-
Ẹ Wá Ọlọ́run, Kẹ́ Ẹ sì Rí I Ní Ti Gidi“Jẹ́rìí Kúnnákúnná Nípa Ìjọba Ọlọ́run”
-
-
ORÍ 18
‘Ẹ Wá Ọlọ́run, Kẹ́ Ẹ sì Rí I Ní Ti Gidi’
Pọ́ọ̀lù wá ibi tí ọ̀rọ̀ òun àti tàwọn tó wàásù fún ti jọra, ó sì mú ọ̀rọ̀ ẹ̀ bá ipò wọn mu
Ó dá lórí Ìṣe 17:16-34
1-3. (a) Kí ló ba àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù lọ́kàn jẹ́ nígbà tó dé Áténì? (b) Kí la lè rí kọ́ látinú àpẹẹrẹ Pọ́ọ̀lù?
PỌ́Ọ̀LÙ rí ohun tó bà á lọ́kàn jẹ́ gan-an nígbà tó dé Áténì, nílùú Gíríìsì. Ojúkò ìmọ̀ ẹ̀kọ́ ni Áténì, ibẹ̀ ni Socrates, Plato àti Aristotle ti fìgbà kan rí kọ́ àwọn èèyàn lẹ́kọ̀ọ́. Ọ̀rọ̀ ẹ̀sìn jẹ àwọn ará ìlú yìí lógún. Kò síbi tí Pọ́ọ̀lù yíjú sí tí ò ti rí ère rẹpẹtẹ, ì báà jẹ́ inú tẹ́ńpìlì, inú ìlú, tàbí lójú ọ̀nà. Ìdí tó sì fi rí bẹ́ẹ̀ ni pé oríṣiríṣi òrìṣà làwọn ará Áténì ń bọ. Pọ́ọ̀lù mọ ojú tí Jèhófà Ọlọ́run tòótọ́ fi ń wo ìbọ̀rìṣà. (Ẹ́kís. 20:4, 5) Bí Jèhófà ṣe kórìíra ìbọ̀rìṣà náà ni àpọ́sítélì olóòótọ́ yìí ṣe kórìíra rẹ̀!
2 Ohun tí Pọ́ọ̀lù rí bó ṣe wọ ibi ọjà ìlú yẹn bà á lọ́kàn jẹ́ gan-an ni. Wọ́n to àwọn ère tó ní ìrísí ẹ̀yà ìbímọ, tí wọ́n fi ń jọ́sìn òrìṣà Hẹ́mísì sí apá àríwá ìwọ̀ oòrùn ìlú náà, nítòsí ọ̀nà àbáwọlé. Ńṣe ni ojúbọ kún ibi ọjà náà fọ́fọ́. Báwo ni àpọ́sítélì onítara yìí ṣe wá máa wàásù nílùú táwọn èèyàn ti ń bọ̀rìṣà yìí? Ṣé ó máa fara balẹ̀ ronú ohun tó máa sọ, kó lè wá ibi tí ọ̀rọ̀ òun àti tàwọn tó fẹ́ wàásù fún ti jọra? Ṣé ó máa lè ran àwọn èèyàn yẹn lọ́wọ́ láti wá Ọlọ́run tòótọ́, kí wọ́n sì rí I?
3 Nínú Ìṣe 17:22-31, a rí bí Pọ́ọ̀lù ṣe bá àwọn ọ̀mọ̀wé ìlú Áténì sọ̀rọ̀. Àpẹẹrẹ rere lohun tó ṣe yìí jẹ́ tó bá kan ti pé ká bá àwọn èèyàn sọ̀rọ̀ lọ́nà tó máa wọ̀ wọ́n lọ́kàn, tá ò sì ní múnú bí wọn. Tá a bá ronú lórí ohun tí Pọ́ọ̀lù ṣe yìí, ó máa jẹ́ ká mọ ibi tọ́rọ̀ wa àti tàwọn tá à ń wàásù fún ti jọra, ká sì bá wọn fèròwérò.
Ó Ń Kọ́ Wọn “ní Ibi Ọjà” (Ìṣe 17:16-21)
4, 5. Ibo ni Pọ́ọ̀lù ti wàásù nílùú Áténì, irú àwọn èèyàn wo ló sì bá níbẹ̀?
4 Nígbà ìrìn àjò míṣọ́nnárì ẹlẹ́ẹ̀kejì tí Pọ́ọ̀lù rìn ní nǹkan bí ọdún 50 Sànmánì Kristẹni, ó lọ sí ìlú Áténì.a Nígbà tó ń dúró kí Sílà àti Tímótì dé láti Bèróà, bí àṣà rẹ̀, “ó bẹ̀rẹ̀ sí í bá àwọn Júù fèròwérò nínú sínágọ́gù.” Ó tún lọ síbi tí wọ́n ń pè ní agora tàbí “ibi ọjà,” tó ti lè rí àwọn tí kì í ṣe Júù tó ń gbé nílùú Áténì. (Ìṣe 17:17) Ọjà tó wà nílùú Áténì tóbi gan-an, ó sì wà nítòsí òkè kan tí wọ́n ń pè ní Acropolis. Ọjà nìkan kọ́ ni wọ́n ń ná níbẹ̀; wọ́n tún máa ń lo ibẹ̀ bíi gbọ̀ngàn táwọn èèyàn ti lè kóra jọ. Ìwé kan tá a ṣèwádìí nínú rẹ̀ sọ pé, “wọ́n máa ń ṣòwò níbẹ̀, àwọn olóṣèlú náà máa ń lo ibẹ̀, ó tún jẹ́ ojúkò àṣà ìṣẹ̀ǹbáyé ìlú náà.” Àwọn ọ̀mọ̀wé ará Áténì nífẹ̀ẹ́ láti máa wá síbẹ̀ kí wọ́n lè máa jíròrò àwọn nǹkan tuntun.
5 Kò rọrùn láti yí àwọn tí Pọ́ọ̀lù rí níbi ọjà náà lérò pa dà. Lára àwọn tó ń bá sọ̀rọ̀ ni àwọn Epikúríà àtàwọn Sítọ́íkì, wọ́n jẹ́ ọmọ ilé ẹ̀kọ́ onímọ̀ ọgbọ́n orí, ohun tí wọ́n sì gbà gbọ́ yàtọ̀ síra.b Bí àpẹẹrẹ, àwọn Epikúríà gbà gbọ́ pé ṣe làwọn ohun alààyè kàn ṣàdédé wà. Èrò wọn ni pé: “Kò sídìí láti bẹ̀rù Ọlọ́run; Òkú ò mọ nǹkan kan; Ohun rere lè tẹ̀ wá lọ́wọ́ láì làágùn jìnnà; Èèyàn lè fara da ìṣòro láìsí ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run.” Ní tàwọn Sítọ́íkì, èrò wọn ni pé Ọlọ́run kan ṣoṣo ló wà. Bákan náà, wọ́n gbà pé ọgbọ́n àti làákàyè àwa èèyàn ti tó fún wa láti ṣàṣeyọrí. Àwùjọ méjèèjì ò nígbàgbọ́ nínú àjíǹde táwọn ọmọ ẹ̀yìn Kristi fi ń kọ́ni. Ó ṣe kedere pé èrò wọn ò bá òtítọ́ tí ẹ̀sìn Kristẹni tòótọ́ fi ń kọ́ni mu, òtítọ́ yìí ni Pọ́ọ̀lù sì ń wàásù rẹ̀.
6, 7. Kí làwọn Gíríìkì tó jẹ́ ọ̀mọ̀wé ṣe nígbà tí wọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ Pọ́ọ̀lù, kí làwa náà máa ń bá pàdé lónìí?
6 Kí làwọn Gíríìkì tó jẹ́ ọ̀mọ̀wé yìí ṣe nígbà tí wọ́n gbọ́ ohun tí Pọ́ọ̀lù fi ń kọ́ni? Àwọn kan lára wọn sọ pé “onírèégbè” ni Pọ́ọ̀lù, ìyẹn sì lè túmọ̀ sí ‘ẹni tó ń ṣa èso kiri’ lédè Gíríìkì. (Ìṣe 17:18) Nígbà tí ọ̀mọ̀wé kan ń sọ̀rọ̀ nípa ọ̀rọ̀ Gíríìkì tí wọ́n lò yìí, ó sọ pé: “Ẹyẹ kékeré kan tó máa ń ṣa èso kiri ni wọ́n kọ́kọ́ ń fi orúkọ yìí pè, àmọ́ nígbà tó yá, wọ́n wá ń fi orúkọ náà pe ẹni tó bá ń ṣa ilẹ̀ jẹ nínú ọjà. Bákan náà, wọ́n tún máa ń lo orúkọ yìí fún ẹnikẹ́ni tó bá ń kó onírúurú ìsọfúnni jọ, tàbí tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ ò yé èèyàn dáadáa, tí ò sì lè ṣàlàyé ọ̀rọ̀ náà lọ́nà tó yéni.” Lọ́rọ̀ kan ṣá, ohun táwọn ọ̀mọ̀wé yìí ń sọ ni pé Pọ́ọ̀lù ò mọ nǹkan tó ń ṣe, pé àgbọ́sọ lásán ló ń sọ. Àmọ́, bá a ṣe máa rí i, Pọ́ọ̀lù ò jẹ́ kí orúkọ tí ò dáa tí wọ́n ń pè é yìí mú kó rẹ̀wẹ̀sì.
