ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jẹ́nẹ́sísì 12:6
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 Ábúrámù rin ilẹ̀ náà já títí dé ibi tí Ṣékémù+ wà, nítòsí àwọn igi ńlá tó wà ní Mórè.+ Àwọn ọmọ Kénáánì wà ní ilẹ̀ náà nígbà yẹn.

  • Jóṣúà 20:7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 7 Torí náà, wọ́n ya Kédéṣì+ ní Gálílì sọ́tọ̀* ní agbègbè olókè Náfútálì, Ṣékémù+ ní agbègbè olókè Éfúrémù àti Kiriati-ábà,+ ìyẹn Hébúrónì, ní agbègbè olókè Júdà.

  • Jóṣúà 20:9
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 9 Àwọn ìlú yìí ni wọ́n yàn fún gbogbo ọmọ Ísírẹ́lì àtàwọn àjèjì tó ń gbé láàárín wọn, kí ẹnikẹ́ni tó bá ṣèèṣì pa èèyàn* lè sá lọ síbẹ̀,+ kí ẹni tó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ má bàa pa á kí wọ́n tó gbọ́ ẹjọ́ rẹ̀ níwájú àpéjọ náà.+

  • Àwọn Onídàájọ́ 9:1, 2
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 9 Nígbà tó yá, Ábímélékì+ ọmọ Jerubáálì lọ sọ́dọ̀ àwọn arákùnrin ìyá rẹ̀ ní Ṣékémù, ó sì sọ fún àwọn àti gbogbo ìdílé bàbá rẹ̀ àgbà* pé: 2 “Ẹ jọ̀ọ́, ẹ bi gbogbo àwọn olórí* ní Ṣékémù pé, ‘Èwo ló dáa jù fún yín, pé kí gbogbo àádọ́rin (70) ọmọkùnrin Jerubáálì+ máa jọba lé yín lórí àbí kí ọkùnrin kan ṣoṣo máa jọba lé yín lórí? Ẹ má gbàgbé pé ẹ̀jẹ̀ kan náà ni wá.’”*

  • Ìṣe 7:15, 16
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 15 Jékọ́bù lọ sí Íjíbítì,+ ó sì kú síbẹ̀,+ ohun kan náà ló ṣẹlẹ̀ sí àwọn baba ńlá wa.+ 16 Wọ́n gbé wọn lọ sí Ṣékémù, wọ́n sì tẹ́ wọn sínú ibojì tí Ábúráhámù fi owó fàdákà rà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Hámórì ní Ṣékémù.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́