Saturday, August 16
Ó máa fẹsẹ̀ yín múlẹ̀ gbọn-in.—1 Pét. 5:10.
Tó o bá ṣàyẹ̀wò ara ẹ dáadáa, o lè rí i pé ó láwọn ibi tó o kù sí, àmọ́ má ṣe jẹ́ kó sú ẹ. Bíbélì sọ pé: “Onínúure ni [Jésù] Olúwa,” ó sì máa ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti ṣe àwọn àtúnṣe tó yẹ. (1 Pét. 2:3) Àpọ́sítélì Pétérù fi dá wa lójú pé: “Ọlọ́run . . . máa fúnra rẹ̀ parí ìdálẹ́kọ̀ọ́ yín. Ó máa fún yín lókun.” Ìgbà kan wà tí Pétérù ronú pé òun ò yẹ lẹ́ni tó ń di ọmọ ẹ̀yìn Jésù. (Lúùkù 5:8) Àmọ́ torí pé Jèhófà àti Jésù ràn án lọ́wọ́, ó ṣiṣẹ́ kára kó lè máa jẹ́ ọmọ ẹ̀yìn Kristi nìṣó. Torí náà, Jèhófà fún Pétérù láǹfààní láti “wọlé fàlàlà sínú Ìjọba ayérayé ti Olúwa àti Olùgbàlà wa Jésù Kristi.” (2 Pét. 1:11) Ẹ ò rí i pé èrè ńlá nìyẹn! Tá a bá fara wé Pétérù, tá a jẹ́ kí Jèhófà dá wa lẹ́kọ̀ọ́ dáadáa, tá ò sì jẹ́ kó sú wa, àá gba èrè ìyè àìnípẹ̀kun. ‘Ọwọ́ wa sì máa tẹ èrè ìgbàgbọ́ wa, ìyẹn ìgbàlà wa.’—1 Pét. 1:9. w23.09 31 ¶16-17
Sunday, August 17
Ẹ jọ́sìn Ẹni tó dá ọ̀run àti ayé.—Ìfi. 14:7.
Inú àgbàlá kan ni àgọ́ ìjọsìn wà, wọ́n sì ṣe ọgbà yí i ká. Ibẹ̀ ni àwọn àlùfáà ti máa ń ṣiṣẹ́. Pẹpẹ bàbà ńlá kan tí wọ́n ń rú ẹbọ sísun lórí ẹ̀ wà nínú àgbàlá náà, bàsíà kan tí wọ́n fi bàbà ṣe tún wà níbẹ̀. Inú ẹ̀ ni àwọn àlùfáà ti máa ń bu omi láti fi wẹ̀ kí wọ́n tó ṣe iṣẹ́ ìsìn mímọ́. (Ẹ́kís. 30:17-20; 40:6-8) Lónìí, àwọn tó ṣẹ́ kù lára àwọn ẹni àmì òróró ń ṣiṣẹ́ ní àgbàlá inú tẹ́ńpìlì tẹ̀mí tó wà láyé. Omi tó wà nínú bàsíà ńlá ń rán àwọn ẹni àmì òróró létí pé, ó yẹ kí wọ́n jẹ́ mímọ́ nínú ìwà wọn àti nínú ìjọsìn wọn, bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe ń rán àwa Kristẹni yòókù létí. Ibo wá ni “ogunlọ́gọ̀ èèyàn” ti ń jọ́sìn? Àpọ́sítélì Jòhánù rí wọn tí “wọ́n dúró níwájú ìtẹ́.” Ní ayé níbí, iwájú ìtẹ́ yẹn ló ṣàpẹẹrẹ àgbàlá ìta níbi tí “wọ́n [ti] ń ṣe iṣẹ́ ìsìn mímọ́ fún [Ọlọ́run] tọ̀sántòru nínú tẹ́ńpìlì rẹ̀.” (Ìfi. 7:9, 13-15) A mà dúpẹ́ o, pé Jèhófà jẹ́ ká máa jọ́sìn òun nínú tẹ́ńpìlì ńlá rẹ̀ tẹ̀mí! w23.10 28 ¶15-16
Monday, August 18
Nítorí ìlérí Ọlọ́run, . . . ìgbàgbọ́ rẹ̀ mú kó di alágbára.—Róòmù 4:20.
Àwọn alàgbà wà lára àwọn tí Jèhófà ń lò láti fún wa lókun. (Àìsá. 32:1, 2) Torí náà, tí nǹkan kan bá ń dà ẹ́ láàmú, sọ nǹkan náà fáwọn alàgbà. Tí wọ́n bá láwọn fẹ́ ràn ẹ́ lọ́wọ́, má kọ ìrànlọ́wọ́ tí wọ́n fẹ́ ṣe fún ẹ. Ìdí sì ni pé Jèhófà lè lò wọ́n láti mú kí ìgbàgbọ́ ẹ lágbára. Àwọn ìlérí tó wà nínú Bíbélì pé àwọn Kristẹni kan máa gbé ọ̀run títí láé, àwọn yòókù sì máa gbé ayé títí láé nínú Párádísè máa ń jẹ́ ká nírètí. (Róòmù 4:3, 18, 19) Ìrètí tá a ní yìí ń fún wa lókun ká lè fara da ìṣòro, ká máa wàásù ìhìn rere, ká sì máa ran àwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin wa lọ́wọ́. (1 Tẹs. 1:3) Ìrètí yẹn kan náà ló fún àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù lókun. Ó sọ pé wọ́n ‘há òun gádígádí, ọkàn òun dà rú, wọ́n ṣe inúnibíni sí òun, wọ́n sì gbé òun ṣánlẹ̀.’ Kódà, ẹ̀mí ẹ̀ máa ń wà nínú ewu. (2 Kọ́r. 4:8-10) Pọ́ọ̀lù rí okun gbà torí pé ó tẹjú mọ́ ohun tó ń retí, ìyẹn sì jẹ́ kó fara da àwọn ìṣòro ẹ̀. (2 Kọ́r. 4:16-18) Pọ́ọ̀lù tẹjú mọ́ èrè ọjọ́ iwájú tó ní láti gbé ọ̀run títí láé. Ó máa ń ronú nípa ìrètí yẹn, torí náà, ó ń di “ọ̀tun láti ọjọ́ dé ọjọ́.” w23.10 15-16 ¶14-17