7 Bẹ́ẹ̀ náà lọ̀rọ̀ rí lónìí. Àwọn èèyàn máa ń pe àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà láwọn orúkọ tí ò dáa torí pé ohun tá a gbà gbọ́ bá Bíbélì mu. Bí àpẹẹrẹ, àwọn olùkọ́ kan ń kọ́ àwọn èèyàn pé òtítọ́ ni ẹ̀kọ́ ẹfolúṣọ̀n tó sọ pé ara ẹranko lèèyàn ti jáde wá, wọ́n sì ń sọ pé tí orí éèyàn bá pé, ó yẹ kó gbà á gbọ́. Ohun tí wọ́n ń sọ ni pé aláìmọ̀kan lẹni tó bá kọ̀ láti gbà pé ara ẹranko lèèyàn ti jáde wá. Àwọn ọ̀mọ̀wé yìí fẹ́ káwọn èèyàn máa wò wá bí aláìríkan-ṣèkan tá a bá ń ṣàlàyé ohun tí Bíbélì sọ nípa ìṣẹ̀dá, tá a sì ń fi ohun tí Ẹlẹ́dàá dá ti ọ̀rọ̀ wa lẹ́yìn. Àmọ́ ìyẹn ò bà wá lẹ́rù. Kàkà bẹ́ẹ̀, ṣe la máa ń fìgboyà sọ̀rọ̀ nígbà tá a bá ń sọ ohun tá a gbà gbọ́ pé Jèhófà Ọlọ́run, Ẹlẹ́dàá tí ọgbọ́n rẹ̀ ò láàlà, ló dá ayé.—Ìfi. 4:11.
8. (a) Kí làwọn kan lára àwọn tó gbọ́ ìwàásù Pọ́ọ̀lù ṣe? (b) Kí ló ṣeé ṣe kí Áréópágù tí wọ́n mú Pọ́ọ̀lù lọ túmọ̀ sí? (Wo àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé.)
8 Èrò àwọn míì tó gbọ́ ìwàásù Pọ́ọ̀lù níbi ọjà náà yàtọ̀. Lójú wọn, “ó jọ ẹni tó ń kéde àwọn ọlọ́run àjèjì.” (Ìṣe 17:18) Tó bá jẹ́ pé lóòótọ́ ni Pọ́ọ̀lù ń ṣàlàyé ọlọ́run míì fáwọn ará Áténì, a jẹ́ pé kékeré kọ́ lọ̀rọ̀ yìí, torí pé ó jọ ọ̀kan lára ẹ̀sùn tí wọ́n fi kan onímọ̀ ọgbọ́n orí náà Socrates tí wọ́n sì pa á ní ọ̀pọ̀ ọdún sẹ́yìn. Abájọ tí wọ́n fi mú Pọ́ọ̀lù lọ sí Áréópágù, tí wọ́n sì sọ pé kó ṣàlàyé ẹ̀kọ́ àjèjì yìí fáwọn ará Áténì.c Tóò, báwo wá ni Pọ́ọ̀lù á ṣe ṣàlàyé ọ̀rọ̀ ẹ̀ fáwọn èèyàn tí ò mọ Ìwé Mímọ́ yìí?
“Ẹ̀yin Èèyàn Áténì, Mo Kíyè Sí Pé” (Ìṣe 17:22, 23)
9-11. (a) Báwo ni Pọ́ọ̀lù ṣe bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ ẹ̀ pẹ̀lú àwọn èèyàn náà láti ibi térò wọn ti jọra? (b) Báwo la ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Pọ́ọ̀lù lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù wa?
9 Ká má gbàgbé pé ìbọ̀rìṣà tó gbilẹ̀ ní ìlú náà ba Pọ́ọ̀lù nínú jẹ́ gan-an. Àmọ́ dípò tí á fi sọ kòbákùngbé ọ̀rọ̀ sí àwọn abọ̀rìṣà yẹn, ṣe ló kó ara ẹ̀ níjàánu. Pọ́ọ̀lù lo ọgbọ́n láti bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ ẹ̀ níbi térò wọn ti jọra. Ó bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ ẹ̀ báyìí: “Ẹ̀yin èèyàn Áténì, mo kíyè sí pé nínú ohun gbogbo, ó jọ pé ẹ bẹ̀rù àwọn ọlọ́run ju bí àwọn yòókù ṣe bẹ̀rù wọn lọ.” (Ìṣe 17:22) Ohun tí Pọ́ọ̀lù ń dọ́gbọ́n sọ ni pé, ‘Mo rí i pé ọ̀rọ̀ ìjọsìn jẹ yín lógún gan-an.’ Ó bọ́gbọ́n mu pé Pọ́ọ̀lù yìn wọ́n fún bí wọ́n ṣe nítara fún ẹ̀sìn. Ó gbà pé ó ṣeé ṣe káwọn kan lára àwọn tí ẹ̀kọ́ èké ti fọ́ lójú ṣe tán láti gbọ́ ohun tó fẹ́ sọ. Ó ṣe tán, Pọ́ọ̀lù rántí pé òun náà ti fìgbà kan rí jẹ́ ‘aláìmọ̀kan, tí ò sì ní ìgbàgbọ́.’—1 Tím. 1:13.
10 Pọ́ọ̀lù wá ń bọ́rọ̀ ẹ̀ lọ láti ibi térò wọn ti jọra, ó sọ ohun tó mú kó gbà pé lóòótọ́ lọ̀rọ̀ ẹ̀sìn jẹ àwọn ará Áténì lógún, nígbà tó mẹ́nu kan pẹpẹ kan tí wọ́n yà sí mímọ́ “Sí Ọlọ́run Àìmọ̀.” Ìwé kan sọ pé, “àṣà àwọn Gíríìkì àtàwọn míì ni láti máa ya àwọn pẹpẹ sí mímọ́ fún ‘àwọn ọlọ́run àìmọ̀,’ torí wọ́n máa ń bẹ̀rù pé àwọn lè ti yọ àwọn ọlọ́run kan sílẹ̀ nínú ìjọsìn àwọn, tó sì ṣeé ṣe kí wọ́n bínú.” Pẹpẹ táwọn ará Áténì ṣe yìí fi hàn pé wọ́n gbà pé Ọlọ́run kan wà táwọn ò mọ̀. Pọ́ọ̀lù wá lo pẹpẹ yìí láti fi bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ ẹ̀ nígbà tó ń wàásù ìhìn rere fún wọn. Ó ṣàlàyé pé: “Ohun tí ẹ̀ ń sìn láìmọ̀ ni mo wá kéde fún yín.” (Ìṣe 17:23) Ẹ ò rí i pé ọ̀nà tó dáa jù ni Pọ́ọ̀lù gbà báwọn èèyàn yìí fèròwérò! Kò sọ̀rọ̀ nípa ọlọ́run ilẹ̀ òkèèrè bí ẹ̀sùn táwọn kan lára wọn fi kàn án. Àmọ́, ṣe ló ń ṣàlàyé fún wọn nípa Ọlọ́run tòótọ́ tí wọn ò mọ̀.
11 Báwo la ṣe lè máa tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Pọ́ọ̀lù lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù wa? Tá a bá lákìíyèsí, a lè rí àwọn nǹkan tó máa fi hàn pé ọ̀rọ̀ ẹ̀sìn jẹ ẹnì kan lógún, bí ohun tẹ́ni náà fi sọ́rùn tàbí tó gbé kọ́ sínú ilé rẹ̀ tàbí ohun kan tó gbé sínú ọgbà ẹ̀. A lè sọ pé: ‘Mo rí i pé ẹ ní ẹ̀sìn tẹ́ ẹ̀ ń ṣe. Ó wù mí kí n bá èèyàn bíi tiyín, tó ní ẹ̀sìn tiẹ̀ sọ̀rọ̀.’ Lẹ́yìn tá a bá ti fọgbọ́n sọ fẹ́ni náà pé a mọyì bó ṣe ní ẹ̀sìn tiẹ̀, a lè wá bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ wa níbi térò wa ti jọra. Ẹ má gbàgbé pé a ò lè pinnu bóyá ẹnì kan máa tẹ́tí sí wa tàbí kò ní tẹ́tí sí wa torí ohun tó gbà gbọ́. Ó ṣe tán, ọ̀pọ̀ lára àwọn ará wa náà ti fìgbà kan rí gba ẹ̀kọ́ èké gbọ́.
