Saturday, August 9
Tí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ máa tẹ̀ lé mi, kó sẹ́ ara rẹ̀, kó máa gbé òpó igi oró rẹ̀ lójoojúmọ́, kó sì máa tẹ̀ lé mi.—Lúùkù 9:23.
Ó ṣeé ṣe káwọn ìdílé ẹ máa ṣenúnibíni sí ẹ, o sì ti lè yááfì àwọn ohun ìní tara kan kó o lè fi Ìjọba Ọlọ́run sípò àkọ́kọ́. (Mát. 6:33) Tó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, jẹ́ kó dá ẹ lójú pé Jèhófà mọ gbogbo nǹkan tó ò ń ṣe torí ìjọsìn ẹ̀. (Héb. 6:10) Ó ṣeé ṣe kíwọ náà ti rí i pé òótọ́ pọ́ńbélé ni Jésù sọ nígbà tó sọ pé: “Kò sí ẹni tó fi ilé tàbí àwọn arákùnrin, àwọn arábìnrin, ìyá, bàbá, àwọn ọmọ tàbí àwọn pápá sílẹ̀ nítorí mi àti nítorí ìhìn rere, tí kò ní gba ìlọ́po ọgọ́rùn-ún (100) àwọn ilé, àwọn arákùnrin, àwọn arábìnrin, àwọn ìyá, àwọn ọmọ àti àwọn pápá, pẹ̀lú àwọn inúnibíni ní báyìí àti ìyè àìnípẹ̀kun nínú ètò àwọn nǹkan tó ń bọ̀.” (Máàkù 10:29, 30) Kò sí àní-àní pé àwọn ìbùkún tó o ti rí gbà pọ̀ gan-an ju ohunkóhun tó o yááfì lọ.—Sm. 37:4. w24.03 9 ¶5
Sunday, August 10
Ọ̀rẹ́ tòótọ́ máa ń nífẹ̀ẹ́ ẹni nígbà gbogbo, ó sì jẹ́ ọmọ ìyá tí a bí fún ìgbà wàhálà.—Òwe 17:17.
Nígbà tí ìyàn ńlá mú àwọn ará ní Jùdíà, àwọn ará tó wà ní ìjọ Áńtíókù ti Síríà gbọ́ nípa ìyàn náà. Torí náà, wọ́n “pinnu, gẹ́gẹ́ bí ohun tí agbára kálukú wọn gbé, láti fi nǹkan ìrànwọ́ ránṣẹ́ sí àwọn ará tó ń gbé ní Jùdíà.” (Ìṣe 11:27-30) Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ibi táwọn ará tí ìyàn náà mú ń gbé jìnnà gan-an, àwọn ará tó wà ní Áńtíókù pinnu pé àwọn gbọ́dọ̀ ràn wọ́n lọ́wọ́. (1 Jòh. 3:17, 18) Àwa náà lè fàánú hàn sáwọn ará wa lónìí tá a bá gbọ́ pé àjálù ṣẹlẹ̀ sí wọn. Bá a ṣe lè fi hàn pé à ń káàánú àwọn ará wa ni pé tí àjálù bá ṣẹlẹ̀ sí wọn, ká tètè béèrè lọ́wọ́ àwọn alàgbà bóyá a lè yọ̀ǹda ara wa láti ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn tó ń ṣèrànwọ́ nígbà àjálù. Yàtọ̀ síyẹn, a lè fowó ṣètìlẹyìn fún iṣẹ́ kárí ayé tàbí ká gbàdúrà fáwọn tí àjálù dé bá. Ó tún lè pọn dandan pé ká ran àwọn ará wa lọ́wọ́ kí wọ́n lè rí oúnjẹ àtàwọn nǹkan míì tí wọ́n nílò. Torí náà, tí Jésù Kristi Ọba wa bá dé láti ṣèdájọ́ ayé burúkú yìí, ó máa rí i pé à ń fàánú hàn sáwọn èèyàn, á sì pè wá pé ká wá “jogún Ìjọba” náà.—Mát. 25:34-40. w23.07 4 ¶9-10; 6 ¶12
Monday, August 11
Ẹ jẹ́ kí gbogbo èèyàn rí i pé ẹ̀ ń fòye báni lò.—Fílí. 4:5.
Jésù máa ń fòye báni lò bíi ti Jèhófà. Jèhófà rán an wá sáyé kó lè wàásù fún “àwọn àgùntàn ilé Ísírẹ́lì tó sọ nù.” Síbẹ̀, ó máa ń fòye báni lò bó ṣe ń wàásù fáwọn èèyàn. Nígbà kan, obìnrin kan tí kì í ṣe ọmọ Ísírẹ́lì bẹ̀ ẹ́ pé kó wo ọmọbìnrin òun sàn torí pé ‘ẹ̀mí èṣù ń yọ ọ́ lẹ́nu gidigidi.’ Àánú obìnrin yẹn ṣe Jésù, ó ṣe ohun tó sọ, ó sì wo ọmọbìnrin ẹ̀ sàn. (Mát. 15:21-28) Ẹ jẹ́ ká tún wo àpẹẹrẹ míì. Lẹ́yìn tí Jésù bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀, ó sọ pé: “Ẹnikẹ́ni tó bá sẹ́ mi . . . , èmi náà máa sẹ́ ẹ.” (Mát. 10:33) Àmọ́ nígbà tí Pétérù sẹ́ ẹ lẹ́ẹ̀mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, ṣé ó pa á tì? Rárá. Jésù mọ̀ pé Pétérù kábàámọ̀ ohun tó ṣe, olóòótọ́ sì ni. Lẹ́yìn tí Jésù jíǹde, ó fara han Pétérù, ó sì ṣeé ṣe kó fi dá a lójú pé òun ti dárí jì í àti pé òun ṣì nífẹ̀ẹ́ ẹ̀. (Lúùkù 24:33, 34) Jèhófà àti Jésù Kristi máa ń fòye báni lò. Àwa ńkọ́? Jèhófà fẹ́ káwa náà máa fòye báni lò. w23.07 21 ¶6-7