ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ẹ́kísódù 40:21
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 21 Ó gbé Àpótí náà wá sínú àgọ́ ìjọsìn, ó sì ta aṣọ ìdábùú+ bo ibẹ̀. Ó fi bo ibi tí àpótí Ẹ̀rí náà+ wà, bí Jèhófà ṣe pa á láṣẹ fún Mósè.

  • Léfítíkù 16:2
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 2 Jèhófà sọ fún Mósè pé: “Sọ fún Áárónì ẹ̀gbọ́n rẹ pé kó má kàn wá sínú ibi mímọ́+ tó wà lẹ́yìn aṣọ ìdábùú+ nígbàkigbà, níwájú ìbòrí Àpótí, kó má bàa kú,+ torí màá fara hàn nínú ìkùukùu*+ lórí ìbòrí+ náà.

  • 1 Àwọn Ọba 8:6
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 Nígbà náà, àwọn àlùfáà gbé àpótí májẹ̀mú Jèhófà wá sí àyè rẹ̀,+ ní yàrá inú lọ́hùn-ún ilé náà, ìyẹn Ibi Mímọ́ Jù Lọ, wọ́n gbé e sí abẹ́ ìyẹ́ apá àwọn kérúbù.+

  • Hébérù 9:2-4
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 2 Torí wọ́n kọ́ apá àkọ́kọ́ nínú àgọ́, níbi tí ọ̀pá fìtílà,+ tábìlì àti àwọn búrẹ́dì tí wọ́n ń gbé síwájú*+ wà; a sì ń pè é ní Ibi Mímọ́.+ 3 Àmọ́ lẹ́yìn aṣọ ìdábùú kejì,+ apá kan wà tí à ń pè ní Ibi Mímọ́ Jù Lọ.+ 4 Àwo tùràrí oníwúrà+ àti àpótí májẹ̀mú  + tí wọ́n fi wúrà bò látòkè délẹ̀+ wà níbẹ̀, inú rẹ̀ ni ìṣà wúrà tí wọ́n kó mánà+ sí wà pẹ̀lú ọ̀pá Áárónì tó yọ òdòdó+ àti àwọn wàláà+ májẹ̀mú;

  • Hébérù 9:12
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 12 Kì í ṣe ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́ àti ti àwọn akọ ọmọ màlúù ló gbé wọnú ibi mímọ́, àmọ́ ẹ̀jẹ̀ òun fúnra rẹ̀ ni,+ lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo láìtún ní ṣe é mọ́ láé, ó sì gba ìtúsílẹ̀* àìnípẹ̀kun fún wa.+

  • Hébérù 9:24
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 24 Torí Kristi ò wọnú ibi mímọ́ tí wọ́n fi ọwọ́ ṣe,+ tó jẹ́ àpẹẹrẹ ohun gidi,+ àmọ́ ọ̀run gangan ló wọ̀ lọ,+ tó fi jẹ́ pé ó ń fara hàn báyìí níwájú* Ọlọ́run nítorí wa.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́