Máa bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ níbi tí èrò ẹ àti tàwọn tó o fẹ́ wàásù fún ti jọra
Ọlọ́run “Kò Jìnnà sí Ẹnì Kọ̀ọ̀kan Wa” (Ìṣe 17:24-28)
12. Báwo ni Pọ́ọ̀lù ṣe mú kọ́rọ̀ ẹ̀ bá ipò àwọn tó ń tẹ́tí sí i mu?
12 Pọ́ọ̀lù ti bẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ ẹ̀ níbi tí èrò ẹ̀ ti jọ tàwọn tó ń wàásù fún, àmọ́ ṣé kò ní gbé ọ̀rọ̀ gba ibòmíì bó ṣe ń bá ọ̀rọ̀ ẹ̀ lọ? Pọ́ọ̀lù mọ̀ pé àwọn tó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ òun ní ìmọ̀ ọgbọ́n orí Gíríìkì, àmọ́ wọn ò mọ Ìwé Mímọ́, torí náà ó bá wọn sọ̀rọ̀ lóríṣiríṣi ọ̀nà. Lákọ̀ọ́kọ́, ó ṣàlàyé àwọn ẹ̀kọ́ tó wà nínú Bíbélì fún wọn láìkà á ní tààràtà. Ìkejì, ó jẹ́ káwọn tó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹ̀ mọ̀ pé òun mọ bí nǹkan ṣe rí lára wọn, àti pé èèyàn bíi tiwọn lòun náà. Ẹ̀kẹta, ó fa ọ̀rọ̀ yọ látinú ìwé lítíréṣọ̀ èdè Gíríìkì kí wọ́n lè mọ̀ pé ohun tó fi ń kọ́ni wà nínú ìwé táwọn òǹkọ̀wé Gíríìkì kọ. Ní báyìí, ẹ jẹ́ ká gbé gbankọgbì ọ̀rọ̀ tí Pọ́ọ̀lù sọ yẹ̀ wò. Òótọ́ pàtàkì wo ló sọ nípa Ọlọ́run táwọn ará Áténì ò mọ̀ nípa ẹ̀?
13. Àlàyé wo ni Pọ́ọ̀lù ṣe nípa ẹni tó dá ọ̀run àti ayé, kí ló sì fẹ́ káwọn èèyàn náà mọ̀?
13 Ọlọ́run ló dá ọ̀run àti ayé. Pọ́ọ̀lù sọ pé: “Ọlọ́run tó dá ayé àti gbogbo ohun tó wà nínú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí òun fúnra rẹ̀ ṣe jẹ́ Olúwa ọ̀run àti ayé, kì í gbé inú àwọn tẹ́ńpìlì tí a fi ọwọ́ kọ́.”d (Ìṣe 17:24) Ọ̀run àti ayé ò ṣèèṣì wà. Ọlọ́run tòótọ́ ni Ẹlẹ́dàá ohun gbogbo. (Sm. 146:6) Jèhófà ò dà bí Átẹ́nà àtàwọn òrìṣà yòókù tó jẹ́ pé inú tẹ́ńpìlì, ojúbọ àtàwọn pẹpẹ ló ń pinnu ògo wọn, torí pé tẹ́ńpìlì téèyàn kọ́ ò lè gba Olúwa Ọba Aláṣẹ ọ̀run àti ayé. (1 Ọba 8:27) Ọ̀rọ̀ Pọ́ọ̀lù ò lọ́jú pọ̀ rárá, ohun tó ń sọ ni pé, Ọlọ́run tòótọ́ lágbára ju àwọn òrìṣà táwọn èèyàn ṣe tí wọ́n sì gbé sínú tẹ́ńpìlì.—Àìsá. 40:18-26.
14. Báwo ni Pọ́ọ̀lù ṣe fi hàn pé Ọlọ́run ò gbára lé àwa èèyàn fún ohunkóhun?
14 Ọlọ́run ò retí pé káwọn èèyàn ran òun lọ́wọ́. Àwọn abọ̀rìṣà sábà máa ń wọṣọ olówó ńlá fáwọn ère wọn, wọ́n máa ń fún wọn lẹ́bùn olówó iyebíye, tàbí kí wọ́n fi oúnjẹ àti àwọn ohun mímu rúbọ sí wọn, bí ẹni pé àwọn ère yẹn nílò àwọn nǹkan wọ̀nyẹn. Ó ṣeé ṣe káwọn kan lára àwọn onímọ̀ ọgbọ́n orí ọmọ ilẹ̀ Gíríìkì tó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ Pọ́ọ̀lù mọ̀ pé ọlọ́run ò retí ìrànlọ́wọ́ kankan látọ̀dọ̀ èèyàn. Tọ́rọ̀ bá rí bẹ́ẹ̀, ó ṣeé ṣe kí wọ́n gbà pé òótọ́ lọ̀rọ̀ Pọ́ọ̀lù pé “Ọlọ́run kì í retí pé kí èèyàn ran òun lọ́wọ́ bíi pé ó nílò ohunkóhun.” Torí náà, Ẹlẹ́dàá ò retí ohunkóhun látọ̀dọ̀ àwa èèyàn. Kàkà bẹ́ẹ̀, òun ló ń pèsè gbogbo ohun tá a nílò, bí “ìyè àti èémí àti ohun gbogbo,” tó fi mọ́ oòrùn, òjò àti ilẹ̀ tó ń so éso. (Ìṣe 17:25; Jẹ́n. 2:7) Torí náà, Ọlọ́run tó jẹ́ Olùpèsè kò retí ohunkóhun látọ̀dọ̀ àwa èèyàn.
15. Kí ni Pọ́ọ̀lù sọ fáwọn ará Áténì tí wọ́n gbà pé àwọn dáa ju àwọn tí kì í ṣe Gíríìkì lọ, ẹ̀kọ́ pàtàkì wo la sì lè rí kọ́ látinú àpẹẹrẹ rẹ̀?
15 Ọlọ́run ló dá èèyàn. Èrò àwọn ará Áténì ni pé àwọn dáa ju àwọn tí kì í ṣe Gíríìkì lọ. Àmọ́, Bíbélì jẹ́ ká mọ̀ pé kò yẹ ká máa fi orílẹ̀-èdè wa yangàn tàbí ká máa rò pé ẹ̀yà tiwa ló dáa jù. (Diu. 10:17) Pọ́ọ̀lù wá fọgbọ́n tún òye wọn ṣe lórí ọ̀rọ̀ tó gbẹgẹ́ yìí, ó sọ pé: ‘Láti ara ọkùnrin kan ni Ọlọ́run ti dá gbogbo orílẹ̀-èdè àwọn èèyàn,’ ó dájú pé ohun tí Pọ́ọ̀lù sọ yìí mú káwọn tí wọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ ronú jinlẹ̀. (Ìṣe 17:26) Ohun tí Jẹ́nẹ́sísì sọ nípa Ádámù, tó jẹ́ baba ńlá gbogbo èèyàn ló ń tọ́ka sí. (Jẹ́n. 1:26-28) Níwọ̀n bó ti jẹ́ pé ọ̀dọ̀ ẹnì kan náà ni gbogbo èèyàn ti wá, kò sí ẹ̀yà tàbí orílẹ̀-èdè tó dáa ju òmíì lọ. Torí náà, ó dájú pé àwọn tí Pọ́ọ̀lù ń bá sọ̀rọ̀ á lóye ohun tó ń sọ. Àpẹẹrẹ Pọ́ọ̀lù kọ́ wa ní ẹ̀kọ́ pàtàkì kan pé, bá a ṣe ń sapá láti lo ọgbọ́n àti òye lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù tá à ń ṣe, a ò gbọ́dọ̀ bomi la òtítọ́ tó wà nínú Bíbélì torí káwọn èèyàn lè gbọ́rọ̀ wa.
16. Kí ni Ẹlẹ́dàá fẹ́ káwọn èèyàn ṣe?
16 Ọlọ́run ò fẹ́ káwọn èèyàn jìnnà sóun. Táwọn onímọ̀ ọgbọ́n orí tó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ Pọ́ọ̀lù bá tiẹ̀ ti ń sọ̀rọ̀ nípa ìdí téèyàn fi wà láàyè fún ọ̀pọ̀ ọdún, wọn ò lè ṣàlàyé lọ́nà tó fi máa yéni. Àmọ́, Pọ́ọ̀lù ṣàlàyé tó yéni yékéyéké nípa ìdí tí Ẹlẹ́dàá fi dá èèyàn, ìyẹn ni pé kí wọ́n “máa wá Ọlọ́run, tí wọ́n bá lè táràrà fún un, kí wọ́n sì rí i ní ti gidi, bó tilẹ̀ jẹ́ pé, ní tòótọ́, kò jìnnà sí ẹnì kọ̀ọ̀kan wa.” (Ìṣe 17:27) Ó dájú pé Ọlọ́run táwọn ará Áténì ò mọ̀ yẹn, ṣeé mọ̀ ní ti gidi. Ìyẹn ló fi jẹ́ pé, kò jìnnà sáwọn tó fẹ́ mọ̀ ọ́n, tí wọ́n sì fẹ́ kẹ́kọ̀ọ́ nípa rẹ̀. (Sm. 145:18) Ẹ kíyè sí i pé Pọ́ọ̀lù lo ọ̀rọ̀ náà “wa,” ó ṣe bẹ́ẹ̀ kó lè fi hàn pé òun náà wà lára àwọn tó yẹ kí wọ́n “máa wá” Ọlọ́run, kí wọ́n sì máa “táràrà fún un.”
