-
Àìsáyà 56:6, 7Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
6 Ní ti àwọn àjèjì tó fara mọ́ Jèhófà láti máa ṣe ìránṣẹ́ fún un,
Láti nífẹ̀ẹ́ orúkọ Jèhófà,+
Kí wọ́n sì di ìránṣẹ́ rẹ̀,
Gbogbo àwọn tó ń pa Sábáàtì mọ́, tí wọn ò sì kẹ́gàn rẹ̀,
Tí wọ́n ń rọ̀ mọ́ májẹ̀mú mi,
7 Màá tún mú wọn wá sí òkè mímọ́ mi,+
Màá sì mú kí wọ́n máa yọ̀ nínú ilé àdúrà mi.
Màá tẹ́wọ́ gba odindi ẹbọ sísun wọn àtàwọn ẹbọ wọn lórí pẹpẹ mi.
Torí a ó máa pe ilé mi ní ilé àdúrà fún gbogbo èèyàn.”+
-
-
Sekaráyà 8:22, 23Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
22 Ọ̀pọ̀ èèyàn àti orílẹ̀-èdè alágbára yóò wá sí Jerúsálẹ́mù láti wá Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun,+ kí wọ́n sì lè bẹ Jèhófà pé kó ṣojúure sí àwọn.’*
23 “Ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun sọ nìyí, ‘Ní àwọn ọjọ́ yẹn, ọkùnrin mẹ́wàá láti inú gbogbo èdè àwọn orílẹ̀-èdè+ yóò di aṣọ* Júù* kan mú, àní wọn yóò dì í mú ṣinṣin, wọ́n á sì sọ pé: “A fẹ́ bá yín lọ,+ torí a ti gbọ́ pé Ọlọ́run wà pẹ̀lú yín.”’”+
-