gbogbo wọn ló máa pa òwe, àṣamọ̀ àti àlọ́ láti bá a jà?+
Wọ́n á sọ pé:
‘Ẹni tó ń kó ohun tí kì í ṣe tirẹ̀ jọ gbé!
Tó sì ń mú kí gbèsè ọrùn rẹ̀ pọ̀ sí i.
Ìgbà wo ló máa ṣe èyí dà?
7 Ǹjẹ́ àwọn tó yá ọ lówó kò ní dìde sí ọ lójijì?
Wọ́n á ta jí, wọ́n á sì fipá mì ọ́ jìgìjìgì,
Wọ́n á sì kó ọ bí ẹrù tí wọ́n kó dé látojú ogun.+
8 Torí ìwọ náà ti kó ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè lẹ́rù,
Gbogbo èèyàn yóò kó ọ lẹ́rù,+
Nítorí ẹ̀jẹ̀ àwọn èèyàn tí o ta sílẹ̀
Àti ìwà ipá tí o hù sí ayé,
Sí àwọn ìlú àti àwọn tó ń gbé inú wọn.+
9 Ẹni tó ń kó èrè tí kò tọ́ jọ fún ilé rẹ̀ gbé!
Kó lè kọ́ ìtẹ́ rẹ̀ sí ibi gíga,
Kó má bàa kó sínú àjálù.
10 O ti gbèrò ohun tó kó ìtìjú bá ilé rẹ.
O ṣẹ̀ sí ara* rẹ bí o ṣe pa ọ̀pọ̀ èèyàn run.+
11 Òkúta yóò ké jáde láti inú ògiri,
Igi ìrólé yóò sì dá a lóhùn látorí àjà.
12 Ẹni tó ń fi ìtàjẹ̀sílẹ̀ kọ́ ìlú gbé,
Àti ẹni tó ń fi àìṣòdodo tẹ ìlú dó!
13 Wò ó! Ṣé kì í ṣe Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun ló ń mú kí àwọn èèyàn ṣiṣẹ́ kára fún ohun tó ṣì máa jóná,
Tó sì ń mú kí àwọn orílẹ̀-èdè ṣe wàhálà lásán?+
14 Torí gbogbo ayé yóò ní ìmọ̀ nípa ògo Jèhófà
Bí ìgbà tí omi bo òkun.+
15 Ẹni tó ń fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ ní nǹkan mu gbé!
Tó ń fi ìbínú àti ìkanra ṣe é, kó lè mú kí wọ́n yó,
Kó lè wo ìhòòhò wọn!
16 Àbùkù ni wọn yóò fi kàn ọ́ dípò ògo.
Ìwọ náà mu ún, kí o sì ṣí adọ̀dọ́ rẹ tí wọn ò dá sí gbangba.*
Ife ọwọ́ ọ̀tún Jèhófà yóò dé ọ̀dọ̀ rẹ,+
Ìtìjú yóò sì bo ògo rẹ mọ́lẹ̀;
17 Torí ìwà ipá tí o hù sí Lẹ́bánónì yóò bò ọ́ mọ́lẹ̀,
Ìparun tó dẹ́rù ba àwọn ẹranko yóò dé bá ọ,
Nítorí ẹ̀jẹ̀ àwọn èèyàn tí o ta sílẹ̀
Àti ìwà ipá tí o hù sí ayé,
Sí àwọn ìlú àti àwọn tó ń gbé inú wọn.+
18 Kí ni àǹfààní ère,
Nígbà tó jẹ́ pé èèyàn ló gbẹ́ ẹ?
Kí ni àǹfààní ère onírin* àti olùkọ́ èké,
Tí ẹni tó ṣe é bá tiẹ̀ gbẹ́kẹ̀ lé e,
Tó ṣe àwọn ọlọ́run tí kò ní láárí, tí kò lè sọ̀rọ̀?+
19 O gbé, ìwọ tí ò ń sọ fún igi pé: “Dìde!”
Tàbí fún òkúta tí kò lè sọ̀rọ̀ pé: “Gbéra nílẹ̀! Máa kọ́ wa!”
20 Àmọ́ Jèhófà wà nínú tẹ́ńpìlì mímọ́ rẹ̀.+
Gbogbo ayé, ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú rẹ̀!’”+
3 Àdúrà tí wòlíì Hábákúkù fi orin arò* gbà:
2 Jèhófà, mo ti gbọ́ ìròyìn nípa rẹ.
Jèhófà, ohun tí o ṣe bà mí lẹ́rù.
Tún ṣe bẹ́ẹ̀ lásìkò wa!*
Jẹ́ ká tún rí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ nígbà tiwa.*
Jọ̀ọ́, rántí fi àánú hàn nígbà wàhálà.+
Iyì rẹ̀ gba ọ̀run kan;+
Ayé sì kún fún ìyìn rẹ̀.
Ìtànṣán méjì jáde láti ọwọ́ rẹ̀,
Níbi tí agbára rẹ̀ wà.
6 Ó dúró jẹ́ẹ́, ó sì mi ayé jìgìjìgì.+
Ó wo àwọn orílẹ̀-èdè, ó sì mú kí wọ́n gbọ̀n rìrì.+
Ó fọ́ àwọn òkè tó ti wà tipẹ́,
Àwọn òkè àtayébáyé sì tẹrí ba.+
Òun ló ni àwọn ọ̀nà àtijọ́.
