Friday, August 8
Ẹni tó ń rìn nínú ìdúróṣinṣin ń bẹ̀rù Jèhófà.—Òwe 14:2.
Tá a bá wo bí ìwàkiwà ṣe kún inú ayé lónìí, ó dájú pé bí nǹkan ṣe rí lára Lọ́ọ̀tì náà ló rí lára wa. Bíbélì sọ pé ó “banú jẹ́ gidigidi nítorí ìwà àìnítìjú àwọn arúfin èèyàn” torí ó mọ̀ pé Baba wa ọ̀run kórìíra ìwà burúkú. (2 Pét. 2:7, 8) Kí nìdí tí Lọ́ọ̀tì fi kórìíra ìwà burúkú ìgbà ayé ẹ̀? Ìdí ni pé ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ó sì nífẹ̀ẹ́ ẹ̀. Bákan náà lónìí, ìwà burúkú ló gba ayé kan torí pé àwọn èèyàn ò bẹ̀rù Ọlọ́run. Bó ti wù kó rí, àwa Kristẹni ṣì lè jẹ́ oníwà mímọ́ tá a bá nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run, tá a sì ń bẹ̀rù ẹ̀ tọkàntọkàn. Kíyẹn lè ṣeé ṣe, Jèhófà jẹ́ kí wọ́n kọ àwọn ohun tó yẹ ká ṣe àtàwọn ohun tí ò yẹ ká ṣe sínú ìwé Òwe, ó sì rọ̀ wá pé ká máa ṣe ohun tó tọ́. Torí náà, gbogbo àwa Kristẹni pátápátá lọ́mọdé lágbà, lọ́kùnrin àti lóbìnrin la máa jàǹfààní tá a bá ń fi ìmọ̀ràn inú ẹ̀ sílò. Tá a bá bẹ̀rù Jèhófà lóòótọ́, kò yẹ ká máa kẹ́gbẹ́ pẹ̀lú àwọn tó ń hùwàkiwà. w23.06 20 ¶1-2; 21 ¶5
Saturday, August 9
Tí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ máa tẹ̀ lé mi, kó sẹ́ ara rẹ̀, kó máa gbé òpó igi oró rẹ̀ lójoojúmọ́, kó sì máa tẹ̀ lé mi.—Lúùkù 9:23.
Ó ṣeé ṣe káwọn ìdílé ẹ máa ṣenúnibíni sí ẹ, o sì ti lè yááfì àwọn ohun ìní tara kan kó o lè fi Ìjọba Ọlọ́run sípò àkọ́kọ́. (Mát. 6:33) Tó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, jẹ́ kó dá ẹ lójú pé Jèhófà mọ gbogbo nǹkan tó ò ń ṣe torí ìjọsìn ẹ̀. (Héb. 6:10) Ó ṣeé ṣe kíwọ náà ti rí i pé òótọ́ pọ́ńbélé ni Jésù sọ nígbà tó sọ pé: “Kò sí ẹni tó fi ilé tàbí àwọn arákùnrin, àwọn arábìnrin, ìyá, bàbá, àwọn ọmọ tàbí àwọn pápá sílẹ̀ nítorí mi àti nítorí ìhìn rere, tí kò ní gba ìlọ́po ọgọ́rùn-ún (100) àwọn ilé, àwọn arákùnrin, àwọn arábìnrin, àwọn ìyá, àwọn ọmọ àti àwọn pápá, pẹ̀lú àwọn inúnibíni ní báyìí àti ìyè àìnípẹ̀kun nínú ètò àwọn nǹkan tó ń bọ̀.” (Máàkù 10:29, 30) Kò sí àní-àní pé àwọn ìbùkún tó o ti rí gbà pọ̀ gan-an ju ohunkóhun tó o yááfì lọ.—Sm. 37:4. w24.03 9 ¶5
Sunday, August 10
Ọ̀rẹ́ tòótọ́ máa ń nífẹ̀ẹ́ ẹni nígbà gbogbo, ó sì jẹ́ ọmọ ìyá tí a bí fún ìgbà wàhálà.—Òwe 17:17.
Nígbà tí ìyàn ńlá mú àwọn ará ní Jùdíà, àwọn ará tó wà ní ìjọ Áńtíókù ti Síríà gbọ́ nípa ìyàn náà. Torí náà, wọ́n “pinnu, gẹ́gẹ́ bí ohun tí agbára kálukú wọn gbé, láti fi nǹkan ìrànwọ́ ránṣẹ́ sí àwọn ará tó ń gbé ní Jùdíà.” (Ìṣe 11:27-30) Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ibi táwọn ará tí ìyàn náà mú ń gbé jìnnà gan-an, àwọn ará tó wà ní Áńtíókù pinnu pé àwọn gbọ́dọ̀ ràn wọ́n lọ́wọ́. (1 Jòh. 3:17, 18) Àwa náà lè fàánú hàn sáwọn ará wa lónìí tá a bá gbọ́ pé àjálù ṣẹlẹ̀ sí wọn. Bá a ṣe lè fi hàn pé à ń káàánú àwọn ará wa ni pé tí àjálù bá ṣẹlẹ̀ sí wọn, ká tètè béèrè lọ́wọ́ àwọn alàgbà bóyá a lè yọ̀ǹda ara wa láti ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn tó ń ṣèrànwọ́ nígbà àjálù. Yàtọ̀ síyẹn, a lè fowó ṣètìlẹyìn fún iṣẹ́ kárí ayé tàbí ká gbàdúrà fáwọn tí àjálù dé bá. Ó tún lè pọn dandan pé ká ran àwọn ará wa lọ́wọ́ kí wọ́n lè rí oúnjẹ àtàwọn nǹkan míì tí wọ́n nílò. Torí náà, tí Jésù Kristi Ọba wa bá dé láti ṣèdájọ́ ayé burúkú yìí, ó máa rí i pé à ń fàánú hàn sáwọn èèyàn, á sì pè wá pé ká wá “jogún Ìjọba” náà.—Mát. 25:34-40. w23.07 4 ¶9-10; 6 ¶12