Friday, August 22
Ṣe bí ọkùnrin.—1 Ọba 2:2.
Arákùnrin kan gbọ́dọ̀ kọ́ béèyàn ṣe ń báni sọ̀rọ̀. Ó gbọ́dọ̀ mọ bá a ṣe ń tẹ́tí sílẹ̀ dáadáa, kó sì mọ bí nǹkan ṣe ń rí lára àwọn ẹlòmíì. (Òwe 20:5) Ó yẹ kó máa kíyè sí ohùn tẹ́nì kan fi sọ̀rọ̀, bó ṣe ṣojú àti ìṣesí ẹ̀. O ò lè kíyè sí àwọn nǹkan yìí tó ò bá kí í bá àwọn èèyàn sọ̀rọ̀ lójúkojú. Tó bá jẹ́ gbogbo ìgbà lò ń fi fóònù bá àwọn èèyàn sọ̀rọ̀, tó o sì ń lò ó láti fọ̀rọ̀ ránṣẹ́, ó máa nira fún ẹ láti bá àwọn èèyàn sọ̀rọ̀ lójúkojú. Torí náà, máa wáyè bá àwọn èèyàn sọ̀rọ̀ lójúkojú. (2 Jòh. 12) Ọkùnrin Kristẹni tí òtítọ́ jinlẹ̀ nínú ẹ̀ gbọ́dọ̀ lè bójú tó ara ẹ̀ àti ìdílé ẹ̀. (1 Tím. 5:8) Ohun tó dáa jù ni pé kó o kọ́ṣẹ́ táá jẹ́ kó o máa ríṣẹ́ ṣe. (Ìṣe 18:2, 3; 20:34; Éfé. 4:28) Jẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ pé òṣìṣẹ́ kára ni ẹ́, tó o bá sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ kan, o máa ń parí ẹ̀. Tó o bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, ó ṣeé ṣe kó o ríṣẹ́, kó má sì bọ́ mọ́ ẹ lọ́wọ́. w23.12 27 ¶12-13
Saturday, August 23
Ọjọ́ Jèhófà ń bọ̀ bí olè ní òru.—1 Tẹs. 5:2.
Nígbà tí Bíbélì ń sọ̀rọ̀ nípa “ọjọ́ Jèhófà,” ohun tó ń sọ ni ìgbà tó máa pa àwọn ọ̀tá ẹ̀ run, tó sì máa gba àwọn èèyàn ẹ̀ là. Nígbà àtijọ́, Jèhófà fìyà jẹ àwọn orílẹ̀-èdè kan. (Àìsá. 13:1, 6; Ìsík. 13:5; Sef. 1:8) Lákòókò tiwa yìí, “ọjọ́ Jèhófà” máa bẹ̀rẹ̀ nígbà táwọn alákòóso ayé bá pa Bábílónì Ńlá run, ó sì máa parí nígbà ogun Amágẹ́dọ́nì. Tá ò bá fẹ́ wà lára àwọn tó máa pa run lọ́jọ́ yẹn, ó yẹ ká bẹ̀rẹ̀ sí í múra sílẹ̀ báyìí. Jésù kọ́ wa pé kì í ṣe ká kàn máa retí ìgbà tí “ìpọ́njú ńlá” máa bẹ̀rẹ̀, ó tún yẹ ká máa “múra sílẹ̀” de ọjọ́ yẹn. (Mát. 24:21; Lúùkù 12:40) Nínú lẹ́tà àkọ́kọ́ tí ẹ̀mí Ọlọ́run darí Pọ́ọ̀lù láti kọ sáwọn ará Tẹsalóníkà, ó lo ọ̀pọ̀ àpèjúwe láti jẹ́ kí wọ́n mọ bí wọ́n ṣe máa múra sílẹ̀ de ọjọ́ ìdájọ́ Jèhófà. Pọ́ọ̀lù mọ̀ pé àkókò yẹn kọ́ ni ọjọ́ Jèhófà máa dé. (2 Tẹs. 2:1-3) Síbẹ̀, ó gba àwọn ará yẹn níyànjú pé kí wọ́n máa múra sílẹ̀ bíi pé ọ̀la ló máa dé, ó sì yẹ káwa náà fi ìmọ̀ràn yẹn sílò lónìí. w23.06 8 ¶1-2
Sunday, August 24
Ẹ̀yin ará mi ọ̀wọ́n, ẹ dúró gbọn-in, ẹ má yẹsẹ̀.—1 Kọ́r. 15:58.
Lọ́dún 1978, wọ́n kọ́ ilé tó ní ọgọ́ta (60) àjà sílùú Tokyo, lórílẹ̀-èdè Japan, òun sì ni ilé tó ga jù nílùú yẹn. Àmọ́, nítorí ìmìtìtì ilẹ̀ tó máa ń ṣẹlẹ̀ nílùú yẹn, àwọn èèyàn rò pé ilé náà máa wó. Báwo ni wọ́n ṣe kọ́ ilé náà tí kò fi wó nígbà tí ìmìtìtì ilẹ̀ ṣẹlẹ̀? Àwọn tó kọ́ ilé náà ṣe ìpìlẹ̀ ẹ̀ lọ́nà tó dúró digbí, ó sì lè fì sọ́tùn-ún fì sósì débi pé tí ìmìtìtì ilẹ̀ bá ṣẹlẹ̀ ilé náà ò ní wó. Àwa Kristẹni náà dà bí ilé gogoro yẹn. Lọ́nà wo? Àwa Kristẹni gbọ́dọ̀ dúró gbọin-in, a ò sì gbọ́dọ̀ fọwọ́ tó le jù mú nǹkan. Ó yẹ ká jẹ́ adúróṣinṣin tó bá dọ̀rọ̀ ká tẹ̀ lé òfin àtàwọn ìlànà Jèhófà. Ó tún yẹ ká “ṣe tán láti ṣègbọràn,” ká má sì yí ìpinnu wa pa dà. Àmọ́ ṣá o, ó yẹ ká jẹ́ ẹni tó ń “fòye báni lò” tàbí ẹni tó máa ń gba tàwọn ẹlòmíì rò tá a bá rí ibi tó yẹ ká ti ṣe bẹ́ẹ̀. (Jém. 3:17) Tí Kristẹni kan bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, kò ní jẹ́ ẹni tó ń fọwọ́ tó le jù mú nǹkan, kò sì ní jẹ́ ẹni tó ń fọwọ́ yẹpẹrẹ mú nǹkan. w23.07 14 ¶1-2