Àìsáyà 11:6, 7 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 6 Ìkookò máa bá ọ̀dọ́ àgùntàn gbé fúngbà díẹ̀,+Àmọ̀tẹ́kùn máa dùbúlẹ̀ ti ọmọ ewúrẹ́,Ọmọ màlúù, kìnnìún* àti ẹran tó sanra á jọ wà pa pọ̀;*+Ọmọ kékeré á sì máa dà wọ́n. 7 Màlúù àti bíárì á jọ máa jẹun,Àwọn ọmọ wọn á sì jọ dùbúlẹ̀. Kìnnìún máa jẹ pòròpórò bí akọ màlúù.+ Àìsáyà 65:25 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 25 Ìkookò àti ọ̀dọ́ àgùntàn máa jẹun pa pọ̀,Kìnnìún máa jẹ pòròpórò bí akọ màlúù,+Erùpẹ̀ sì ni ejò á máa jẹ. Wọn ò ní ṣe ìpalára kankan, wọn ò sì ní fa ìparun kankan ní gbogbo òkè mímọ́ mi,”+ ni Jèhófà wí. Ìsíkíẹ́lì 34:25 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 25 “‘“Èmi yóò bá wọn dá májẹ̀mú àlàáfíà,+ èmi yóò sì pa àwọn ẹranko ẹhànnà run ní ilẹ̀ náà,+ kí wọ́n lè máa gbé láìséwu nínú aginjù, kí wọ́n sì sùn nínú igbó.+ Hósíà 2:18 Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun 18 Ní ọjọ́ yẹn, màá bá àwọn ẹran inú igbó dá májẹ̀mú nítorí wọn,+Màá sì bá àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ohun tó ń rákò lórí ilẹ̀ dá májẹ̀mú;+Màá mú ọfà* àti idà àti ogun kúrò ní ilẹ̀ náà,+Màá sì jẹ́ kí wọ́n dùbúlẹ̀* ní ààbò.+
6 Ìkookò máa bá ọ̀dọ́ àgùntàn gbé fúngbà díẹ̀,+Àmọ̀tẹ́kùn máa dùbúlẹ̀ ti ọmọ ewúrẹ́,Ọmọ màlúù, kìnnìún* àti ẹran tó sanra á jọ wà pa pọ̀;*+Ọmọ kékeré á sì máa dà wọ́n. 7 Màlúù àti bíárì á jọ máa jẹun,Àwọn ọmọ wọn á sì jọ dùbúlẹ̀. Kìnnìún máa jẹ pòròpórò bí akọ màlúù.+
25 Ìkookò àti ọ̀dọ́ àgùntàn máa jẹun pa pọ̀,Kìnnìún máa jẹ pòròpórò bí akọ màlúù,+Erùpẹ̀ sì ni ejò á máa jẹ. Wọn ò ní ṣe ìpalára kankan, wọn ò sì ní fa ìparun kankan ní gbogbo òkè mímọ́ mi,”+ ni Jèhófà wí.
25 “‘“Èmi yóò bá wọn dá májẹ̀mú àlàáfíà,+ èmi yóò sì pa àwọn ẹranko ẹhànnà run ní ilẹ̀ náà,+ kí wọ́n lè máa gbé láìséwu nínú aginjù, kí wọ́n sì sùn nínú igbó.+
18 Ní ọjọ́ yẹn, màá bá àwọn ẹran inú igbó dá májẹ̀mú nítorí wọn,+Màá sì bá àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ohun tó ń rákò lórí ilẹ̀ dá májẹ̀mú;+Màá mú ọfà* àti idà àti ogun kúrò ní ilẹ̀ náà,+Màá sì jẹ́ kí wọ́n dùbúlẹ̀* ní ààbò.+