ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Kíróníkà 2:6
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 Ta ni agbára rẹ̀ gbé e láti kọ́ ilé fún un? Nítorí àwọn ọ̀run àti ọ̀run àwọn ọ̀run kò lè gbà á,+ ta wá ni mí tí màá fi kọ́ ilé fún un? Àfi kí n kàn kọ́ ọ gẹ́gẹ́ bí ibi tí a ó ti máa mú ẹbọ rú èéfín níwájú rẹ̀.

  • 2 Kíróníkà 6:18-21
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 18 “Àmọ́, ṣé Ọlọ́run á máa bá àwọn èèyàn gbé inú ayé ni?+ Wò ó! Àwọn ọ̀run, àní, ọ̀run àwọn ọ̀run, kò lè gbà ọ́;+ ká má ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sọ ti ilé tí mo kọ́ yìí!+ 19 Ní báyìí, Jèhófà Ọlọ́run mi, fiyè sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ̀ fún ojú rere, kí o sì fetí sí igbe ìránṣẹ́ rẹ fún ìrànlọ́wọ́ àti àdúrà tó ń gbà níwájú rẹ. 20 Kí ojú rẹ wà lára ilé yìí tọ̀sántòru, lára ibi tí o sọ pé wàá fi orúkọ rẹ sí,+ láti fetí sí àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní ìdojúkọ ibí yìí. 21 Kí o gbọ́ ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ fún ìrànlọ́wọ́ àti ẹ̀bẹ̀ àwọn èèyàn rẹ Ísírẹ́lì nígbà tí wọ́n bá gbàdúrà ní ìdojúkọ ibí yìí,+ kí o gbọ́ láti ibi tí ò ń gbé, láti ọ̀run;+ kí o gbọ́, kí o sì dárí jì wọ́n.+

  • Nehemáyà 9:6
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 “Ìwọ nìkan ṣoṣo ni Jèhófà;+ ìwọ lo dá ọ̀run, àní ọ̀run àwọn ọ̀run àti gbogbo ọmọ ogun wọn, ayé àti gbogbo ohun tó wà lórí rẹ̀, àwọn òkun àti gbogbo ohun tó wà nínú wọn. O pa gbogbo wọn mọ́, àwọn ọmọ ogun ọ̀run sì ń forí balẹ̀ fún ọ.

  • Ìṣe 17:24
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 24 Ọlọ́run tó dá ayé àti gbogbo ohun tó wà nínú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí òun fúnra rẹ̀ ṣe jẹ́ Olúwa ọ̀run àti ayé,+ kì í gbé inú àwọn tẹ́ńpìlì tí a fi ọwọ́ kọ́;+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́