ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Òní

Thursday, October 23

Kí ẹ ta gbòǹgbò, kí ẹ sì fìdí múlẹ̀ lórí ìpìlẹ̀ náà.—Éfé. 3:17.

Kì í ṣe àwọn ẹ̀kọ́ àkọ́bẹ̀rẹ̀ nìkan ló yẹ káwa Kristẹni mọ̀. Ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run tún máa ń jẹ́ kó wù wá láti lóye “àwọn ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run.” (1 Kọ́r. 2:​9, 10) O ò ṣe bẹ̀rẹ̀ sí í kẹ́kọ̀ọ́ jinlẹ̀ nípa àwọn apá kan nínú Bíbélì táá jẹ́ kó o túbọ̀ sún mọ́ Jèhófà? Bí àpẹẹrẹ, o lè kẹ́kọ̀ọ́ nípa àwọn nǹkan tó ṣe fáwọn ìránṣẹ́ ẹ̀ nígbà àtijọ́ tó jẹ́ kí wọ́n mọ̀ pé ó nífẹ̀ẹ́ wọn àtàwọn nǹkan tó ń ṣe fún ìwọ náà báyìí tó jẹ́ kó o mọ̀ pé ó nífẹ̀ẹ́ ẹ. O lè kẹ́kọ̀ọ́ nípa bí Jèhófà ṣe ṣètò pé káwọn ọmọ Ísírẹ́lì máa jọ́sìn òun, kó o wá fi wé báwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ń jọ́sìn ẹ̀ lónìí. Yàtọ̀ síyẹn, o tún lè kẹ́kọ̀ọ́ nípa àwọn àsọtẹ́lẹ̀ tó ṣẹ sí Jésù lára nígbà tó ń ṣiṣẹ́ òjíṣẹ́ ẹ̀ láyé. Inú ẹ máa dùn gan-an tó o bá ṣèwádìí nípa àwọn nǹkan yìí nínú Watch Tower Publications Index lédè Gẹ̀ẹ́sì tàbí Ìwé Ìwádìí fún Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà. Tó o bá ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì jinlẹ̀, ìgbàgbọ́ ẹ máa lágbára, wàá sì “rí ìmọ̀ Ọlọ́run.”—Òwe 2:​4, 5. w23.10 18-19 ¶3-5

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Friday, October 24

Ju gbogbo rẹ̀ lọ, ẹ ní ìfẹ́ tó jinlẹ̀ fún ara yín, torí ìfẹ́ máa ń bo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ mọ́lẹ̀.—1 Pét. 4:8.

Ọ̀rọ̀ tí Pétérù lò nínú ẹsẹ yìí, ìyẹn “jinlẹ̀” túmọ̀ sí kéèyàn “na nǹkan.” Apá kejì nínú ẹsẹ yẹn wá sọ ohun tó yẹ ká ṣe tá a bá ní ìfẹ́ tó jinlẹ̀ sáwọn èèyàn. Ó sọ pé ó máa ń bo ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ará mọ́lẹ̀. Ẹ jẹ́ ká ṣàpèjúwe ẹ̀ báyìí: Téèyàn bá fi ọwọ́ méjèèjì di aṣọ kan mú tó sì fẹ́ fi bo nǹkan, ńṣe lá bẹ̀rẹ̀ sí í nà án títí á fi bo gbogbo ohun tó fẹ́ bò. Lọ́nà kan náà, ó yẹ ká máa fi ìfẹ́ bo ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ará mọ́lẹ̀, kì í ṣe ẹ̀ṣẹ̀ ẹyọ kan tàbí méjì, àmọ́ “ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀.” A lè fi béèyàn ṣe ń bo nǹkan wé béèyàn ṣe ń dárí ji àwọn ẹlòmíì. Bí aṣọ ṣe máa ń bo àbùkù ara, bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe yẹ ká máa fi ìfẹ́ bo kùdìẹ̀-kudiẹ àwọn ará. Tá a bá nífẹ̀ẹ́ àwọn ará gan-an, àá dárí jì wọ́n, kódà tó bá ṣòro láti ṣe bẹ́ẹ̀. (Kól. 3:13) Tá a bá ń dárí ji àwọn ará, ìyẹn máa fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ wọn, a sì fẹ́ múnú Jèhófà dùn. w23.11 10-12 ¶13-15

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Saturday, October 25

Ṣáfánì bẹ̀rẹ̀ sí í kà á níwájú ọba.—2 Kíró. 34:18.

Nígbà tí Ọba Jòsáyà pé ẹni ọdún mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n (26), ó bẹ̀rẹ̀ sí í tún tẹ́ńpìlì Jèhófà ṣe. Bí wọ́n ṣe ń ṣiṣẹ́ náà, wọ́n rí “ìwé Òfin tí Jèhófà fún wọn nípasẹ̀ Mósè.” Nígbà tí wọ́n ka ìwé náà fún ọba, ohun tó gbọ́ mú kó ṣe àtúnṣe lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀. (2 Kíró. 34:​14, 19-21) Ṣé ìwọ náà á máa ka Bíbélì lójoojúmọ́? Tó o bá ti ń ṣe bẹ́ẹ̀, ṣé ò ń gbádùn ẹ̀? Ṣé o máa ń ṣàkọsílẹ̀ àwọn ẹsẹ tó máa ràn ẹ́ lọ́wọ́? Nígbà tí Jòsáyà pé ẹni ọdún mọ́kàndínlógójì (39), ó ṣe àṣìṣe ńlá kan tó gba ẹ̀mí ẹ̀. Ó gbára lé ara ẹ̀ dípò kó gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà. (2 Kíró. 35:​20-25) Kí nìyẹn kọ́ wa? Kò sí bá a ṣe dàgbà tó tàbí bó ṣe wù kó pẹ́ tó tá a ti ń sin Jèhófà bọ̀, ó ṣe pàtàkì pé ká máa wá ìtọ́sọ́nà Jèhófà. Tá a bá máa ṣe bẹ́ẹ̀, ó gba pé ká máa gbàdúrà nígbà gbogbo pé kí Jèhófà tọ́ wa sọ́nà, ká máa kẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ rẹ̀, ká sì máa gbàmọ̀ràn lọ́dọ̀ àwọn Kristẹni tí òtítọ́ jinlẹ̀ nínú wọn. Tá a bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, a ò ní ṣàṣìṣe ńlá tó máa gbẹ̀mí wa bíi ti Jòsáyà, àá sì máa láyọ̀.—Jém. 1:25. w23.09 12-13 ¶15-16

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́