ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 2 Àwọn Ọba 24:14, 15
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 14 Ó kó gbogbo Jerúsálẹ́mù lọ sí ìgbèkùn, gbogbo ìjòyè,+ gbogbo jagunjagun tó lákíkanjú àti gbogbo oníṣẹ́ ọnà pẹ̀lú gbogbo oníṣẹ́ irin,*+ ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá (10,000) èèyàn ló kó lọ sí ìgbèkùn. Kò ṣẹ́ ku ẹnì kankan àfi àwọn aláìní ní ilẹ̀ náà.+ 15 Bó ṣe mú Jèhóákínì+ lọ sí ìgbèkùn ní Bábílónì+ nìyẹn; ó tún mú ìyá ọba, àwọn ìyàwó ọba, àwọn òṣìṣẹ́ ààfin àti àwọn aṣáájú ilẹ̀ náà, ó sì kó wọn ní ìgbèkùn láti Jerúsálẹ́mù lọ sí Bábílónì.

  • 1 Kíróníkà 3:16
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 16 Ọmọ* Jèhóákímù ni Jekonáyà,+ Sedekáyà sì ni ọmọ rẹ̀.

  • 2 Kíróníkà 36:9, 10
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 9 Ọmọ ọdún méjìdínlógún (18) ni Jèhóákínì+ nígbà tó jọba, oṣù mẹ́ta àti ọjọ́ mẹ́wàá ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù; ó ń ṣe ohun tó burú ní ojú Jèhófà.+ 10 Ní ìbẹ̀rẹ̀ ọdún,* Ọba Nebukadinésárì ní kí wọ́n lọ mú un wá sí Bábílónì+ pẹ̀lú àwọn ohun iyebíye tó wà ní ilé Jèhófà.+ Bákan náà, ó fi Sedekáyà arákùnrin bàbá rẹ̀ jọba lórí Júdà àti Jerúsálẹ́mù.+

  • Jeremáyà 22:28
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 28 Ṣé ọkùnrin yìí, Konáyà, jẹ́ ẹni ẹ̀sín, ìkòkò tó ti fọ́,

      Ohun èlò tí ẹnikẹ́ni kò fẹ́?

      Kí nìdí tí a fi wó òun pẹ̀lú àtọmọdọ́mọ rẹ̀ lulẹ̀

      Tí a sì sọ wọ́n sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀?’+

  • Jeremáyà 24:1
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 24 Lẹ́yìn náà, Jèhófà fi apẹ̀rẹ̀ méjì tí ọ̀pọ̀tọ́ wà nínú wọn níwájú tẹ́ńpìlì Jèhófà hàn mí. Èyí wáyé lẹ́yìn tí Nebukadinésárì* ọba Bábílónì mú Jekonáyà*+ ọmọ Jèhóákímù,+ ọba Júdà lọ sí ìgbèkùn pẹ̀lú àwọn ìjòyè Júdà àti àwọn oníṣẹ́ ọnà pẹ̀lú àwọn oníṣẹ́ irin.* Ó kó wọn láti Jerúsálẹ́mù lọ sí Bábílónì.+

  • Jeremáyà 37:1
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 37 Ọba Sedekáyà+ ọmọ Jòsáyà bẹ̀rẹ̀ sí í jọba ní ipò Konáyà*+ ọmọ Jèhóákímù, nítorí Nebukadinésárì* ọba Bábílónì fi jẹ ọba ní ilẹ̀ Júdà.+

  • Jeremáyà 52:31
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 31 Ní ọdún kẹtàdínlógójì tí Jèhóákínì+ ọba Júdà ti wà ní ìgbèkùn, ní oṣù kejìlá, ní ọjọ́ kẹẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n oṣù náà, Efili-méródákì ọba Bábílónì, ní ọdún tó jọba, dá Jèhóákínì ọba Júdà sílẹ̀,* ó sì mú un kúrò lẹ́wọ̀n.+

  • Mátíù 1:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 Jòsáyà+ bí Jekonáyà+ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ nígbà tí wọ́n kó wọn lọ sí Bábílónì.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́