18 Bí ẹ̀mí rẹ̀ ṣe ń bọ́ lọ* (torí ó ń kú lọ), ó sọ ọmọ náà ní Bẹni-ónì,* àmọ́ bàbá rẹ̀ sọ ọ́ ní Bẹ́ńjámínì.*+19 Réṣẹ́lì wá kú, wọ́n sì sin ín ní ojú ọ̀nà Éfúrátì, ìyẹn Bẹ́tílẹ́hẹ́mù.+
38 Àmọ́ ó sọ pé: “Ọmọ mi ò ní bá yín lọ, torí ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan ló sì ṣẹ́ kù.+ Bí jàǹbá bá lọ ṣe é ní ìrìn àjò tí ẹ fẹ́ lọ yìí, ó dájú pé ẹ ó mú kí n ṣọ̀fọ̀+ wọnú Isà Òkú*+ pẹ̀lú ewú orí mi.”
20 A sì sọ fún ọ̀gá mi pé, ‘A ní bàbá tó ti darúgbó, ó sì bí ọmọ kan ní ọjọ́ ogbó rẹ̀, òun ló kéré jù.+ Àmọ́ ẹ̀gbọ́n ọmọ náà ti kú,+ torí náà, òun ló ṣẹ́ kù nínú àwọn ọmọ ìyá+ rẹ̀, bàbá rẹ̀ sì nífẹ̀ẹ́ rẹ̀.’