ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ẹ́sírà 2:2-35
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 2 àwọn tí wọ́n tẹ̀ lé ni Serubábélì,+ Jéṣúà,+ Nehemáyà, Seráyà, Reeláyà, Módékáì, Bílíṣánì, Mísípárì, Bígífáì, Réhúmù àti Báánà.

      Iye àwọn ọkùnrin tí wọ́n jẹ́ ọmọ Ísírẹ́lì nìyí:+ 3 àwọn ọmọ Páróṣì jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì ó lé méjìléláàádọ́sàn-án (2,172); 4 àwọn ọmọ Ṣẹfatáyà jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́ta ó lé méjìléláàádọ́rin (372); 5 àwọn ọmọ Áráhì+ jẹ́ ọgọ́rùn-ún méje ó lé márùndínlọ́gọ́rin (775); 6 àwọn ọmọ Pahati-móábù,+ látinú àwọn ọmọ Jéṣúà àti Jóábù jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì ó lé ọgọ́rùn-ún mẹ́jọ àti méjìlá (2,812); 7 àwọn ọmọ Élámù+ jẹ́ ẹgbẹ̀rún kan ó lé igba àti mẹ́rìnléláàádọ́ta (1,254); 8 àwọn ọmọ Sátù+ jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́sàn-án ó lé márùnlélógójì (945); 9 àwọn ọmọ Sákáì jẹ́ ọgọ́rùn-ún méje ó lé ọgọ́ta (760); 10 àwọn ọmọ Bánì jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́fà ó lé méjìlélógójì (642); 11 àwọn ọmọ Bébáì jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́fà ó lé mẹ́tàlélógún (623); 12 àwọn ọmọ Ásígádì jẹ́ ẹgbẹ̀rún kan ó lé igba àti méjìlélógún (1,222); 13 àwọn ọmọ Ádóníkámù jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́fà àti ọgọ́ta ó lé mẹ́fà (666); 14 àwọn ọmọ Bígífáì jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta (2,056); 15 àwọn ọmọ Ádínì jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́rin ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta (454); 16 àwọn ọmọ Átérì láti ilé Hẹsikáyà jẹ́ méjìdínlọ́gọ́rùn-ún (98); 17 àwọn ọmọ Bísáì jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́ta ó lé mẹ́tàlélógún (323); 18 àwọn ọmọ Jórà jẹ́ méjìléláàádọ́fà (112); 19 àwọn ọmọ Háṣúmù+ jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún (223); 20 àwọn ọmọ Gíbárì jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn-ún (95); 21 àwọn ọmọ Bẹ́tílẹ́hẹ́mù jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà (123); 22 àwọn ọkùnrin Nétófà jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta (56); 23 àwọn ọkùnrin Ánátótì+ jẹ́ méjìdínláàádóje (128); 24 àwọn ọmọ Ásímáfẹ́tì jẹ́ méjìlélógójì (42); 25 àwọn ọmọ Kiriati-jéárímù, Kéfírà àti Béérótì jẹ́ ọgọ́rùn-ún méje ó lé mẹ́tàlélógójì (743); 26 àwọn ọmọ Rámà+ àti Gébà+ jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́fà ó lé mọ́kànlélógún (621); 27 àwọn ọkùnrin Míkímásì jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà (122); 28 àwọn ọkùnrin Bẹ́tẹ́lì àti Áì+ jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún (223); 29 àwọn ọmọ Nébò+ jẹ́ méjìléláàádọ́ta (52); 30 àwọn ọmọ Mágíbíṣì jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ (156); 31 àwọn ọmọ Élámù kejì jẹ́ ẹgbẹ̀rún kan ó lé igba àti mẹ́rìnléláàádọ́ta (1,254); 32 àwọn ọmọ Hárímù jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́ta ó lé ogún (320); 33 àwọn ọmọ Lódì, Hádídì àti Ónò jẹ́ ọgọ́rùn-ún méje ó lé mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (725); 34 àwọn ọmọ Jẹ́ríkò jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́ta ó lé márùnlélógójì (345); 35 àwọn ọmọ Sénáà jẹ́ ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ó lé ọgọ́rùn-ún mẹ́fà àti ọgbọ̀n (3,630).

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́