17, 18. Kí nìdí tó fi yẹ káwọn èèyàn fẹ́ láti sún mọ́ Ọlọ́run, kí la sì lè rí kọ́ látinú bí Pọ́ọ̀lù ṣe jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ̀ wọ àwọn tó ń bá sọ̀rọ̀ lọ́kàn?
17 Ó yẹ káwọn èèyàn fẹ́ láti sún mọ́ Ọlọ́run. Pọ́ọ̀lù sọ pé, nípasẹ̀ Ọlọ́run ni “a fi ní ìyè, tí à ń rìn, tí a sì wà.” Àwọn ọ̀mọ̀wé kan sọ pé ọ̀rọ̀ Epimenides, ìyẹn akéwì ọmọ ilẹ̀ Kírétè tó gbáyé ní ọgọ́rùn-ún ọdún kẹfà ṣáájú Sànmánì Kristẹni ni Pọ́ọ̀lù ń tọ́ka sí, “àwọn ará Áténì ò sì kóyán rẹ̀ kéré nínú ààtò ẹ̀sìn wọn.” Pọ́ọ̀lù tún sọ ìdí míì tó fi yẹ kéèyàn fẹ́ láti sún mọ́ Ọlọ́run, ó sọ pé: “Bí ọ̀rọ̀ àwọn kan lára àwọn akéwì yín tó sọ pé, ‘Nítorí àwa náà jẹ́ ọmọ rẹ̀.’ ” (Ìṣe 17:28) Àwa èèyàn gbọ́dọ̀ máa wo ara wa bí ẹni tó ní àjọṣe tímọ́tímọ́ pẹ̀lú Ọlọ́run, torí pé òun ló dá baba ńlá wa. Kí ọ̀rọ̀ Pọ́ọ̀lù lè wọ àwọn tó ń bá sọ̀rọ̀ lọ́kàn, ó fa ọ̀rọ̀ yọ ní tààràtà látinú ìwé Gíríìkì tí kò sí àní-àní pé àwọn tó ń bá sọ̀rọ̀ náà mọ̀ nípa ẹ̀.e Bíi ti Pọ́ọ̀lù, lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan, àwa náà lè fa ọ̀rọ̀ yọ látinú àwọn ìwé ìtàn, ìwé gbédègbẹ́yọ̀, tàbí àwọn ìwé míì téèyàn lè ṣèwádìí nínú ẹ̀. Bí àpẹẹrẹ, tá a bá mú ọ̀rọ̀ tó bá ohun tá à ń jíròrò mu látinú ìwé kan táwọn èèyàn fojú pàtàkì wò, ó lè mú kí àwọn tí kì í ṣe Ẹlẹ́rìí Jèhófà yí èrò wọn pa dà nípa àwọn àṣà ẹ̀sìn èké kan tí wọ́n ń lọ́wọ́ sí.
18 Níbi tí Pọ́ọ̀lù bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ dé yìí, ó ti sọ àwọn ohun tó jẹ́ òótọ́ nípa Ọlọ́run, ó sì tún ń fọgbọ́n jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ̀ bá àwọn tó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ mu. Kí ni àpọ́sítélì yìí fẹ́ káwọn ará Áténì ṣe nípa ìsọfúnni pàtàkì yìí? Láìfọ̀rọ̀ falẹ̀, ó sọ fún wọ́n bó ṣe ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ.
“Kí Gbogbo Èèyàn Níbi Gbogbo . . . Ronú Pìwà Dà” (Ìṣe 17:29-31)
19, 20. (a) Báwo ni Pọ́ọ̀lù ṣe lo ọgbọ́n láti fi hàn pé ìwà òmùgọ̀ ni kéèyàn máa jọ́sìn àwọn ère? (b) Kí ló yẹ káwọn tí Pọ́ọ̀lù ń bá sọ̀rọ̀ ṣe?
19 Pọ́ọ̀lù ti ṣe tán láti mú káwọn tó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣiṣẹ́ lórí ohun tí wọ́n gbọ́. Ó rán wọn létí ọ̀rọ̀ tó fà yọ nínú ìwé àwọn Gíríìkì, ó sọ pé: “Nítorí náà, bí a ṣe jẹ́ ọmọ Ọlọ́run, kò yẹ kí a rò pé Olú Ọ̀run rí bíi wúrà tàbí fàdákà tàbí òkúta, bí ohun tí a fi ọgbọ́n àti iṣẹ́ ọnà èèyàn gbẹ́ lére.” (Ìṣe 17:29) Tó bá jẹ́ pé Ọlọ́run ló dá àwọn èèyàn lóòótọ́, báwo ló tún ṣe máa wá jẹ́ pé, òun náà ni ère téèyàn fọwọ́ ara rẹ̀ gbẹ́? Pọ́ọ̀lù lo ọgbọ́n láti fi hàn pé ìwà òmùgọ̀ ló jẹ́ láti máa jọ́sìn àwọn ère táwọn èèyàn ṣe. (Sm. 115:4-8; Àìsá. 44:9-20) Nígbà tí Pọ́ọ̀lù sọ pé “kò yẹ kí a,” ó kó ara ẹ̀ mọ́ àwọn tó ń bá sọ̀rọ̀, ìyẹn ni ò jẹ́ kí ọ̀rọ̀ náà gbòdì lára wọn.
20 Àpọ́sítélì náà wá jẹ́ kó yé wọn pé wọ́n ní láti gbé ìgbésẹ̀, ó sọ pé: “Ọlọ́run ti gbójú fo ìgbà àìmọ̀ yìí [téèyàn ti lè máa ronú pé àwọn tó ń bọ òrìṣà lè tu Ọlọ́run lójú], àmọ́ ní báyìí, ó ń sọ fún gbogbo èèyàn níbi gbogbo pé kí wọ́n ronú pìwà dà.” (Ìṣe 17:30) Ó ṣeé ṣe kí àyà àwọn kan lára àwọn tí Pọ́ọ̀lù ń bá sọ̀rọ̀ já nígbà tó sọ pé kí wọ́n ronú pìwà dà. Àmọ́ ọ̀rọ̀ pàtàkì tó bá wọn sọ jẹ́ kí wọ́n mọ̀ pé Ọlọ́run ló dá wọn, Òun ni wọ́n sì máa jíhìn fún. Ó pọn dandan pé kí wọ́n wá Ọlọ́run, kí wọ́n kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́ nípa rẹ̀, kí wọ́n sì máa gbé ìgbé ayé wọn níbàámu pẹ̀lú ohun tí wọ́n kọ́. Ohun tí èyí túmọ̀ sí fáwọn ará Áténì yìí ni pé kí wọ́n mọ̀ pé ohun táwọn ń ṣe ò dáa, kí wọ́n sì jáwọ́ nínú ìbọ̀rìṣà.
21, 22. Ọ̀rọ̀ pàtàkì wo ni Pọ́ọ̀lù fi parí ìwàásù ẹ̀, kí la sì lè kọ́ látinú ohun tó sọ?
21 Ọ̀rọ̀ pàtàkì tí Pọ́ọ̀lù fi parí ìwàásù ẹ̀ ni pé: “[Ọlọ́run] ti dá ọjọ́ kan tó máa fi òdodo ṣèdájọ́ ayé láti ọwọ́ ọkùnrin kan tó ti yàn, ó sì ti pèsè ẹ̀rí tó dájú fún gbogbo èèyàn bó ṣe jí i dìde kúrò nínú ikú.” (Ìṣe 17:31) Ọjọ́ Ìdájọ́ kan ń bọ̀ kẹ̀? Ẹ ò rí i pé ìdí tó ṣe pàtàkì lèyí jẹ́ fún wọn láti wá Ọlọ́run tòótọ́, kí wọ́n sì mọ̀ ọ́n! Pọ́ọ̀lù ò dárúkọ Onídàájọ́ tí Ọlọ́run ti yàn náà. Kàkà bẹ́ẹ̀, ó sọ ohun kan tó yà wọ́n lẹ́nu nípa Onídàájọ́ náà pé: Ó ti gbé ayé bí èèyàn, ó kú, Ọlọ́run sì jí i dìde!
22 Ọ̀pọ̀ ẹ̀kọ́ la lè rí kọ́ nínú ọ̀rọ̀ tó wọni lọ́kàn tí Pọ́ọ̀lù fi parí ìwàásù rẹ̀ yìí. A mọ̀ pé Jésù Kristi tó ti jíǹde ni Onídàájọ́ tí Ọlọ́run yàn. (Jòh. 5:22) A tún mọ̀ pé ẹgbẹ̀rún ọdún ni Ọjọ́ Ìdájọ́ náà máa jẹ́, ó sì ń yára sún mọ́lé. (Ìfi. 20:4, 6) A ò bẹ̀rù Ọjọ́ Ìdájọ́, torí a mọ̀ pé ìbùkún àgbàyanu ló máa mú wá fáwọn olóòótọ́. Àjíǹde Jésù Kristi ni iṣẹ́ ìyanu tó lágbára jù lọ, ó sì jẹ́ ẹ̀rí pé àwọn ohun àgbàyanu tí Ọlọ́run ti ṣèlérí fáwọn olóòótọ́ máa ṣẹlẹ̀ lóòótọ́!
