ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Nọ́ńbà 9:14
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 14 “‘Tí àjèjì kan bá ń gbé lọ́dọ̀ yín, kí òun náà ṣètò ẹbọ Ìrékọjá fún Jèhófà.+ Kó tẹ̀ lé àṣẹ àti ìlànà tó wà fún Ìrékọjá láti ṣètò rẹ̀.+ Àṣẹ kan náà ni kí ẹ máa tẹ̀ lé, ì báà jẹ́ àjèjì tàbí ọmọ ìbílẹ̀.’”+

  • Rúùtù 1:16
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 16 Àmọ́ Rúùtù sọ pé: “Má rọ̀ mí pé kí n fi ọ́ sílẹ̀, pé kí n má ṣe bá ọ lọ; torí ibi tí o bá lọ ni èmi yóò lọ, ibi tí o bá sùn ni èmi yóò sùn. Àwọn èèyàn rẹ ni yóò jẹ́ èèyàn mi, Ọlọ́run rẹ ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run mi.+

  • 2 Àwọn Ọba 5:15
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 15 Lẹ́yìn náà, ó pa dà lọ sọ́dọ̀ èèyàn Ọlọ́run tòótọ́,+ òun pẹ̀lú gbogbo àwọn tó tẹ̀ lé e,* ó dúró níwájú rẹ̀, ó sì sọ pé: “Mo ti wá mọ̀ báyìí pé kò sí Ọlọ́run níbikíbi láyé, àfi ní Ísírẹ́lì.+ Jọ̀ọ́, gba ẹ̀bùn* yìí lọ́wọ́ ìránṣẹ́ rẹ.”

  • 2 Kíróníkà 6:32, 33
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 32 “Bákan náà, ní ti àjèjì tí kì í ṣe ara àwọn èèyàn rẹ Ísírẹ́lì, àmọ́ tó wá láti ilẹ̀ tó jìnnà nítorí orúkọ ńlá rẹ*+ àti ọwọ́ agbára rẹ pẹ̀lú apá rẹ tó nà jáde, tí ó sì wá gbàdúrà ní ìdojúkọ ilé yìí,+ 33 nígbà náà, kí o fetí sílẹ̀ láti ọ̀run, ibi tí ò ń gbé, kí o sì ṣe gbogbo ohun tí àjèjì náà béèrè lọ́wọ́ rẹ, kí gbogbo aráyé lè mọ orúkọ rẹ,+ kí wọ́n sì máa bẹ̀rù rẹ, bí àwọn èèyàn rẹ Ísírẹ́lì ti ń ṣe, kí wọ́n sì mọ̀ pé a ti fi orúkọ rẹ pe ilé tí mo kọ́ yìí.

  • Àìsáyà 56:6, 7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  6 Ní ti àwọn àjèjì tó fara mọ́ Jèhófà láti máa ṣe ìránṣẹ́ fún un,

      Láti nífẹ̀ẹ́ orúkọ Jèhófà,+

      Kí wọ́n sì di ìránṣẹ́ rẹ̀,

      Gbogbo àwọn tó ń pa Sábáàtì mọ́, tí wọn ò sì kẹ́gàn rẹ̀,

      Tí wọ́n ń rọ̀ mọ́ májẹ̀mú mi,

       7 Màá tún mú wọn wá sí òkè mímọ́ mi,+

      Màá sì mú kí wọ́n máa yọ̀ nínú ilé àdúrà mi.

      Màá tẹ́wọ́ gba odindi ẹbọ sísun wọn àtàwọn ẹbọ wọn lórí pẹpẹ mi.

      Torí a ó máa pe ilé mi ní ilé àdúrà fún gbogbo èèyàn.”+

  • Ìṣe 8:27
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 27 Ló bá dìde, ó lọ, sì wò ó! ìwẹ̀fà* ará Etiópíà kan, ọkùnrin tó wà nípò àṣẹ lábẹ́ Káńdésì ọbabìnrin àwọn ará Etiópíà, òun ló ń bójú tó gbogbo ìṣúra rẹ̀. Ó lọ jọ́sìn ní Jerúsálẹ́mù,+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́