-
1 Àwọn Ọba 8:27-30Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
27 “Àmọ́, ṣé Ọlọ́run máa gbé inú ayé ni?+ Wò ó! Àwọn ọ̀run, àní, ọ̀run àwọn ọ̀run, kò lè gbà ọ́;+ ká má ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sọ ti ilé tí mo kọ́ yìí!+ 28 Ní báyìí, Jèhófà Ọlọ́run mi, fiyè sí àdúrà ìránṣẹ́ rẹ àti ẹ̀bẹ̀ rẹ̀ fún ojú rere, kí o sì fetí sí igbe ìránṣẹ́ rẹ fún ìrànlọ́wọ́ àti àdúrà tó ń gbà níwájú rẹ lónìí. 29 Kí ojú rẹ wà lára ilé yìí tọ̀sántòru, lára ibi tí o sọ pé, ‘Orúkọ mi yóò wà níbẹ̀,’+ láti fetí sí àdúrà tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbà ní ìdojúkọ ibí yìí.+ 30 Kí o gbọ́ ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ fún ojú rere àti ẹ̀bẹ̀ àwọn èèyàn rẹ Ísírẹ́lì, tí wọ́n ń sọ nínú àdúrà ní ìdojúkọ ibí yìí; kí o gbọ́ láti ibi tí ò ń gbé ní ọ̀run;+ kí o gbọ́, kí o sì dárí jì wọ́n.+
-