‘Àwọn Kan Di Onígbàgbọ́’ (Ìṣe 17:32-34)
23. Kí làwọn èèyàn ṣe nígbà tí wọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ Pọ́ọ̀lù?
23 Lẹ́yìn tí Pọ́ọ̀lù bá àwọn èèyàn yẹn sọ̀rọ̀, ohun tí wọ́n ṣe yàtọ̀ síra. “Àwọn kan bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe yẹ̀yẹ” nígbà tí wọ́n gbọ́ nípa àjíǹde. Àwọn kan ní tiwọn ò ṣe yẹ̀yẹ́, àmọ́ wọn ò mọ ohun tí wọn máa ṣe, wọ́n ní: “A máa gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí lẹ́nu rẹ nígbà míì.” (Ìṣe 17:32) Àmọ́ àwọn kan gbọ́, wọ́n sì gbà. Bíbélì sọ nípa wọn pé: “Àwọn kan dara pọ̀ mọ́ ọn, wọ́n sì di onígbàgbọ́. Lára wọn ni Díónísíù tó jẹ́ adájọ́ ní kọ́ọ̀tù Áréópágù àti obìnrin kan tó ń jẹ́ Dámárì pẹ̀lú àwọn míì.” (Ìṣe 17:34) Bí wọ́n ṣe máa ń ṣe sáwa náà nìyẹn tá a bá wà lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù. Àwọn kan lè fi wá ṣe yẹ̀yẹ́, bẹ́ẹ̀ sì rèé àwọn kan lè má fi wá ṣe yẹ̀yẹ́, àmọ́ wọ́n lè má fẹ́ gbọ́. Àmọ́, inú wa máa ń dùn táwọn kan bá gbọ́ ìwàásù wa, tí wọ́n sì kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́.
24. Kí la lè rí kọ́ nínú ọ̀rọ̀ tí Pọ́ọ̀lù sọ ní Áréópágù?
24 Tá a bá ń ronú lórí ọ̀rọ̀ Pọ́ọ̀lù, ìyẹn á jẹ́ ká lè mọ bá a ṣe lè ṣàlàyé ọ̀rọ̀ fáwọn èèyàn lọ́nà táá fi wọ̀ wọ́n lọ́kàn, táá sì tún jẹ́ kó dá wọn lójú pé òtítọ́ là ń kọ́ wọn. Yàtọ̀ síyẹn, a lè kọ́ bá a ṣe lè ní sùúrù ká sì lo ọgbọ́n pẹ̀lú àwọn tí wọ́n gba ẹ̀kọ́ èké gbọ́. A tún kọ́ ẹ̀kọ́ pàtàkì míì pé: A ò gbọ́dọ̀ bomi la ọ̀rọ̀ òtítọ́ Bíbélì torí káwọn èèyàn lè gbọ́ wa. Torí náà, tá a bá ń tẹ̀ lé àpẹẹrẹ àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù, ìyẹn á jẹ́ ká di olùkọ́ tó mọ̀ọ̀yàn kọ́ dáadáa lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù. Láfikún sí i, àpẹẹrẹ yìí lè ran àwọn alábòójútó lọ́wọ́ láti di olùkọ́ tó kúnjú ìwọ̀n nínú ìjọ. Ìyẹn á sì jẹ́ ká ṣe tán láti ran àwọn èèyàn lọ́wọ́ kí wọ́n lè “wá Ọlọ́run, . . . kí wọ́n sì rí i ní ti gidi.”—Ìṣe 17:27.
a Wo àpótí náà, “Ìlú Áténì—Ojúkò Àṣà Ìṣẹ̀ǹbáyé Láyé Àtijọ́.”
b Wo àpótí náà, “Àwọn Epikúríà Àtàwọn Sítọ́íkì.”
c Téńté ìlú Áténì, lápá àríwá ìwọ̀ oòrùn, ni Áréópágù wà, ibẹ̀ sì ni ìgbìmọ̀ alákòóso ìlú Áténì ti máa ń ṣe àpérò. Ó ṣeé ṣe kí “Áréópágù” túmọ̀ sí ìgbìmọ̀ alákòóso tàbí kó jẹ́ pé òkè tí wọ́n ti ń ṣe àpérò náà ló ń jẹ́ bẹ́ẹ̀. Torí náà, èrò àwọn ọ̀mọ̀wé ò ṣọ̀kan lórí ibi tí wọ́n mú Pọ́ọ̀lù lọ, bóyá ìtòsí òkè kékeré yìí ni o tàbí orí òkè náà gan-an, tàbí ibi táwọn ìgbìmọ̀ alákòóso ti máa ń pàdé lápá ibòmíì níbi ọjà.
d Ọ̀rọ̀ Gíríìkì tá a túmọ̀ sí “ayé” lédè Yorùbá ni koʹsmos, èèyàn làwọn Gíríìkì sì sábà máa ń lo ọ̀rọ̀ náà fún. Nígbà tí Pọ́ọ̀lù lo ọ̀rọ̀ yìí, ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé àwọn èèyàn ló ní lọ́kàn, kí ìjíròrò rẹ̀ pẹ̀lú àwọn Gíríìkì lè máa bá a lọ.
e Pọ́ọ̀lù fa ọ̀rọ̀ yọ látinú àwọn ewì nípa ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ sánmà, ìyẹn Phaenomena, tí akéwì onímọ̀ ọgbọ́n orí Sítọ́íkì náà Aratus kọ. Lára àwọn ọ̀rọ̀ yìí wà nínú àwọn ìwé míì táwọn Gíríìkì kọ, títí kan ìwé orin tí wọ́n pè ní Hymn to Zeus, tí onímọ̀ ọgbọ́n orí Sítọ́íkì náà Cleanthes kọ.
-
-
“Máa Sọ̀rọ̀ Nìṣó, Má sì Dákẹ́”“Jẹ́rìí Kúnnákúnná Nípa Ìjọba Ọlọ́run”
-
-
ORÍ 19
“Máa Sọ̀rọ̀ Nìṣó, Má sì Dákẹ́”
Pọ́ọ̀lù ṣiṣẹ́, àmọ́ iṣẹ́ ìwàásù ló fi sípò àkọ́kọ́
Ó dá lórí Ìṣe 18:1-22
1-3. Kí nìdí tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù fi lọ sí ìlú Kọ́ríńtì, àwọn ipò wo ló sì bá ara ẹ̀?
NÍ APÁ ìparí ọdún 50 Sànmánì Kristẹni, àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù wà nílùú Kọ́ríńtì. Ojúkò ìṣòwò ni ìlú Kọ́ríńtì, àwọn ará ibẹ̀ lọ́rọ̀, ọ̀pọ̀ èèyàn ló sì máa ń wá ṣe káràkátà níbẹ̀, kódà ọ̀pọ̀ àwọn Gíríìkì, àwọn ará Róòmù àtàwọn Júù ló ń gbébẹ̀.a Àmọ́, kì í ṣe pé Pọ́ọ̀lù lọ síbẹ̀ láti lọ ṣòwò, bẹ́ẹ̀ sì ni kò wáṣẹ́ lọ. Ohun tó gbé e wá sílùú Kọ́ríńtì ṣe pàtàkì jùyẹn lọ, ṣe ló lọ síbẹ̀ láti lọ wàásù ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run. Síbẹ̀, Pọ́ọ̀lù nílò ibi táá máa gbé, ó sì ti pinnu pé òun ò ní torí ìyẹn di ẹrù ìnáwó ru ẹnikẹ́ni. Kò fẹ́ kí ẹnikẹ́ni rò pé òun retí kí wọ́n máa fowó ṣètìlẹyìn fún òun, torí pé òun ń wàásù ọ̀rọ̀ Ọlọ́run. Kí ló máa wá ṣe báyìí?
2 Iṣẹ́ ọwọ́ kan wà tí Pọ́ọ̀lù mọ̀ dáadáa, ìyẹn ni iṣẹ́ àgọ́ pípa. Àgọ́ pípa ò rọrùn, àmọ́ ó fẹ́ ṣiṣẹ́ kó lè máa rówó gbọ́ bùkátà ara ẹ̀. Ṣó máa ríṣẹ́ ṣe nílùú térò ti pọ̀ bí omi yìí? Ṣó máa rí ilé tó dáa, táá sì tẹ́ ẹ lọ́rùn gbé? Bó tiẹ̀ jẹ́ pé àwọn ipò tí Pọ́ọ̀lù bá ara rẹ̀ yìí kò rọrùn, kò gbàgbé iṣẹ́ pàtàkì tó gbé e dé ìlú Kọ́ríńtì, ìyẹn iṣẹ́ ìwàásù.
3 Pọ́ọ̀lù gbé ní Kọ́ríńtì fún àkókò díẹ̀, iṣẹ́ ìwàásù tó ṣe níbẹ̀ sì yọrí sí rere. Kí la lè kọ́ nínú ohun tí Pọ́ọ̀lù ṣe nígbà tó wà nílùú Kọ́ríńtì tó máa ràn wá lọ́wọ́ láti jẹ́rìí kúnnákúnná nípa Ìjọba Ọlọ́run ní ìpínlẹ̀ ìwàásù wa?
