ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ẹ́kísódù 7:5
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 5 Ó sì dájú pé àwọn ará Íjíbítì yóò mọ̀ pé èmi ni Jèhófà+ nígbà tí mo bá na ọwọ́ mi láti bá Íjíbítì jà, tí mo sì mú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì kúrò láàárín wọn.”

  • Ẹ́kísódù 7:17
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 17 Ohun tí Jèhófà sọ nìyí: “Ohun tí wàá fi mọ̀ pé èmi ni Jèhófà+ nìyí. Màá fi ọ̀pá ọwọ́ mi lu omi odò Náílì, á sì di ẹ̀jẹ̀.

  • Ẹ́kísódù 8:9, 10
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 9 Mósè sọ fún Fáráò pé: “Mo fún ọ láǹfààní láti sọ ìgbà tí o fẹ́ kí n bẹ̀bẹ̀ pé kí àwọn àkèré náà kúrò lọ́dọ̀ rẹ, ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn èèyàn rẹ àti nínú àwọn ilé rẹ. Inú odò Náílì nìkan ni wọ́n á ṣẹ́ kù sí.” 10 Ó fèsì pé: “Ní ọ̀la.” Ó wá sọ pé: “Bí o ṣe sọ ló máa rí, kí o lè mọ̀ pé kò sẹ́ni tó dà bíi Jèhófà Ọlọ́run wa.+

  • Ẹ́kísódù 8:22
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 22 Ní ọjọ́ yẹn, ó dájú pé màá ya ilẹ̀ Góṣénì sọ́tọ̀, níbi tí àwọn èèyàn mi ń gbé. Eṣinṣin mùjẹ̀mùjẹ̀ kankan ò ní sí níbẹ̀;+ èyí á sì jẹ́ kí o mọ̀ pé èmi Jèhófà wà ní ilẹ̀ yìí.+

  • Ẹ́kísódù 14:4
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 4 Màá jẹ́ kí ọkàn Fáráò le,+ ó máa lépa wọn, màá sì ṣe ara mi lógo nípasẹ̀ Fáráò àti gbogbo ọmọ ogun rẹ̀.+ Ó dájú pé àwọn ará Íjíbítì yóò mọ̀ pé èmi ni Jèhófà.”+ Ohun tí wọ́n sì ṣe nìyẹn.

  • Diutarónómì 10:14
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 14 Wò ó, Jèhófà Ọlọ́run rẹ ló ni ọ̀run, àní ọ̀run àwọn ọ̀run,* pẹ̀lú ayé àti gbogbo ohun tó wà nínú rẹ̀.+

  • Sáàmù 24:1
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 24 Jèhófà ló ni ayé àti gbogbo ohun tó wà nínú rẹ̀,+

      Ilẹ̀ tó ń méso jáde àti àwọn tó ń gbé orí rẹ̀.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́