ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g97 1/22 ojú ìwé 31
  • Òpópónà Emmy Zehden—Bí Orúkọ náà Ṣe Wáyé

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Òpópónà Emmy Zehden—Bí Orúkọ náà Ṣe Wáyé
  • Jí!—1997
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Kí Ló Ṣẹlẹ̀ sí Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà Nígbà Ìpakúpa Rẹpẹtẹ Tó Wáyé Nígbà Ìjọba Násì?
    Àwọn Ìbéèrè Táwọn Èèyàn Sábà Máa Ń Béèrè Nípa Ẹlẹ́rìí Jèhófà
  • Bíi Ti Pétérù, Má Jẹ́ Kó Sú Ẹ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2023
  • Jehofa Bojuto Wa Labẹ Ifofinde—Apa 3
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1992
  • Bí Ìdílé Mi Ṣe Dúró Ṣinṣin ti Ọlọ́run Sún Mi Ṣiṣẹ́
    Jí!—1998
Àwọn Míì
Jí!—1997
g97 1/22 ojú ìwé 31

Òpópónà Emmy Zehden—Bí Orúkọ náà Ṣe Wáyé

NÍ May 1992, wọ́n sọ òpópó kan ní ìlú ńlá Berlin, Germany, ní orúkọ Emmy Zehden, tí ó jẹ́ ọ̀kan lára Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà.

Wọ́n bí Emmy ní ọdún 1900. Júù oníṣòwò kan, Richard Zehden, tí ó kú sí àgọ́ ìṣẹ́niníṣẹ̀ẹ́ Auschwitz lákòókò ìṣàkóso ìjọba Nazi, ni ọkọ rẹ̀. Richard àti Emmy ní ọmọkùnrin kan tí wọ́n gbà ṣọmọ, Horst Schmidt. Ó di ọ̀ràn-anyàn fún Horst àti àwọn ọ̀dọ́ Ẹlẹ́rìí Jèhófà méjì míràn láti sá pa mọ́ nígbà tí a pè wọ́n fún iṣẹ́ ológun.

Emmy fi Horst àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ méjèèjì pa mọ́. Bí ó ti wù kí ó rí, bí àkókò ti ń lọ, àṣírí tú. Wọ́n dájọ́ ikú fún àwọn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin—ti àwọn ọmọdékùnrin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta náà jẹ́ nítorí pé wọn kò tẹ́wọ́ gba iṣẹ́ ológun, ti Emmy sì jẹ́ nítorí pé ó fi wọ́n pa mọ́. Wọ́n bẹ́ àwọn ẹlẹgbẹ́ Horst méjèèjì lórí. Emmy béèrè fún ìdáríjì, àmọ́ wọn kò dárí jì í. Wọ́n bẹ́ ẹ lórí ní Plötzensee, ní Berlin, ní June 9, 1944.a Horst Schmidt la ìṣẹ́niníṣẹ̀ẹ́ ìjọba Nazi já, nígbà tí ó sì ṣe, ó gbé Ẹlẹ́rìí kan tí ó la àgọ́ ìṣẹ́niníṣẹ̀ẹ́ já níyàwó.

Ní May 7, 1992, wọ́n sọ òpópónà kan ní Berlin ní orúkọ Emmy Zehden. Nínú ọ̀rọ̀ kan tí òṣìṣẹ́ kan ní Germany sọ, wọ́n yìn ín fún ìgboyà rẹ̀, wọ́n sì tọ́ka sí i gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ ọ̀kan lára ọ̀pọ̀ ‘àwọn òjìyà’ ogun náà ‘tí a ti gbàgbé.’

[Àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé]

a Gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ tí a fàṣẹ sí tí ó wà ní Ibi Ìrántí Berlin-Plötzensee, June 9, 1944 ni wọ́n pa Emmy Zehden.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́