“Iṣẹ́ Àgọ́ Pípa Ni Wọ́n Ń Ṣe” (Ìṣe 18:1-4)
4, 5. (a) Ibo ni Pọ́ọ̀lù ń gbé nígbà tó wà ní Kọ́ríńtì, iṣẹ́ wo ló sì fi ń gbọ́ bùkátà ara ẹ̀? (b) Báwo ni Pọ́ọ̀lù ṣe dẹni tó mọ̀ nípa iṣẹ́ àgọ́ pípa?
4 Kò pẹ́ tí Pọ́ọ̀lù dé ìlú Kọ́ríńtì tó fi rí tọkọtaya Júù kan tó lawọ́, ìyẹn Ákúílà àti ìyàwó rẹ̀ Pírísílà, tàbí Pírísíkà. Àṣẹ tí Olú Ọba Kíláúdíù pa, pé kí “àwọn Júù kúrò ní Róòmù,” ló mú kí tọkọtaya náà wá máa gbé nílùú Kọ́ríńtì. (Ìṣe 18:1, 2) Ákúílà àti Pírísílà gba Pọ́ọ̀lù sínú ilé wọn, wọ́n sì tún jẹ́ kó bá àwọn ṣiṣẹ́. Bíbélì sọ pé: “Torí pé iṣẹ́ kan náà ni wọ́n jọ ń ṣe, ó [Pọ́ọ̀lù] dúró sí ilé wọn, ó sì ń bá wọn ṣiṣẹ́, torí iṣẹ́ àgọ́ pípa ni wọ́n ń ṣe.” (Ìṣe 18:3) Bó ṣe di pé ilé àwọn tọkọtaya tó jẹ́ onínúure àti ọ̀làwọ́ yìí ni Pọ́ọ̀lù ń gbé nìyẹn ní gbogbo ìgbà tó fi wàásù nílùú Kọ́ríńtì. Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ìgbà tí Pọ́ọ̀lù ń gbé pẹ̀lú Ákúílà àti Pírísílà ló kọ àwọn lẹ́tà tó wá di apá kan Bíbélì lónìí.b
5 Báwo ni Pọ́ọ̀lù, ọkùnrin tó gba ẹ̀kọ́ “lọ́dọ̀ Gàmálíẹ́lì,” ṣe wá di ẹni tó ń pàgọ́? (Ìṣe 22:3) Kì í ṣe ohun ìtìjú fáwọn Júù tó gbáyé ní ọgọ́rùn-ún ọdún kìíní láti fi iṣẹ́ ọwọ́ tí wọ́n mọ̀ kọ́ àwọn ọmọ wọn, kódà táwọn ọmọ bẹ́ẹ̀ bá tiẹ̀ kàwé. Aṣọ àgọ́ tí wọ́n ń pè ní cilicium pọ̀ ní ìlú Tásù ní Sìlíṣíà, torí pé ibẹ̀ ni Pọ́ọ̀lù sì ti wá, àfàìmọ̀ kó má jẹ́ pé àtikékeré ni wọ́n ti kọ́ ọ níṣẹ́ àgọ́ pípa. Báwo ni wọ́n ṣe ń pàgọ́? Tí wọ́n bá fẹ́ pa àgọ́, ṣe ni wọ́n máa ń hun aṣọ tàbí kí wọ́n gé àwọn aṣọ tó le bíi tapólì, kí wọ́n sì rán an láti fi ṣe àgọ́. Lọ́rọ̀ kan ṣá, iṣẹ́ tó le ni.
6, 7. (a) Ojú wo ni Pọ́ọ̀lù fi wo àgọ́ pípa, kí ló sì fi hàn pé irú ojú tí Ákúílà àti Pírísílà náà fi wò ó nìyẹn? (b) Báwo làwọn Kristẹni lónìí ṣe ń tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Pọ́ọ̀lù, Ákúílà àti Pírísílà?
6 Iṣẹ́ àgọ́ pípa kọ́ ló ṣe pàtàkì jù sí Pọ́ọ̀lù. Àmọ́, ó ń ṣe é láti gbọ́ bùkátà ara ẹ̀ bó ṣe ń ṣe iṣẹ́ ìwàásù, tó sì ń kéde ìhìn rere “lọ́fẹ̀ẹ́.” (2 Kọ́r. 11:7) Ojú wo ni Ákúílà àti Pírísílà fi wo iṣẹ́ àgọ́ pípa? Kristẹni làwọn náà, torí náà, ó dájú pé ojú tí Pọ́ọ̀lù fi wò ó làwọn náà fi wò ó. Kódà, nígbà tí Pọ́ọ̀lù kúrò ní Kọ́ríńtì lọ́dún 52 Sànmánì Kristẹni, Ákúílà àti Pírísílà fi iṣẹ́ wọn sílẹ̀, wọ́n sì tẹ̀ lé e lọ sí Éfésù. Ilé tí wọ́n ń gbé sì ni ìjọ tó sún mọ́ wọn ti ń ṣèpàdé. (1 Kọ́r. 16:19) Nígbà tó yá, wọ́n pa dà sí Róòmù, lẹ́yìn náà wọ́n tún pa dà sí Éfésù. Àwọn tọkọtaya tó nítara yìí fi àwọn nǹkan tó jẹ mọ́ ìjọsìn Ọlọ́run àti iṣẹ́ ìwàásù sí ipò àkọ́kọ́, wọ́n sì ń yọ̀ǹda ara wọn kí wọ́n lè ran àwọn míì lọ́wọ́, “gbogbo ìjọ àwọn orílẹ̀-èdè” sì ń dúpẹ́ lọ́wọ́ wọn.—Róòmù 16:3-5; 2 Tím. 4:19.
7 Lónìí, àwọn Kristẹni máa ń tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Pọ́ọ̀lù, Ákúílà àti Pírísílà. Àwọn ará tí wọ́n ń fìtara wàásù máa ń ṣiṣẹ́ kára kí wọ́n má bàa “di ẹrù wọ” àwọn míì lọ́rùn. (1 Tẹs. 2:9) Ohun tó wúni lórí ni pé ọ̀pọ̀ àwọn tó ń fi àkókò tó pọ̀ wàásù ló ń ṣe iṣẹ́ tí kò fi bẹ́ẹ̀ gba àkókò kí wọ́n lè máa fi gbọ́ bùkátà ara wọn. Ìyẹn sì ń jẹ́ kí wọ́n lè máa bá iṣẹ́ náà nìṣó. Bíi ti Ákúílà àti Pírísílà, ọ̀pọ̀ àwọn ìránṣẹ́ Jèhófà ló fẹ́ràn láti máa ṣàlejò, kódà wọ́n máa ń gba àwọn alábòójútó àyíká sílé wọn. Àwọn tó bá sì ń “ṣe aájò àlejò” máa ń rí ìṣírí gbà, wọ́n sì máa ń láyọ̀.—Róòmù 12:13.
“Ọ̀pọ̀ Àwọn Ará Kọ́ríńtì . . . Bẹ̀rẹ̀ Sí Í Gbà Gbọ́” (Ìṣe 18:5-8)
8, 9. Kí ni Pọ́ọ̀lù ṣe nígbà táwọn Júù tó fìtara wàásù fún ń ṣàtakò sí i, ibo ló sì ti lọ wàásù lẹ́yìn náà?
8 Bí Sílà àti Tímótì ṣe kó ẹ̀bùn wá fún Pọ́ọ̀lù ní Makedóníà fí hàn pé kì í ṣe gbogbo àkókò ẹ̀ ló fi ń ṣiṣẹ́ àgọ́ pípa, àmọ́ ó ń ṣe é kó lè fi gbọ́ bùkátà ara ẹ̀. (2 Kọ́r. 11:9) Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, “ọ̀rọ̀ Ọlọ́run mú kí ọwọ́ Pọ́ọ̀lù dí gan-an [Pọ́ọ̀lù “fi gbogbo àkókò rẹ̀ sílẹ̀ fún iwaasu,” Bíbélì Ìròhìn Ayọ̀].” (Ìṣe 18:5) Àmọ́, bó ṣe ń fìtara wàásù fáwọn Júù, ṣe ni wọ́n ń ṣenúnibíni sí i ṣáà. Wọn ò gbà gbọ́ pé Kristi lè gbà wọ́n là. Kí Pọ́ọ̀lù lè fi hàn pé òun ò lẹ́bi, ó gbọn ẹ̀wù rẹ̀, ó sì sọ fáwọn Júù tó ń ṣàtakò sí i pé: “Kí ẹ̀jẹ̀ yín wà lórí ẹ̀yin fúnra yín. Ọrùn mi mọ́. Láti ìsinsìnyí lọ, màá lọ máa bá àwọn èèyàn orílẹ̀-èdè.”—Ìṣe 18:6; Ìsík. 3:18, 19.
