-
Léfítíkù 21:10-12Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
10 “‘Ẹni tó jẹ́ àlùfáà àgbà nínú àwọn arákùnrin rẹ̀, tí wọ́n da òróró àfiyanni+ sí lórí, tí wọ́n sì ti fi iṣẹ́ lé lọ́wọ́* kó lè wọ aṣọ àlùfáà,+ kò gbọ́dọ̀ fi orí rẹ̀ sílẹ̀ láìtọ́jú tàbí kó ya aṣọ rẹ̀.+ 11 Kó má ṣe sún mọ́ òkú ẹnikẹ́ni;*+ tó bá tiẹ̀ jẹ́ bàbá rẹ̀ tàbí ìyá rẹ̀, kò gbọ́dọ̀ fi wọ́n sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́. 12 Kò gbọ́dọ̀ jáde kúrò nínú ibi mímọ́, kò sì gbọ́dọ̀ sọ ibi mímọ́ Ọlọ́run rẹ̀ di aláìmọ́,+ torí àmì ìyàsímímọ́, òróró àfiyanni ti Ọlọ́run rẹ̀,+ wà lórí rẹ̀. Èmi ni Jèhófà.
-