Thursday, August 21
Ìfaradà ń mú ìtẹ́wọ́gbà wá; ìtẹ́wọ́gbà sì ń mú ìrètí wá.—Róòmù 5:4.
Tó o bá nífaradà, Jèhófà máa tẹ́wọ́ gbà ẹ́. Àmọ́ kì í ṣe torí pé o níṣòro tàbí torí àdánwò tó dé bá ẹ ni Jèhófà ṣe tẹ́wọ́ gbà ẹ́. Ìwọ ni Ọlọ́run tẹ́wọ́ gbà, kì í ṣe àwọn ìṣòro ẹ. Torí pé o nífaradà ni inú Jèhófà ṣe ń dùn sí ẹ. Ṣéyẹn ò múnú ẹ dùn? (Sm. 5:12) Rántí pé Ábúráhámù fara da àwọn àdánwò tó dé bá a, Jèhófà sì tẹ́wọ́ gbà á. Jèhófà pè é ní olódodo, ó sì sọ ọ́ di ọ̀rẹ́ ẹ̀. (Jẹ́n. 15:6; Róòmù 4:13, 22) Ọlọ́run lè ṣe bẹ́ẹ̀ fún àwa náà. Kì í ṣe irú iṣẹ́ tá à ń ṣe nínú ìjọsìn Ọlọ́run tàbí bí iṣẹ́ tá à ń ṣe ṣe pọ̀ tó ni Ọlọ́run máa fi tẹ́wọ́ gbà wá. Ohun tó ń múnú Jèhófà dùn sí wa ni pé a jẹ́ olóòótọ́, a sì nífaradà. Láìka ọjọ́ orí wa, ohun tí agbára wa gbé tàbí ipò wa sí, gbogbo wa la lè nífaradà. Ṣé àdánwò kan wà tó ò ń fara dà lọ́wọ́lọ́wọ́? Tó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, máa rántí pé inú Ọlọ́run ń dùn sí ẹ, kó o sì jẹ́ kíyẹn máa mára tù ẹ́. Bá a ṣe mọ̀ pé Ọlọ́run tẹ́wọ́ gbà wá ń fi wá lọ́kàn balẹ̀, ó sì jẹ́ kó túbọ̀ dá wa lójú pé ọwọ́ wa máa tẹ àwọn ohun rere lọ́jọ́ iwájú. w23.12 11 ¶13-14
Friday, August 22
Ṣe bí ọkùnrin.—1 Ọba 2:2.
Arákùnrin kan gbọ́dọ̀ kọ́ béèyàn ṣe ń báni sọ̀rọ̀. Ó gbọ́dọ̀ mọ bá a ṣe ń tẹ́tí sílẹ̀ dáadáa, kó sì mọ bí nǹkan ṣe ń rí lára àwọn ẹlòmíì. (Òwe 20:5) Ó yẹ kó máa kíyè sí ohùn tẹ́nì kan fi sọ̀rọ̀, bó ṣe ṣojú àti ìṣesí ẹ̀. O ò lè kíyè sí àwọn nǹkan yìí tó ò bá kí í bá àwọn èèyàn sọ̀rọ̀ lójúkojú. Tó bá jẹ́ gbogbo ìgbà lò ń fi fóònù bá àwọn èèyàn sọ̀rọ̀, tó o sì ń lò ó láti fọ̀rọ̀ ránṣẹ́, ó máa nira fún ẹ láti bá àwọn èèyàn sọ̀rọ̀ lójúkojú. Torí náà, máa wáyè bá àwọn èèyàn sọ̀rọ̀ lójúkojú. (2 Jòh. 12) Ọkùnrin Kristẹni tí òtítọ́ jinlẹ̀ nínú ẹ̀ gbọ́dọ̀ lè bójú tó ara ẹ̀ àti ìdílé ẹ̀. (1 Tím. 5:8) Ohun tó dáa jù ni pé kó o kọ́ṣẹ́ táá jẹ́ kó o máa ríṣẹ́ ṣe. (Ìṣe 18:2, 3; 20:34; Éfé. 4:28) Jẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ pé òṣìṣẹ́ kára ni ẹ́, tó o bá sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ kan, o máa ń parí ẹ̀. Tó o bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, ó ṣeé ṣe kó o ríṣẹ́, kó má sì bọ́ mọ́ ẹ lọ́wọ́. w23.12 27 ¶12-13
Saturday, August 23
Ọjọ́ Jèhófà ń bọ̀ bí olè ní òru.—1 Tẹs. 5:2.
Nígbà tí Bíbélì ń sọ̀rọ̀ nípa “ọjọ́ Jèhófà,” ohun tó ń sọ ni ìgbà tó máa pa àwọn ọ̀tá ẹ̀ run, tó sì máa gba àwọn èèyàn ẹ̀ là. Nígbà àtijọ́, Jèhófà fìyà jẹ àwọn orílẹ̀-èdè kan. (Àìsá. 13:1, 6; Ìsík. 13:5; Sef. 1:8) Lákòókò tiwa yìí, “ọjọ́ Jèhófà” máa bẹ̀rẹ̀ nígbà táwọn alákòóso ayé bá pa Bábílónì Ńlá run, ó sì máa parí nígbà ogun Amágẹ́dọ́nì. Tá ò bá fẹ́ wà lára àwọn tó máa pa run lọ́jọ́ yẹn, ó yẹ ká bẹ̀rẹ̀ sí í múra sílẹ̀ báyìí. Jésù kọ́ wa pé kì í ṣe ká kàn máa retí ìgbà tí “ìpọ́njú ńlá” máa bẹ̀rẹ̀, ó tún yẹ ká máa “múra sílẹ̀” de ọjọ́ yẹn. (Mát. 24:21; Lúùkù 12:40) Nínú lẹ́tà àkọ́kọ́ tí ẹ̀mí Ọlọ́run darí Pọ́ọ̀lù láti kọ sáwọn ará Tẹsalóníkà, ó lo ọ̀pọ̀ àpèjúwe láti jẹ́ kí wọ́n mọ bí wọ́n ṣe máa múra sílẹ̀ de ọjọ́ ìdájọ́ Jèhófà. Pọ́ọ̀lù mọ̀ pé àkókò yẹn kọ́ ni ọjọ́ Jèhófà máa dé. (2 Tẹs. 2:1-3) Síbẹ̀, ó gba àwọn ará yẹn níyànjú pé kí wọ́n máa múra sílẹ̀ bíi pé ọ̀la ló máa dé, ó sì yẹ káwa náà fi ìmọ̀ràn yẹn sílò lónìí. w23.06 8 ¶1-2