12 Torí màá lọ káàkiri ilẹ̀ Íjíbítì lálẹ́ yìí, màá sì pa gbogbo àkọ́bí nílẹ̀ Íjíbítì, látorí èèyàn dórí ẹranko;+ màá sì dá gbogbo ọlọ́run Íjíbítì lẹ́jọ́.+ Èmi ni Jèhófà.
29 Nígbà tó di ọ̀gànjọ́ òru, Jèhófà pa gbogbo àkọ́bí nílẹ̀ Íjíbítì,+ látorí àkọ́bí Fáráò tó wà lórí ìtẹ́ dórí àkọ́bí ẹni tó wà lẹ́wọ̀n* àti gbogbo àkọ́bí ẹranko.+