-
Jeremáyà 50:3Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
3 Nítorí orílẹ̀-èdè kan ti wá gbéjà kò ó láti àríwá.+
Ó ti sọ ilẹ̀ rẹ̀ di ohun àríbẹ̀rù;
Kò sì sí ẹni tó ń gbé inú rẹ̀.
Èèyàn àti ẹranko ti fẹsẹ̀ fẹ;
Wọ́n ti lọ.”
-
-
Jeremáyà 50:13Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
Ẹnikẹ́ni tó bá ń kọjá lọ lẹ́gbẹ̀ẹ́ Bábílónì á wò ó, ẹ̀rù á bà á
Á sì súfèé nítorí gbogbo ìyọnu rẹ̀.+
-
-
Jeremáyà 51:29Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
29 Ilẹ̀ ayé á mì tìtì, jìnnìjìnnì á sì bá a,
Nítorí pé èrò Jèhófà sí Bábílónì máa ṣẹ
Láti sọ ilẹ̀ Bábílónì di ohun àríbẹ̀rù, tí ẹnì kánkán kò ní gbé ibẹ̀.+
-