ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Òní

Friday, October 24

Ju gbogbo rẹ̀ lọ, ẹ ní ìfẹ́ tó jinlẹ̀ fún ara yín, torí ìfẹ́ máa ń bo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ mọ́lẹ̀.—1 Pét. 4:8.

Ọ̀rọ̀ tí Pétérù lò nínú ẹsẹ yìí, ìyẹn “jinlẹ̀” túmọ̀ sí kéèyàn “na nǹkan.” Apá kejì nínú ẹsẹ yẹn wá sọ ohun tó yẹ ká ṣe tá a bá ní ìfẹ́ tó jinlẹ̀ sáwọn èèyàn. Ó sọ pé ó máa ń bo ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ará mọ́lẹ̀. Ẹ jẹ́ ká ṣàpèjúwe ẹ̀ báyìí: Téèyàn bá fi ọwọ́ méjèèjì di aṣọ kan mú tó sì fẹ́ fi bo nǹkan, ńṣe lá bẹ̀rẹ̀ sí í nà án títí á fi bo gbogbo ohun tó fẹ́ bò. Lọ́nà kan náà, ó yẹ ká máa fi ìfẹ́ bo ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ará mọ́lẹ̀, kì í ṣe ẹ̀ṣẹ̀ ẹyọ kan tàbí méjì, àmọ́ “ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀.” A lè fi béèyàn ṣe ń bo nǹkan wé béèyàn ṣe ń dárí ji àwọn ẹlòmíì. Bí aṣọ ṣe máa ń bo àbùkù ara, bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe yẹ ká máa fi ìfẹ́ bo kùdìẹ̀-kudiẹ àwọn ará. Tá a bá nífẹ̀ẹ́ àwọn ará gan-an, àá dárí jì wọ́n, kódà tó bá ṣòro láti ṣe bẹ́ẹ̀. (Kól. 3:13) Tá a bá ń dárí ji àwọn ará, ìyẹn máa fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ wọn, a sì fẹ́ múnú Jèhófà dùn. w23.11 10-12 ¶13-15

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Saturday, October 25

Ṣáfánì bẹ̀rẹ̀ sí í kà á níwájú ọba.—2 Kíró. 34:18.

Nígbà tí Ọba Jòsáyà pé ẹni ọdún mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n (26), ó bẹ̀rẹ̀ sí í tún tẹ́ńpìlì Jèhófà ṣe. Bí wọ́n ṣe ń ṣiṣẹ́ náà, wọ́n rí “ìwé Òfin tí Jèhófà fún wọn nípasẹ̀ Mósè.” Nígbà tí wọ́n ka ìwé náà fún ọba, ohun tó gbọ́ mú kó ṣe àtúnṣe lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀. (2 Kíró. 34:​14, 19-21) Ṣé ìwọ náà á máa ka Bíbélì lójoojúmọ́? Tó o bá ti ń ṣe bẹ́ẹ̀, ṣé ò ń gbádùn ẹ̀? Ṣé o máa ń ṣàkọsílẹ̀ àwọn ẹsẹ tó máa ràn ẹ́ lọ́wọ́? Nígbà tí Jòsáyà pé ẹni ọdún mọ́kàndínlógójì (39), ó ṣe àṣìṣe ńlá kan tó gba ẹ̀mí ẹ̀. Ó gbára lé ara ẹ̀ dípò kó gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà. (2 Kíró. 35:​20-25) Kí nìyẹn kọ́ wa? Kò sí bá a ṣe dàgbà tó tàbí bó ṣe wù kó pẹ́ tó tá a ti ń sin Jèhófà bọ̀, ó ṣe pàtàkì pé ká máa wá ìtọ́sọ́nà Jèhófà. Tá a bá máa ṣe bẹ́ẹ̀, ó gba pé ká máa gbàdúrà nígbà gbogbo pé kí Jèhófà tọ́ wa sọ́nà, ká máa kẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ rẹ̀, ká sì máa gbàmọ̀ràn lọ́dọ̀ àwọn Kristẹni tí òtítọ́ jinlẹ̀ nínú wọn. Tá a bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, a ò ní ṣàṣìṣe ńlá tó máa gbẹ̀mí wa bíi ti Jòsáyà, àá sì máa láyọ̀.—Jém. 1:25. w23.09 12-13 ¶15-16

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Sunday, October 26

Ọlọ́run dojú ìjà kọ àwọn agbéraga, àmọ́ ó ń fi inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí hàn sí àwọn onírẹ̀lẹ̀.—Jém. 4:6.

Bíbélì sọ̀rọ̀ nípa àwọn obìnrin oníwà rere tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, tí wọ́n sì sìn ín. Wọn kì í ṣe “aláṣejù,” “wọ́n [sì] jẹ́ olóòótọ́ nínú ohun gbogbo.” (1 Tím. 3:11) Yàtọ̀ síyẹn, àwọn ọ̀dọ́bìnrin máa rí àwọn obìnrin Kristẹni tí òtítọ́ jinlẹ̀ nínú wọn ní ìjọ wọn, tí wọ́n lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ wọn. Ẹ̀yin ọ̀dọ́bìnrin, ẹ máa rí àwọn obìnrin rere nínú ìjọ yín tẹ́ ẹ lè fara wé. Ẹ máa kíyè sáwọn ànímọ́ tó dáa tí wọ́n ní. Lẹ́yìn náà, kẹ́ ẹ wo bẹ́ ẹ ṣe lè láwọn ànímọ́ náà. Ó ṣe pàtàkì pé káwa Kristẹni nírẹ̀lẹ̀. Tí obìnrin kan bá nírẹ̀lẹ̀, ó máa ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Jèhófà àtàwọn èèyàn. Bí àpẹẹrẹ, tí obìnrin kan bá nífẹ̀ẹ́ Jèhófà, ìrẹ̀lẹ̀ máa jẹ́ kó tẹ̀ lé ìlànà Jèhófà tó sọ pé orí obìnrin ni ọkùnrin. (1 Kọ́r. 11:3) A lè lo ìlànà yìí nínú ìjọ àti nínú ìdílé. w23.12 18-19 ¶3-5

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́