Friday, August 15
Ó ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀, torí ó ń bẹ̀rù àwọn tó dádọ̀dọ́.—Gál. 2:12.
Kódà lẹ́yìn tí àpọ́sítélì Pétérù di Kristẹni ẹni àmì òróró, ó ṣì ń bá àwọn kùdìẹ̀-kudiẹ kan yí. Nígbà tó di ọdún 36 S.K., Pétérù wà níbẹ̀ nígbà tí Ọlọ́run fẹ̀mí yan Kọ̀nílíù tí kì í ṣe Júù. Èyí jẹ́ ká rí i kedere pé “Ọlọ́run kì í ṣe ojúsàájú,” ó sì fẹ́ káwọn tí kì í ṣe Júù di ara ìjọ Kristẹni. (Ìṣe 10:34, 44, 45) Àtìgbà yẹn ni Pétérù ti ń jẹun pẹ̀lú àwọn tí kì í ṣe Júù torí kì í ṣe bẹ́ẹ̀ tẹ́lẹ̀. Àmọ́ àwọn Júù kan ṣì ń rò pé kò yẹ káwọn Júù àtàwọn tí kì í ṣe Júù máa jẹun pa pọ̀. Nígbà táwọn Júù tó nírú èrò yẹn wá sí Áńtíókù, Pétérù ò jẹun pẹ̀lú àwọn Kristẹni tí kì í ṣe Júù mọ́, ó sì ṣeé ṣe kó jẹ́ torí pé kò fẹ́ múnú bí àwọn Júù tó jẹ́ Kristẹni. Nígbà tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù rí ohun tí Pétérù ṣe yìí, ó bá a wí lójú àwọn èèyàn tó wà níbẹ̀. (Gál. 2:13, 14) Bó tiẹ̀ jẹ́ pé Pétérù ṣàṣìṣe, ó ń sin Jèhófà nìṣó. w23.09 22 ¶8
Saturday, August 16
Ó máa fẹsẹ̀ yín múlẹ̀ gbọn-in.—1 Pét. 5:10.
Tó o bá ṣàyẹ̀wò ara ẹ dáadáa, o lè rí i pé ó láwọn ibi tó o kù sí, àmọ́ má ṣe jẹ́ kó sú ẹ. Bíbélì sọ pé: “Onínúure ni [Jésù] Olúwa,” ó sì máa ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti ṣe àwọn àtúnṣe tó yẹ. (1 Pét. 2:3) Àpọ́sítélì Pétérù fi dá wa lójú pé: “Ọlọ́run . . . máa fúnra rẹ̀ parí ìdálẹ́kọ̀ọ́ yín. Ó máa fún yín lókun.” Ìgbà kan wà tí Pétérù ronú pé òun ò yẹ lẹ́ni tó ń di ọmọ ẹ̀yìn Jésù. (Lúùkù 5:8) Àmọ́ torí pé Jèhófà àti Jésù ràn án lọ́wọ́, ó ṣiṣẹ́ kára kó lè máa jẹ́ ọmọ ẹ̀yìn Kristi nìṣó. Torí náà, Jèhófà fún Pétérù láǹfààní láti “wọlé fàlàlà sínú Ìjọba ayérayé ti Olúwa àti Olùgbàlà wa Jésù Kristi.” (2 Pét. 1:11) Ẹ ò rí i pé èrè ńlá nìyẹn! Tá a bá fara wé Pétérù, tá a jẹ́ kí Jèhófà dá wa lẹ́kọ̀ọ́ dáadáa, tá ò sì jẹ́ kó sú wa, àá gba èrè ìyè àìnípẹ̀kun. ‘Ọwọ́ wa sì máa tẹ èrè ìgbàgbọ́ wa, ìyẹn ìgbàlà wa.’—1 Pét. 1:9. w23.09 31 ¶16-17
Sunday, August 17
Ẹ jọ́sìn Ẹni tó dá ọ̀run àti ayé.—Ìfi. 14:7.
Inú àgbàlá kan ni àgọ́ ìjọsìn wà, wọ́n sì ṣe ọgbà yí i ká. Ibẹ̀ ni àwọn àlùfáà ti máa ń ṣiṣẹ́. Pẹpẹ bàbà ńlá kan tí wọ́n ń rú ẹbọ sísun lórí ẹ̀ wà nínú àgbàlá náà, bàsíà kan tí wọ́n fi bàbà ṣe tún wà níbẹ̀. Inú ẹ̀ ni àwọn àlùfáà ti máa ń bu omi láti fi wẹ̀ kí wọ́n tó ṣe iṣẹ́ ìsìn mímọ́. (Ẹ́kís. 30:17-20; 40:6-8) Lónìí, àwọn tó ṣẹ́ kù lára àwọn ẹni àmì òróró ń ṣiṣẹ́ ní àgbàlá inú tẹ́ńpìlì tẹ̀mí tó wà láyé. Omi tó wà nínú bàsíà ńlá ń rán àwọn ẹni àmì òróró létí pé, ó yẹ kí wọ́n jẹ́ mímọ́ nínú ìwà wọn àti nínú ìjọsìn wọn, bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe ń rán àwa Kristẹni yòókù létí. Ibo wá ni “ogunlọ́gọ̀ èèyàn” ti ń jọ́sìn? Àpọ́sítélì Jòhánù rí wọn tí “wọ́n dúró níwájú ìtẹ́.” Ní ayé níbí, iwájú ìtẹ́ yẹn ló ṣàpẹẹrẹ àgbàlá ìta níbi tí “wọ́n [ti] ń ṣe iṣẹ́ ìsìn mímọ́ fún [Ọlọ́run] tọ̀sántòru nínú tẹ́ńpìlì rẹ̀.” (Ìfi. 7:9, 13-15) A mà dúpẹ́ o, pé Jèhófà jẹ́ ká máa jọ́sìn òun nínú tẹ́ńpìlì ńlá rẹ̀ tẹ̀mí! w23.10 28 ¶15-16