Monday, October 20
Tí ẹ ò bá sọ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi, a máa gé yín sí wẹ́wẹ́.—Dán. 2:5.
Nǹkan bí ọdún méjì lẹ́yìn táwọn ará Bábílónì pa Jerúsálẹ́mù run, Nebukadinésárì ọba Bábílónì lá àlá kan tó bani lẹ́rù. Nínú àlá náà, ó rí ère ńlá kan. Ó sọ pé òun máa pa gbogbo àwọn amòye òun títí kan Dáníẹ́lì tí wọn ò bá lè sọ àlá náà, kí wọ́n sì túmọ̀ ẹ̀. (Dán. 2:3-5) Dáníẹ́lì gbọ́dọ̀ gbé ìgbésẹ̀ kíákíá, àìjẹ́ bẹ́ẹ̀, ọ̀pọ̀ èèyàn ló máa kú. Torí náà ó “wọlé, ó sì ní kí ọba yọ̀ǹda àkókò fún òun kóun lè sọ ìtumọ̀ àlá náà fún ọba.” (Dán. 2:16) Ẹ ò rí i pé ohun tó ṣe yìí gba ìgboyà àti ìgbàgbọ́! Kò sí àkọsílẹ̀ kankan nínú Bíbélì tó fi hàn pé Dáníẹ́lì ti túmọ̀ àlá rí. Torí náà, ó sọ fún àwọn ọ̀rẹ́ ẹ̀ pé “kí wọ́n gbàdúrà sí Ọlọ́run ọ̀run fún àánú nípa àṣírí yìí.” (Dán. 2:18) Jèhófà sì dáhùn àdúrà wọn. Ó ran Dáníẹ́lì lọ́wọ́ láti túmọ̀ àlá Nebukadinésárì, ìyẹn ni ò sì jẹ́ kí Dáníẹ́lì àtàwọn ọ̀rẹ́ ẹ̀ kú. w23.08 3 ¶4
Tuesday, October 21
Ẹni tó bá fara dà á dé òpin máa rí ìgbàlà.—Mát. 24:13.
Wo àǹfààní tá a máa rí tá a bá ń ní sùúrù. Tá a bá ń ní sùúrù, a máa láyọ̀, ọkàn wa sì máa balẹ̀. Torí náà, sùúrù máa ń jẹ́ ká ní ìlera tó jí pépé. Tá a bá ń ní sùúrù fáwọn èèyàn, àárín wa á túbọ̀ gún régé, ìyẹn sì máa jẹ́ káwọn ará ìjọ túbọ̀ wà níṣọ̀kan. Tẹ́nì kan bá múnú bí wa, àmọ́ tá ò tètè bínú, kò ní jẹ́ kọ́rọ̀ náà dìjà. (Sm. 37:8, àlàyé ìsàlẹ̀; Òwe 14:29) Èyí tó ṣe pàtàkì jù ni pé ṣe là ń fara wé Bàbá wa ọ̀run, àá sì túbọ̀ sún mọ́ ọn. Ẹ ò rí i pé ìwà tó dáa gan-an ni sùúrù, ó sì ń ṣeni láǹfààní! Bó tiẹ̀ jẹ́ pé kì í ṣe gbogbo ìgbà ló máa ń rọrùn láti ní sùúrù, tá a bá bẹ Jèhófà pé kó ràn wá lọ́wọ́, àá máa ní sùúrù. Bákan náà, bá a ṣe ń ní sùúrù kí ayé tuntun dé, ẹ jẹ́ kó dá wa lójú pé “ojú Jèhófà ń ṣọ́ àwọn tó bẹ̀rù rẹ̀, àwọn tó ń dúró de ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.” (Sm. 33:18) Torí náà, ẹ jẹ́ kí gbogbo wa máa fi sùúrù wọ ara wa láṣọ. w23.08 22 ¶7; 25 ¶16-17
Wednesday, October 22
Ìgbàgbọ́ nìkan láìsí àwọn iṣẹ́ jẹ́ òkú.—Jém. 2:17.
Jémíìsì jẹ́ ká mọ̀ pé ọkùnrin kan lè sọ pé òun nígbàgbọ́, àmọ́ kò ṣe nǹkan tó fi hàn pé ó nígbàgbọ́. (Jém. 2:1-5, 9) Jémíìsì tún sọ nípa ẹnì kan tó rí ‘arákùnrin tàbí arábìnrin tí ò láṣọ, tí ò sì ní oúnjẹ,’ àmọ́ tí ò ràn án lọ́wọ́. Tírú ẹni bẹ́ẹ̀ bá sọ pé òun nígbàgbọ́ àmọ́ tí ò ṣe ohun tó fi hàn bẹ́ẹ̀, irú ìgbàgbọ́ bẹ́ẹ̀ ò wúlò. (Jém. 2:14-16) Jémíìsì wá sọ̀rọ̀ nípa Ráhábù, ó sì jẹ́ ká mọ̀ pé ó fi àpẹẹrẹ rere lélẹ̀ tó bá dọ̀rọ̀ ká ṣe nǹkan tó fi hàn pé a nígbàgbọ́. (Jém. 2:25, 26) Ráhábù ti gbọ́ nípa Jèhófà, ó sì mọ̀ pé òun ló ń ran àwọn ọmọ Ísírẹ́lì lọ́wọ́. (Jóṣ. 2:9-11) Ó ṣe nǹkan tó fi hàn pé ó nígbàgbọ́. Ó dáàbò bo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì méjì tí wọ́n lọ ṣe amí nígbà tí ẹ̀mí wọn wà nínú ewu. Torí ohun tí obìnrin aláìpé tí kì í ṣe ọmọ Ísírẹ́lì yìí ṣe, a pè é ní olódodo bíi ti Ábúráhámù. Àpẹẹrẹ rere tó fi lélẹ̀ jẹ́ ká rí i pé ó ṣe pàtàkì pé ká ṣe àwọn iṣẹ́ tó fi hàn pé a nígbàgbọ́. w23.12 5 ¶12-13