9 Ibo ni Pọ́ọ̀lù á ti lọ wàásù báyìí o? Ọkùnrin kan tó ń jẹ́ Títíọ́sì Jọ́sítù, tó ṣeé ṣe kó jẹ́ aláwọ̀ṣe Júù tí ilé ẹ̀ wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ sínágọ́gù gba Pọ́ọ̀lù sílé rẹ̀. Torí náà, Pọ́ọ̀lù kúrò ní sínágọ́gù, ó sì lọ sílé Jọ́sítù. (Ìṣe 18:7) Ilé Ákúílà àti Pírísílà ni Pọ́ọ̀lù ń gbé ní gbogbo ìgbà tó fi wà ní Kọ́ríńtì, àmọ́ ilé Jọ́sítù ló ti ń ṣe iṣẹ́ ìwàásù.
10. Kí ló fi hàn pé kì í ṣe àwọn èèyàn orílẹ̀-èdè nìkan ni Pọ́ọ̀lù ṣe tán láti wàásù fún?
10 Ṣé ọ̀rọ̀ tí Pọ́ọ̀lù sọ pé òun máa lọ bá àwọn èèyàn orílẹ̀-èdè túmọ̀ sí pé ó jáwọ́ pátápátá lọ́rọ̀ gbogbo àwọn Júù àtàwọn aláwọ̀ṣe, títí kan àwọn tó gbọ́ ìwàásù ẹ̀? Rárá o. Bí àpẹẹrẹ, “Kírípọ́sì, alága sínágọ́gù, di onígbàgbọ́ nínú Olúwa, òun pẹ̀lú gbogbo agbo ilé rẹ.” Ẹ̀rí fi hàn pé ọ̀pọ̀ lára àwọn tó wà nínú sínágọ́gù náà dara pọ̀ mọ́ Kírípọ́sì, torí Bíbélì sọ pé: “Ọ̀pọ̀ àwọn ará Kọ́ríńtì tí wọ́n gbọ́ bẹ̀rẹ̀ sí í gbà gbọ́, wọ́n sì ṣèrìbọmi.” (Ìṣe 18:8) Torí náà, ilé Títíọ́sì Jọ́sítù di ibi táwọn ará tó wà ní ìjọ tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ dá sílẹ̀ nílùú Kọ́ríńtì ti ń pàdé. Tó bá jẹ́ pé ọ̀nà tí Lúùkù gbà ń kọ̀wé ló gbà kọ ìwé Ìṣe, ìyẹn bó ṣe máa ń to àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ bó ṣe tẹ̀ léra, a jẹ́ pé lẹ́yìn tí Pọ́ọ̀lù gbọn ẹ̀wù rẹ̀ làwọn Júù tàbí àwọn aláwọ̀ṣe yẹn yí pa dà di Kristẹni. Ohun tó ṣẹlẹ̀ yìí fi hàn pé àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù múra tán láti ṣe àwọn àyípadà tó bá yẹ kó lè wàásù fáwọn tó ṣe tán láti gbọ́.
11. Báwo làwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà lónìí ṣe ń tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Pọ́ọ̀lù bí wọ́n ṣe ń wàásù fáwọn oníṣọ́ọ̀ṣì?
11 Ní ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè lónìí, àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ti pọ̀ gan-an, ohunkóhun tí wọ́n bá sì sọ làwọn ọmọ ìjọ wọn máa ń ṣe. Láwọn ilẹ̀ kan, àwọn míṣọ́nnárì táwọn oníṣọ́ọ̀ṣì rán jáde ti yí ọ̀pọ̀ èèyàn lọ́kàn pa dà. Ọ̀pọ̀ àwọn tí wọ́n pera wọn ní Kristẹni ló ṣì máa ń tẹ̀ lé àṣà àtọwọ́dọ́wọ́ bíi tàwọn Júù tó wà nílùú Kọ́ríńtì ní ọgọ́rùn-ún ọdún kìíní. Àmọ́ bíi ti Pọ́ọ̀lù, àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń fìtara wàásù fáwọn èèyàn, a sì ń ràn wọ́n lọ́wọ́ kí wọ́n lè lóye ohun tí wọ́n ti kà nínú Ìwé Mímọ́. Kódà, bí wọ́n bá ta kò wá tàbí tí àwọn aṣáájú ẹ̀sìn wọn bá ṣenúnibíni sí wa, a kì í jẹ́ kó sú wa. Ọ̀pọ̀ èèyàn ló fẹ́ mọ òtítọ́ nípa Ọlọ́run. Wọ́n “ní ìtara fún Ọlọ́run, àmọ́ kì í ṣe pẹ̀lú ìmọ̀ tó péye,” torí náà ó yẹ ká wá wọn lọ.—Róòmù 10:2.
“Mo Ní Ọ̀pọ̀ Èèyàn ní Ìlú Yìí” (Ìṣe 18:9-17)
12. Kí ni Jésù fi dá Pọ́ọ̀lù lójú nínú ìran?
12 Tí Pọ́ọ̀lù bá tiẹ̀ ti ń ṣiyè méjì tẹ́lẹ̀ nípa bóyá kóun máa bá iṣẹ́ òjíṣẹ́ òun lọ ní Kọ́ríńtì, ó dájú pé kò ní ṣiyè méjì mọ́ lálẹ́ ọjọ́ tí Jésù Olúwa fara hàn án nínú ìran, tó sì sọ fún un pé: “Má bẹ̀rù, máa sọ̀rọ̀ nìṣó, má sì dákẹ́, torí mo wà pẹ̀lú rẹ, ẹnikẹ́ni ò ní kọ lù ọ́ láti ṣe ọ́ léṣe; nítorí mo ní ọ̀pọ̀ èèyàn ní ìlú yìí.” (Ìṣe 18:9, 10) Ìran yẹn á mà fún un níṣìírí gan-an ni o! Jésù Olúwa fúnra rẹ̀ fi dá Pọ́ọ̀lù lójú pé òun á dáàbò bò ó lọ́wọ́ àwọn tó bá fẹ́ ṣe é léṣe àti pé ọ̀pọ̀ àwọn olóòótọ́ ọkàn ló ṣì wà ní ìlú yẹn. Kí ni Pọ́ọ̀lù ṣe lẹ́yìn tó rí ìran náà? Bíbélì sọ pé: “Ó lo ọdún kan àti oṣù mẹ́fà níbẹ̀, ó ń kọ́ni ní ọ̀rọ̀ Ọlọ́run láàárín wọn.”—Ìṣe 18:11.
13. Ìṣẹ̀lẹ̀ wo ló ṣeé ṣe kí Pọ́ọ̀lù rántí nígbà tó débi ìjókòó ìdájọ́, àmọ́ kí ló fi í lọ́kàn balẹ̀ pé wọn ò ní pa òun?
13 Lẹ́yìn tí Pọ́ọ̀lù ti lo nǹkan bí ọdún kan nílùú Kọ́ríńtì, ó rí ẹ̀rí míì tó fi hàn pé Olúwa wà pẹ̀lú òun. Bíbélì sọ pé: “Àwọn Júù gbìmọ̀ pọ̀, wọ́n dìde sí Pọ́ọ̀lù, wọ́n sì mú un lọ síwájú ìjókòó ìdájọ́,” tí wọ́n ń pè ní beʹma. (Ìṣe 18:12) Àwọn kan sọ pé beʹma tàbí ìjókòó ìdájọ́ yìí jẹ́ pèpéle gíga tó ṣeé ṣe kó wà ní àárín ọjà Kọ́ríńtì. Òkúta iyebíye aláwọ̀ búlúù àti funfun ni wọ́n fi ṣe é, wọ́n sì gbẹ́ àwọn àwòrán tó rẹwà sí i lára. Àyè tó wà níwájú ẹ̀ fẹ̀, ó lè gba èèyàn tó pọ̀. Ìwádìí táwọn awalẹ̀pìtàn ṣe fi hàn pé ìjókòó ìdájọ́ náà ò jìnnà sí sínágọ́gù àti sí ilé Jọ́sítù. Bí Pọ́ọ̀lù ṣe dé ibi ìjókòó ìdájọ́ yìí, ó ṣeé ṣe kó rántí bí wọ́n ṣe sọ Sítéfánù lókùúta. Sítéfánù yìí làwọn èèyàn mọ̀ sí ẹni àkọ́kọ́ tí wọ́n pa torí pé ó jẹ́ ẹlẹ́rìí Jésù. Pọ́ọ̀lù, tó ń jẹ́ Sọ́ọ̀lù nígbà yẹn, “fọwọ́ sí bí wọ́n ṣe pa Sítéfánù.” (Ìṣe 8:1) Ṣé ohun tó máa ṣẹlẹ̀ sóun náà nìyẹn? Rárá o, torí Jésù ti ṣèlérí fún un pé: “Ẹnikẹ́ni ò ní . . . ṣe ọ́ léṣe.”—Ìṣe 18:10.
“Ló bá lé wọn kúrò níbi ìjókòó ìdájọ́.”—Ìṣe 18:16
14, 15. (a) Ẹ̀sùn wo làwọn Júù fi kan Pọ́ọ̀lù, kí ló sì fà á tí Gálíò fi tú ẹjọ́ náà ká? (b) Kí ló ṣẹlẹ̀ sí Sótínésì, kí sì nìdí tá a fi rò pé ó ṣeé ṣe kó di Kristẹni?