7 Mo rí wàhálà nínú àwọn àgọ́ Kúṣánì.
Àwọn aṣọ àgọ́ ilẹ̀ Mídíánì sì gbọ̀n rìrì.+
8 Jèhófà, ṣé àwọn odò ni?
Ṣé àwọn odò lò ń bínú sí?
Àbí òkun lò ń kanra mọ́?+
9 O ti yọ ọfà rẹ síta, o sì ti ṣe tán láti ta á.
Àwọn ọ̀pá* rẹ fẹ́ ṣe ohun tí o búra.* (Sélà)
O fi odò pín ayé.
10 Àwọn òkè jẹ̀rora nígbà tí wọ́n rí ọ.+
Ọ̀gbàrá òjò wọ́ kọjá.
Ibú omi pariwo.+
Ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè.
11 Oòrùn àti òṣùpá dúró jẹ́ẹ́ níbi tí wọ́n wà lókè.+
Àwọn ọfà rẹ ń yára jáde bí ìmọ́lẹ̀.+
Ọ̀kọ̀ rẹ ń kọ mànà.
12 O fi ìkannú rin ayé já.
O fi ìbínú tẹ àwọn orílẹ̀-èdè mọ́lẹ̀.*
13 O jáde lọ láti gba àwọn èèyàn rẹ là, kí o lè gba ẹni àmì òróró rẹ là.
O tẹ olórí* ilé àwọn ẹni burúkú rẹ́.
O wó ilé náà láti òkè* títí dé ìpìlẹ̀. (Sélà)
14 O fi àwọn ohun ìjà rẹ̀* gún àwọn jagunjagun rẹ̀ ní orí
Nígbà tí wọ́n ya bò mí bí ìjì láti tú mi ká.
Inú wọn dùn láti dúró sí ìkọ̀kọ̀ kí wọ́n lè pa ẹni tí ìyà ń jẹ run.
15 O fi àwọn ẹṣin rẹ rin òkun já,
O fi wọ́n la ibú omi kọjá.
Egungun mi bẹ̀rẹ̀ sí í jẹrà;+
Ẹsẹ̀ mi ń gbọ̀n rìrì.
Àmọ́ mò ń fara balẹ̀ dúró de ọjọ́ wàhálà,+
Torí àwọn tó ń gbógun tì wá ni yóò dé bá.
17 Igi ọ̀pọ̀tọ́ lè má rúwé,
Àjàrà sì lè má so èso;
Tí igi ólífì kò bá tiẹ̀ so,
Tí ilẹ̀* kò sì mú èso jáde;
Tí kò bá tiẹ̀ sí agbo ẹran mọ́ nínú ọgbà ẹran,
Tí kò sì sí màlúù mọ́ ní ilé ẹran;
18 Síbẹ̀, ní tèmi, màá yọ̀ gidigidi nínú Jèhófà;
Inú mi yóò dùn nínú Ọlọ́run ìgbàlà mi.+
19 Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ ni agbára mi;+
Yóò mú kí ẹsẹ̀ mi dà bíi ti àgbọ̀nrín,
Yóò sì mú kí n rìn lórí àwọn ibi gíga.+
Sí olùdarí; pẹ̀lú àwọn ohun ìkọrin mi olókùn tín-ín-rín.
Ó ṣeé ṣe kó túmọ̀ sí “Gbáni Mọ́ra Tọkàntọkàn.”
Tàbí “gbani là.”
Tàbí “iyì.”
Tàbí kó jẹ́, “agbára wọn ni ọlọ́run wọn.”
Tàbí kó jẹ́, “àwa kò ní kú.”
Tàbí “láti báni wí.”
Ìyẹn, àwọn ará Kálídíà tó jẹ́ ọ̀tá.
Tàbí “èéfín ẹbọ.”
Ní Héb., “òróró dun oúnjẹ rẹ̀.”
Tàbí kó jẹ́, “máa fa idà rẹ̀ yọ?”
Tàbí “lọ́nà tó já geere.”
Tàbí “ti fẹ́rẹ̀ẹ́ ṣẹ.”
Tàbí “dà bíi pé ó falẹ̀.”
Tàbí “máa fojú sọ́nà fún un.”
Tàbí “Wò ó! Ọkàn rẹ̀ ń wú fùkẹ̀.”
Tàbí kó jẹ́, “ìgbàgbọ́.”
Tàbí “Ọkàn rẹ̀ kì í.”
Tàbí “Ṣìọ́ọ̀lù,” ìyẹn ibojì aráyé. Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí kó jẹ́, “kí o sì máa ta gọ̀ọ́gọ̀ọ́.”
Tàbí “ère dídà.”
Tàbí “orin ọ̀fọ̀.”
Tàbí kó jẹ́, “láàárín àwọn ọdún.”
Tàbí kó jẹ́, “láàárín àwọn ọdún.”
Wo Àlàyé Ọ̀rọ̀.
Tàbí “gbani là.”
Tàbí kó jẹ́, “ọfà.”
Tàbí kó jẹ́, “Àwọn ẹ̀yà ti sọ ohun tí wọ́n búra.”
Ní Héb., “pa àwọn orílẹ̀-èdè bí ọkà.”
Ní Héb., “orí.”
Ní Héb., “ọrùn.”
Ní Héb., “àwọn ọ̀pá rẹ̀.”
Ní Héb., “ikùn mi gbọ̀n rìrì.”
Tàbí “ilẹ̀ onípele.”