-
Jeremáyà 25:12-14Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
12 “‘Ṣùgbọ́n tí àádọ́rin (70) ọdún bá pé,+ màá pe ọba Bábílónì àti orílẹ̀-èdè yẹn wá jíhìn* nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,’+ ni Jèhófà wí, ‘màá sì sọ ilẹ̀ àwọn ará Kálídíà di ahoro títí láé.+ 13 Màá mú gbogbo ọ̀rọ̀ mi ṣẹ sórí ilẹ̀ náà, èyí tí mo ti sọ sí i, ìyẹn gbogbo ohun tó wà nínú ìwé yìí tí Jeremáyà sọ tẹ́lẹ̀ nípa gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè. 14 Nítorí ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè àti àwọn ọba ńlá+ á sọ wọ́n di ẹrú,+ màá sì san èrè wọn pa dà fún wọn gẹ́gẹ́ bí ìwà àti iṣẹ́ ọwọ́ wọn.’”+
-