Tuesday, August 19
Jèhófà yóò fún àwọn èèyàn rẹ̀ ní agbára. Jèhófà yóò fi àlàáfíà jíǹkí àwọn èèyàn rẹ̀.—Sm. 29:11.
Tó o bá ń gbàdúrà, wò ó bóyá àsìkò ti tó lójú Jèhófà láti dáhùn àdúrà ẹ. Ó lè máa ṣe wá bíi pé kí Jèhófà dáhùn àdúrà wa lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀. Àmọ́, òótọ́ ibẹ̀ ni pé Jèhófà mọ àsìkò tó dáa jù láti dáhùn àdúrà wa. (Héb. 4:16) Tá ò bá tètè rí ìdáhùn àdúrà wa, a lè rò pé Jèhófà ò dáhùn àdúrà wa. Àmọ́, ó lè jẹ́ pé kò tíì tó àsìkò lójú ẹ̀ ni. Bí àpẹẹrẹ, arákùnrin ọ̀dọ́ kan lè bẹ Jèhófà pé kó wo òun sàn. Àmọ́ Jèhófà ò ṣe bẹ́ẹ̀. Ká sọ pé Jèhófà wò ó sàn lọ́nà ìyanu ni, Sátánì lè sọ pé torí pé Jèhófà wò ó sàn ló ṣe ń sin Jèhófà. (Jóòbù 1:9-11; 2:4) Yàtọ̀ síyẹn, Jèhófà ti mọ ìgbà tó máa mú gbogbo àìsàn kúrò pátápátá. (Àìsá. 33:24; Ìfi. 21:3, 4) Àmọ́ kó tó dìgbà yẹn, a ò lè retí pé gbogbo ìgbà ni Jèhófà máa wò wá sàn lọ́nà ìyanu. Torí náà, arákùnrin yẹn lè bẹ Jèhófà pé kó fún òun lókun, kó sì jẹ́ kọ́kàn òun balẹ̀ kóun lè máa fara da àìsàn náà, kóun sì máa sin Jèhófà tọkàntọkàn. w23.11 23 ¶13
Wednesday, August 20
Kò fi àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa hùwà sí wa, kò sì fi ìyà tó yẹ àṣìṣe wa jẹ wá.—Sm. 103:10.
Bó tiẹ̀ jẹ́ pé Sámúsìn ṣe àṣìṣe ńlá, síbẹ̀ kò jẹ́ kó sú òun láti máa sin Jèhófà. Ó lo àǹfààní tó ní láti ṣe iṣẹ́ tí Jèhófà gbé fún un, ìyẹn ni pé kó gbéjà ko àwọn Filísínì. (Oníd. 16:28-30) Sámúsìn bẹ Jèhófà pé kó jẹ́ kóun ‘gbẹ̀san lára àwọn Filísínì.’ Ọlọ́run tòótọ́ dáhùn àdúrà Sámúsìn, ó sì fún un lágbára lọ́nà ìyanu. Àwọn Filísínì tí Sámúsìn pa lọ́tẹ̀ yìí pọ̀ gan-an ju àwọn tó pa tẹ́lẹ̀ lọ. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé Sámúsìn jìyà àbájáde àṣìṣe tó ṣe, kò ṣíwọ́ láti máa sin Jèhófà. Torí náà tá a bá ṣàṣìṣe, tí wọ́n sì bá wa wí tàbí tá a pàdánù àǹfààní iṣẹ́ ìsìn tá a ní, a ò gbọ́dọ̀ jẹ́ kó sú wa láti máa sin Jèhófà nìṣó. Máa rántí pé Jèhófà kì í jẹ́ kọ́rọ̀ wa sú òun. (Sm. 103:8, 9) Torí náà, tá a bá tiẹ̀ ṣe àwọn àṣìṣe kan, Jèhófà ṣì lè lò wá bó ṣe lo Sámúsìn. w23.09 6 ¶15-16
Thursday, August 21
Ìfaradà ń mú ìtẹ́wọ́gbà wá; ìtẹ́wọ́gbà sì ń mú ìrètí wá.—Róòmù 5:4.
Tó o bá nífaradà, Jèhófà máa tẹ́wọ́ gbà ẹ́. Àmọ́ kì í ṣe torí pé o níṣòro tàbí torí àdánwò tó dé bá ẹ ni Jèhófà ṣe tẹ́wọ́ gbà ẹ́. Ìwọ ni Ọlọ́run tẹ́wọ́ gbà, kì í ṣe àwọn ìṣòro ẹ. Torí pé o nífaradà ni inú Jèhófà ṣe ń dùn sí ẹ. Ṣéyẹn ò múnú ẹ dùn? (Sm. 5:12) Rántí pé Ábúráhámù fara da àwọn àdánwò tó dé bá a, Jèhófà sì tẹ́wọ́ gbà á. Jèhófà pè é ní olódodo, ó sì sọ ọ́ di ọ̀rẹ́ ẹ̀. (Jẹ́n. 15:6; Róòmù 4:13, 22) Ọlọ́run lè ṣe bẹ́ẹ̀ fún àwa náà. Kì í ṣe irú iṣẹ́ tá à ń ṣe nínú ìjọsìn Ọlọ́run tàbí bí iṣẹ́ tá à ń ṣe ṣe pọ̀ tó ni Ọlọ́run máa fi tẹ́wọ́ gbà wá. Ohun tó ń múnú Jèhófà dùn sí wa ni pé a jẹ́ olóòótọ́, a sì nífaradà. Láìka ọjọ́ orí wa, ohun tí agbára wa gbé tàbí ipò wa sí, gbogbo wa la lè nífaradà. Ṣé àdánwò kan wà tó ò ń fara dà lọ́wọ́lọ́wọ́? Tó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, máa rántí pé inú Ọlọ́run ń dùn sí ẹ, kó o sì jẹ́ kíyẹn máa mára tù ẹ́. Bá a ṣe mọ̀ pé Ọlọ́run tẹ́wọ́ gbà wá ń fi wá lọ́kàn balẹ̀, ó sì jẹ́ kó túbọ̀ dá wa lójú pé ọwọ́ wa máa tẹ àwọn ohun rere lọ́jọ́ iwájú. w23.12 11 ¶13-14