-
2 Kíróníkà 36:9, 10Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
9 Ọmọ ọdún méjìdínlógún (18) ni Jèhóákínì+ nígbà tó jọba, oṣù mẹ́ta àti ọjọ́ mẹ́wàá ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù; ó ń ṣe ohun tó burú ní ojú Jèhófà.+ 10 Ní ìbẹ̀rẹ̀ ọdún,* Ọba Nebukadinésárì ní kí wọ́n lọ mú un wá sí Bábílónì+ pẹ̀lú àwọn ohun iyebíye tó wà ní ilé Jèhófà.+ Bákan náà, ó fi Sedekáyà arákùnrin bàbá rẹ̀ jọba lórí Júdà àti Jerúsálẹ́mù.+
-
-
Jeremáyà 24:1Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
24 Lẹ́yìn náà, Jèhófà fi apẹ̀rẹ̀ méjì tí ọ̀pọ̀tọ́ wà nínú wọn níwájú tẹ́ńpìlì Jèhófà hàn mí. Èyí wáyé lẹ́yìn tí Nebukadinésárì* ọba Bábílónì mú Jekonáyà*+ ọmọ Jèhóákímù,+ ọba Júdà lọ sí ìgbèkùn pẹ̀lú àwọn ìjòyè Júdà àti àwọn oníṣẹ́ ọnà pẹ̀lú àwọn oníṣẹ́ irin.* Ó kó wọn láti Jerúsálẹ́mù lọ sí Bábílónì.+
-
-
Jeremáyà 29:1, 2Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
29 Èyí ni ọ̀rọ̀ inú lẹ́tà tí wòlíì Jeremáyà fi ránṣẹ́ láti Jerúsálẹ́mù sí àwọn àgbààgbà tó ṣẹ́ kù lára àwọn tó wà nígbèkùn àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú àwọn wòlíì àti gbogbo àwọn èèyàn náà, àwọn tí Nebukadinésárì kó láti Jerúsálẹ́mù lọ sí ìgbèkùn ní Bábílónì, 2 lẹ́yìn tí Ọba Jekonáyà,+ ìyá ọba,*+ àwọn òṣìṣẹ́ ààfin, àwọn ìjòyè Júdà àti Jerúsálẹ́mù pẹ̀lú àwọn oníṣẹ́ ọnà àti àwọn oníṣẹ́ irin* ti jáde kúrò ní Jerúsálẹ́mù.+
-