ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w95 1/15 ojú ìwé 3
  • Báwo Ni Ìwàláàyè Ṣe Ṣeyebíye fún Ọ Tó?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Báwo Ni Ìwàláàyè Ṣe Ṣeyebíye fún Ọ Tó?
  • Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1995
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìṣòro Tó Kárí Ayé
    Jí!—2001
  • Pípa Ara Ẹni—Ìṣòro Wíwọ́pọ̀ Láàárín Àwọn Ọ̀dọ́
    Jí!—1998
  • Ohun Tó Ń mú Káyé Sú Àwọn Èèyàn Kan
    Jí!—2001
  • O Lè Rí Ìrànwọ́
    Jí!—2001
Àwọn Míì
Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1995
w95 1/15 ojú ìwé 3

Báwo Ni Ìwàláàyè Ṣe Ṣeyebíye fún Ọ Tó?

Ọ̀DỌ́MỌDÉKÙNRIN kan ṣekúpa ara rẹ̀ nígbà tí ó bẹ́ sílẹ̀ láti àjà kẹjọ pẹ̀tẹ́ẹ̀sì nínú ilé kan tí ó ní àwọn ibùgbé àdáni. Ó ti ka ìwé tí ó ṣàpèjúwe pé bíbẹ́ sílẹ̀ láti ibi gíga “kò ní nǹkankan ṣe pẹ̀lú ìrora tàbí àìfararọ tàbí ìbẹ̀rù; kàkà bẹ́ẹ̀, ó ń gbádùnmọ́ni.” Ẹni tí ó kọ ìwé tí a tẹ̀jáde ní Japan yìí, sọ pé òun wulẹ̀ ń dábàá “ìfọwọ́ ara-ẹni pa ara-ẹni gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan lára àwọn yíyàn tí ń bẹ nínú ìgbésí-ayé ni.”

Kì í ṣe kìkì àwọn ènìyàn tí wọ́n ń fi ọwọ́ ara wọn pa ara wọn ni wọ́n ṣàìka ìwàláàyè sí lónìí. Àwọn tí ń wakọ̀ níwàkiwà pẹ̀lú ń fi ọ̀wọ̀ tí kò tó nǹkan hàn fún ìwàláàyè. Àwọn kan tilẹ̀ ń mutí wakọ̀, ọ̀pọ̀ ń ṣínábolẹ̀ lójú títì tí wọ́n sì ń ṣekúpa ara wọn.

Àwọn mìíràn ń fi bí wọ́n ṣe kó iyán ìwàláàyè wọn kéré tó hàn nípa ìtẹnumọ́ tí wọ́n gbékarí ìgbádùn. Àwọn amusìgá kọ̀ láti dáwọ́ sìgá mímu dúró, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé sìgá mímu lè fa ikú tí a sì ti pè é ní ikú ayọ́kẹ́lẹ́ pani. Kàkà tí wọn ìbá fi pa ìwà-ní-mímọ́ mọ́ nínú ayé tí ìbálòpọ̀ ń sínníwín yìí, ọ̀pọ̀ ń lépa àti máa ṣe ìṣekúṣe tí ó sábà máa ń yọrísí ikú.

Láìtilẹ̀ mọ̀ rárá, àwọn kan ń fi ọ̀pọ̀ ọdún ìwàláàyè du ara wọn nípa àjẹjù, àmujù, eré ìmárale tí kò tó, àti wíwá ìgbádùn. Òǹkọ̀wé ilẹ̀ Japan náà Shinya Nishimaru kìlọ̀ pé: “Àṣà oúnjẹ jíjẹ tí kò ní ìdiwọ̀n kì í jẹ́ kí ètò-inú ara ṣiṣẹ́ déédéé, bẹ́ẹ̀ sì ni ìlépa ìrọ̀rùn àti ìgbádùn nìkan ṣáá ń sọ àwọn ènìyàn di aláìlókun nínú.” Àwọn kan ní ojú-ìwòye kan náà pẹ̀lú àwọn ará ìgbàanì tí wọ́n sọ pé: “Ẹ jẹ́ kí a máa jẹ, kí a sì máa mu; nítorí ọ̀la ni àwa óò kú.”—Isaiah 22:13; 1 Korinti 15:32, NW.

Bẹ́ẹ̀ni, àìka ìwàláàyè sí ti gbilẹ̀ káàkiri lónìí. Nítorí náà, ó yẹ láti béèrè pé, Báwo ni ìwàláàyè ṣe ṣeyebíye fún ọ tó? Ó ha yẹ kí a pa ìwàláàyè mọ́ ní àforí-àfọrùn bí? Ohunkóhun ha sì wà tí ó ṣeyebíye ju ìwàláàyè wa ìsinsìnyí lọ bí?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́