-
Nọ́ńbà 24:10Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
10 Inú wá bí Bálákì sí Báláámù gan-an. Bálákì wá fi ìbínú pàtẹ́wọ́, ó sì sọ fún Báláámù pé: “Torí kí o lè gégùn-ún fún àwọn ọ̀tá mi ni mo ṣe pè ọ́ + wá, àmọ́ ṣe lo kàn ń súre fún wọn lẹ́ẹ̀mẹta yìí.
-
-
Nehemáyà 13:1, 2Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
13 Ní ọjọ́ yẹn, wọ́n ka ìwé Mósè sétí àwọn èèyàn,+ wọ́n sì rí i pé ó wà lákọsílẹ̀ pé àwọn ọmọ Ámónì àti àwọn ọmọ Móábù+ kò gbọ́dọ̀ wá sínú ìjọ Ọlọ́run tòótọ́ láé,+ 2 nítorí wọn kò fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ní oúnjẹ àti omi, dípò bẹ́ẹ̀ ṣe ni wọ́n háyà Báláámù láti gégùn-ún fún wọn.+ Àmọ́, Ọlọ́run wa yí ègún náà pa dà sí ìbùkún.+
-