ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
Yorùbá Publications (1987-2026)
Jáde
Wọlé
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Òní

Sunday, October 19

Ẹ rọ àwọ̀n yín sísàlẹ̀ láti kó ẹja.—Lúùkù 5:4.

Jésù fi dá àpọ́sítélì Pétérù lójú pé Jèhófà máa bójú tó o. Lẹ́yìn tí Jésù jíǹde, ó jẹ́ kí Pétérù àtàwọn àpọ́sítélì yòókù rí ẹja pa lọ́nà ìyanu. (Jòh. 21:​4-6) Iṣẹ́ ìyanu yìí jẹ́ kó túbọ̀ dá Pétérù lójú pé Jèhófà máa pèsè àwọn ohun tó nílò. Ó ṣeé ṣe kí Pétérù rántí ohun tí Jésù sọ pé Jèhófà máa pèsè fún àwọn tó bá ń ‘wá Ìjọba náà lákọ̀ọ́kọ́.’ (Mát. 6:33) Torí náà, iṣẹ́ ìwàásù ni Pétérù gbájú mọ́, kì í ṣe iṣẹ́ ẹja pípa. Ó fi ìgboyà sọ̀rọ̀ níwájú ọ̀pọ̀ èèyàn lọ́jọ́ Pẹ́ńtíkọ́sì 33 S.K., ìyẹn sì jẹ́ kí wọ́n di ọmọ ẹ̀yìn. (Ìṣe 2:​14, 37-41) Lẹ́yìn náà, ó tún ran àwọn ará Samáríà àtàwọn tí kì í ṣe Júù lọ́wọ́ láti di ọmọ ẹ̀yìn Kristi. (Ìṣe 8:​14-17; 10:​44-48) Ó dájú pé Jèhófà lo Pétérù lọ́nà àrà ọ̀tọ̀ láti ran onírúurú èèyàn lọ́wọ́, kí wọ́n lè dara pọ̀ mọ́ ìjọ Kristẹni. w23.09 20 ¶1; 23 ¶11

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Monday, October 20

Tí ẹ ò bá sọ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi, a máa gé yín sí wẹ́wẹ́.—Dán. 2:5.

Nǹkan bí ọdún méjì lẹ́yìn táwọn ará Bábílónì pa Jerúsálẹ́mù run, Nebukadinésárì ọba Bábílónì lá àlá kan tó bani lẹ́rù. Nínú àlá náà, ó rí ère ńlá kan. Ó sọ pé òun máa pa gbogbo àwọn amòye òun títí kan Dáníẹ́lì tí wọn ò bá lè sọ àlá náà, kí wọ́n sì túmọ̀ ẹ̀. (Dán. 2:​3-5) Dáníẹ́lì gbọ́dọ̀ gbé ìgbésẹ̀ kíákíá, àìjẹ́ bẹ́ẹ̀, ọ̀pọ̀ èèyàn ló máa kú. Torí náà ó “wọlé, ó sì ní kí ọba yọ̀ǹda àkókò fún òun kóun lè sọ ìtumọ̀ àlá náà fún ọba.” (Dán. 2:16) Ẹ ò rí i pé ohun tó ṣe yìí gba ìgboyà àti ìgbàgbọ́! Kò sí àkọsílẹ̀ kankan nínú Bíbélì tó fi hàn pé Dáníẹ́lì ti túmọ̀ àlá rí. Torí náà, ó sọ fún àwọn ọ̀rẹ́ ẹ̀ pé “kí wọ́n gbàdúrà sí Ọlọ́run ọ̀run fún àánú nípa àṣírí yìí.” (Dán. 2:18) Jèhófà sì dáhùn àdúrà wọn. Ó ran Dáníẹ́lì lọ́wọ́ láti túmọ̀ àlá Nebukadinésárì, ìyẹn ni ò sì jẹ́ kí Dáníẹ́lì àtàwọn ọ̀rẹ́ ẹ̀ kú. w23.08 3 ¶4

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Tuesday, October 21

Ẹni tó bá fara dà á dé òpin máa rí ìgbàlà.—Mát. 24:13.

Wo àǹfààní tá a máa rí tá a bá ń ní sùúrù. Tá a bá ń ní sùúrù, a máa láyọ̀, ọkàn wa sì máa balẹ̀. Torí náà, sùúrù máa ń jẹ́ ká ní ìlera tó jí pépé. Tá a bá ń ní sùúrù fáwọn èèyàn, àárín wa á túbọ̀ gún régé, ìyẹn sì máa jẹ́ káwọn ará ìjọ túbọ̀ wà níṣọ̀kan. Tẹ́nì kan bá múnú bí wa, àmọ́ tá ò tètè bínú, kò ní jẹ́ kọ́rọ̀ náà dìjà. (Sm. 37:​8, àlàyé ìsàlẹ̀; Òwe 14:29) Èyí tó ṣe pàtàkì jù ni pé ṣe là ń fara wé Bàbá wa ọ̀run, àá sì túbọ̀ sún mọ́ ọn. Ẹ ò rí i pé ìwà tó dáa gan-an ni sùúrù, ó sì ń ṣeni láǹfààní! Bó tiẹ̀ jẹ́ pé kì í ṣe gbogbo ìgbà ló máa ń rọrùn láti ní sùúrù, tá a bá bẹ Jèhófà pé kó ràn wá lọ́wọ́, àá máa ní sùúrù. Bákan náà, bá a ṣe ń ní sùúrù kí ayé tuntun dé, ẹ jẹ́ kó dá wa lójú pé “ojú Jèhófà ń ṣọ́ àwọn tó bẹ̀rù rẹ̀, àwọn tó ń dúró de ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.” (Sm. 33:18) Torí náà, ẹ jẹ́ kí gbogbo wa máa fi sùúrù wọ ara wa láṣọ. w23.08 22 ¶7; 25 ¶16-17

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́