Sunday, August 17
Ẹ jọ́sìn Ẹni tó dá ọ̀run àti ayé.—Ìfi. 14:7.
Inú àgbàlá kan ni àgọ́ ìjọsìn wà, wọ́n sì ṣe ọgbà yí i ká. Ibẹ̀ ni àwọn àlùfáà ti máa ń ṣiṣẹ́. Pẹpẹ bàbà ńlá kan tí wọ́n ń rú ẹbọ sísun lórí ẹ̀ wà nínú àgbàlá náà, bàsíà kan tí wọ́n fi bàbà ṣe tún wà níbẹ̀. Inú ẹ̀ ni àwọn àlùfáà ti máa ń bu omi láti fi wẹ̀ kí wọ́n tó ṣe iṣẹ́ ìsìn mímọ́. (Ẹ́kís. 30:17-20; 40:6-8) Lónìí, àwọn tó ṣẹ́ kù lára àwọn ẹni àmì òróró ń ṣiṣẹ́ ní àgbàlá inú tẹ́ńpìlì tẹ̀mí tó wà láyé. Omi tó wà nínú bàsíà ńlá ń rán àwọn ẹni àmì òróró létí pé, ó yẹ kí wọ́n jẹ́ mímọ́ nínú ìwà wọn àti nínú ìjọsìn wọn, bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe ń rán àwa Kristẹni yòókù létí. Ibo wá ni “ogunlọ́gọ̀ èèyàn” ti ń jọ́sìn? Àpọ́sítélì Jòhánù rí wọn tí “wọ́n dúró níwájú ìtẹ́.” Ní ayé níbí, iwájú ìtẹ́ yẹn ló ṣàpẹẹrẹ àgbàlá ìta níbi tí “wọ́n [ti] ń ṣe iṣẹ́ ìsìn mímọ́ fún [Ọlọ́run] tọ̀sántòru nínú tẹ́ńpìlì rẹ̀.” (Ìfi. 7:9, 13-15) A mà dúpẹ́ o, pé Jèhófà jẹ́ ká máa jọ́sìn òun nínú tẹ́ńpìlì ńlá rẹ̀ tẹ̀mí! w23.10 28 ¶15-16
Monday, August 18
Nítorí ìlérí Ọlọ́run, . . . ìgbàgbọ́ rẹ̀ mú kó di alágbára.—Róòmù 4:20.
Àwọn alàgbà wà lára àwọn tí Jèhófà ń lò láti fún wa lókun. (Àìsá. 32:1, 2) Torí náà, tí nǹkan kan bá ń dà ẹ́ láàmú, sọ nǹkan náà fáwọn alàgbà. Tí wọ́n bá láwọn fẹ́ ràn ẹ́ lọ́wọ́, má kọ ìrànlọ́wọ́ tí wọ́n fẹ́ ṣe fún ẹ. Ìdí sì ni pé Jèhófà lè lò wọ́n láti mú kí ìgbàgbọ́ ẹ lágbára. Àwọn ìlérí tó wà nínú Bíbélì pé àwọn Kristẹni kan máa gbé ọ̀run títí láé, àwọn yòókù sì máa gbé ayé títí láé nínú Párádísè máa ń jẹ́ ká nírètí. (Róòmù 4:3, 18, 19) Ìrètí tá a ní yìí ń fún wa lókun ká lè fara da ìṣòro, ká máa wàásù ìhìn rere, ká sì máa ran àwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin wa lọ́wọ́. (1 Tẹs. 1:3) Ìrètí yẹn kan náà ló fún àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù lókun. Ó sọ pé wọ́n ‘há òun gádígádí, ọkàn òun dà rú, wọ́n ṣe inúnibíni sí òun, wọ́n sì gbé òun ṣánlẹ̀.’ Kódà, ẹ̀mí ẹ̀ máa ń wà nínú ewu. (2 Kọ́r. 4:8-10) Pọ́ọ̀lù rí okun gbà torí pé ó tẹjú mọ́ ohun tó ń retí, ìyẹn sì jẹ́ kó fara da àwọn ìṣòro ẹ̀. (2 Kọ́r. 4:16-18) Pọ́ọ̀lù tẹjú mọ́ èrè ọjọ́ iwájú tó ní láti gbé ọ̀run títí láé. Ó máa ń ronú nípa ìrètí yẹn, torí náà, ó ń di “ọ̀tun láti ọjọ́ dé ọjọ́.” w23.10 15-16 ¶14-17
Tuesday, August 19
Jèhófà yóò fún àwọn èèyàn rẹ̀ ní agbára. Jèhófà yóò fi àlàáfíà jíǹkí àwọn èèyàn rẹ̀.—Sm. 29:11.
Tó o bá ń gbàdúrà, wò ó bóyá àsìkò ti tó lójú Jèhófà láti dáhùn àdúrà ẹ. Ó lè máa ṣe wá bíi pé kí Jèhófà dáhùn àdúrà wa lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀. Àmọ́, òótọ́ ibẹ̀ ni pé Jèhófà mọ àsìkò tó dáa jù láti dáhùn àdúrà wa. (Héb. 4:16) Tá ò bá tètè rí ìdáhùn àdúrà wa, a lè rò pé Jèhófà ò dáhùn àdúrà wa. Àmọ́, ó lè jẹ́ pé kò tíì tó àsìkò lójú ẹ̀ ni. Bí àpẹẹrẹ, arákùnrin ọ̀dọ́ kan lè bẹ Jèhófà pé kó wo òun sàn. Àmọ́ Jèhófà ò ṣe bẹ́ẹ̀. Ká sọ pé Jèhófà wò ó sàn lọ́nà ìyanu ni, Sátánì lè sọ pé torí pé Jèhófà wò ó sàn ló ṣe ń sin Jèhófà. (Jóòbù 1:9-11; 2:4) Yàtọ̀ síyẹn, Jèhófà ti mọ ìgbà tó máa mú gbogbo àìsàn kúrò pátápátá. (Àìsá. 33:24; Ìfi. 21:3, 4) Àmọ́ kó tó dìgbà yẹn, a ò lè retí pé gbogbo ìgbà ni Jèhófà máa wò wá sàn lọ́nà ìyanu. Torí náà, arákùnrin yẹn lè bẹ Jèhófà pé kó fún òun lókun, kó sì jẹ́ kọ́kàn òun balẹ̀ kóun lè máa fara da àìsàn náà, kóun sì máa sin Jèhófà tọkàntọkàn. w23.11 23 ¶13