-
Jeremáyà 50:1-3Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
50 Ọ̀rọ̀ tí Jèhófà sọ nípa Bábílónì,+ nípa ilẹ̀ àwọn ará Kálídíà, nípasẹ̀ wòlíì Jeremáyà nìyí:
2 “Ẹ sọ ọ́ láàárín àwọn orílẹ̀-èdè kí ẹ sì kéde rẹ̀.
Ẹ gbé àmì kan dúró,* ẹ sì kéde rẹ̀.
Ẹ má fi nǹkan kan pa mọ́!
Ẹ sọ pé, ‘Wọ́n ti gba Bábílónì.+
Ìtìjú ti bá Bélì.+
Méródákì wà nínú ìbẹ̀rù.
Ìtìjú ti bá àwọn ère rẹ̀.
Àwọn òrìṣà ẹ̀gbin rẹ̀* wà nínú ìbẹ̀rù.’
3 Nítorí orílẹ̀-èdè kan ti wá gbéjà kò ó láti àríwá.+
Ó ti sọ ilẹ̀ rẹ̀ di ohun àríbẹ̀rù;
Kò sì sí ẹni tó ń gbé inú rẹ̀.
Èèyàn àti ẹranko ti fẹsẹ̀ fẹ;
Wọ́n ti lọ.”
-