14 Kí ló ṣẹlẹ̀ nígbà tí Pọ́ọ̀lù débi ìjókòó ìdájọ́? Gálíò tó jẹ́ alákòóso ìbílẹ̀ ìlú Ákáyà ni adájọ́ nígbà yẹn, òun ni ẹ̀gbọ́n Seneca tó jẹ́ onímọ̀ èrò orí ìlú Róòmù. Àwọn Júù fẹ̀sùn kan Pọ́ọ̀lù pé: “Ọkùnrin yìí ń yí àwọn èèyàn lérò pa dà láti máa sin Ọlọ́run lọ́nà tó ta ko òfin.” (Ìṣe 18:13) Ohun táwọn Júù yìí ń sọ ni pé ṣe ni Pọ́ọ̀lù ń sọ àwọn èèyàn di Kristẹni, èyí ò sì bófin mu. Àmọ́, Gálíò rí i pé Pọ́ọ̀lù ò hùwà “àìtọ́” rárá, kò sì jẹ̀bi “ìwà ọ̀daràn” kankan. (Ìṣe 18:14) Gálíò kò fẹ́ bá àwọn Júù yẹn fa ọ̀rọ̀, kò sì fẹ́ bá wọn jiyàn. Kódà, Pọ́ọ̀lù ò tiẹ̀ tíì sọ̀rọ̀ kankan láti gbèjà ara ẹ̀ tí Gálíò ti tú ẹjọ́ náà ká! Inú bí àwọn tó fẹ̀sùn kan Pọ́ọ̀lù gan-an. Wọ́n kanra mọ́ Sótínésì, tó ṣeé ṣe kó jẹ́ ẹni tó gbapò alága sínágọ́gù lọ́wọ́ Kírípọ́sì. Wọ́n gbá a mú, “wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í lù ú níwájú ìjókòó ìdájọ́.”—Ìṣe 18:17.
15 Kí nìdí tí Gálíò kò fi dá sí i nígbà táwọn èèyàn náà ń lu Sótínésì? Bóyá Gálíò rò pé Sótínésì ló wà lẹ́yìn àwọn tó ń ta ko Pọ́ọ̀lù àti pé ṣe ló ń jìyà ohun tó ṣe. Èyí ó wù kó jẹ́, ó jọ pé ọ̀rọ̀ náà yọrí sí rere. Lọ́dún mélòó kan lẹ́yìn náà, nínú lẹ́tà àkọ́kọ́ tí Pọ́ọ̀lù kọ sí ìjọ Kọ́ríńtì, ó dárúkọ arákùnrin kan tó ń jẹ́ Sótínésì. (1 Kọ́r. 1:1, 2) Ṣé Sótínésì kan náà táwọn ará Kọ́ríńtì lù yẹn ni? Tó bá jẹ́ òun ni, ó lè jẹ́ pé ohun tí wọ́n fojú ẹ̀ rí ló mú kó di Kristẹni.
16. Báwo ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ pé, “máa sọ̀rọ̀ nìṣó, má sì dákẹ́, torí mo wà pẹ̀lú rẹ,” ṣe ń fún wa lókun lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa?
16 Rántí pé lẹ́yìn táwọn Júù kọ̀ láti gbọ́ ìwàásù Pọ́ọ̀lù ni Jésù Olúwa sọ ọ̀rọ̀ tó fi í lọ́kàn balẹ̀. Ó ní: “Má bẹ̀rù, máa sọ̀rọ̀ nìṣó, má sì dákẹ́, torí mo wà pẹ̀lú rẹ.” (Ìṣe 18:9, 10) Ó máa dáa ká fi àwọn ọ̀rọ̀ yìí sọ́kàn, ní pàtàkì táwọn èèyàn ò bá fẹ́ gbọ́ ìwàásù wa. Má gbàgbé láé pé ọkàn ni Jèhófà máa ń wò, òun ló sì máa ń fa àwọn tó jẹ́ olóòótọ́ ọkàn wá sọ́dọ̀ ara rẹ̀. (1 Sám. 16:7; Jòh. 6:44) Ó dájú pé ọ̀rọ̀ yìí fún wa lókun ká lè máa ṣe iṣẹ́ ìwàásù wa nìṣó! Nǹkan bí ẹgbẹ̀rún lọ́nà ọgọ́rùn-ún mẹ́ta (300,000) èèyàn ló ń ṣèrìbọmi lọ́dọọdún, èyí fi hàn pé nǹkan bí ọgọ́rùn-ún mẹ́jọ (800) èèyàn ló ń ṣèrìbọmi lójúmọ́. Jésù pàṣẹ pé ká máa “sọ àwọn èèyàn gbogbo orílẹ̀-èdè di ọmọ ẹ̀yìn.” Ó sì fi dá gbogbo àwọn tó ń ṣègbọràn sí àṣẹ yẹn lójú pé: “Mo wà pẹ̀lú yín ní gbogbo ọjọ́ títí dé ìparí ètò àwọn nǹkan.”—Mát. 28:19, 20.
“Tí Jèhófà Bá Fẹ́” (Ìṣe 18:18-22)
17, 18. Kí ló ṣeé ṣe kí Pọ́ọ̀lù máa ronú lé lórí bí ọkọ̀ òkun ṣe ń gbé e lọ sí Éfésù?
17 A ò mọ̀ bóyá ọ̀nà tí Gálíò gbà bójú tó ọ̀rọ̀ àwọn tó fẹ̀sùn kan Pọ́ọ̀lù yọrí sí àkókò àlàáfíà fún ìjọ tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ dá sílẹ̀ ní Kọ́ríńtì. Àmọ́, Pọ́ọ̀lù ṣì “lo ọjọ́ mélòó kan sí i níbẹ̀” kó tó dágbére fáwọn ará tó wà ní Kọ́ríńtì. Nígbà ìrúwé ọdún 52 Sànmánì Kristẹni, ó ṣètò láti wọ ọkọ̀ òkun lọ sí Síríà láti etíkun Kẹnkíríà, tó jẹ́ ìrìn àjò kìlómítà mọ́kànlá (11) sí Kọ́ríńtì. Àmọ́, kí Pọ́ọ̀lù tó kúrò ní Kẹnkíríà, ó “gé irun orí rẹ̀ mọ́lẹ̀ . . . torí ó ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ kan.”c (Ìṣe 18:18) Lẹ́yìn náà, ó mú Ákúílà àti Pírísílà, wọ́n sì wọ ọkọ̀ òkun gba orí Òkun Aegean lọ sílùú Éfésù ní Éṣíà Kékeré.
18 Bí ọkọ̀ òkun ṣe ń gbé Pọ́ọ̀lù lọ láti Kẹnkíríà, ó ṣeé ṣe kó máa ronú lórí ohun tó ṣẹlẹ̀ nígbà tó wà nílùú Kọ́ríńtì. Ọ̀pọ̀ nǹkan tó ti ṣe sẹ́yìn mú inú ẹ̀ dùn, ìyẹn sì mú kí ọkàn ẹ̀ balẹ̀. Iṣẹ́ òjíṣẹ́ tó fi ọdún kan àbọ̀ ṣe ti sèso rere. Ìjọ àkọ́kọ́ ti bẹ̀rẹ̀ ní Kọ́ríńtì, ilé Jọ́sítù ni wọ́n sì ti ń pàdé. Lára àwọn tó di onígbàgbọ́ ni Jọ́sítù, Kírípọ́sì àti agboolé rẹ̀ àti ọ̀pọ̀ àwọn míì. Àwọn tó ṣẹ̀ṣẹ̀ di onígbàgbọ́ yẹn jẹ́ ẹni ọ̀wọ́n fún Pọ́ọ̀lù, torí pé ó ràn wọ́n lọ́wọ́ láti di Kristẹni. Nígbà tó yá ó kọ lẹ́tà sí wọn, ó sì sọ pé wọ́n dà bíi lẹ́tà ìdámọ̀ràn tí wọ́n kọ sínú ọkàn òun. Àwa náà gbà pé ẹni ọ̀wọ́n làwọn tá a kọ́ lẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́ tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í sin Jèhófà. Inú wa máa ń dùn gan-an láti rí àwọn arákùnrin tó dà bíi “lẹ́tà ìdámọ̀ràn” bẹ́ẹ̀!—2 Kọ́r. 3:1-3.
19, 20. Kí ni Pọ́ọ̀lù ṣe nígbà tó dé Éfésù, kí la sì rí kọ́ lára ẹ̀ tá a bá láwọn ohun tó wù wá láti ṣe lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà?
19 Nígbà tí Pọ́ọ̀lù dé Éfésù, ó tètè bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ tó bá lọ síbẹ̀. Ó “wọ sínágọ́gù, ó sì ń bá àwọn Júù fèròwérò.” (Ìṣe 18:19) Kò dúró pẹ́ ní Éfésù nígbà yẹn. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé wọ́n rọ̀ ọ́ pé kó dúró, “kò gbà.” Nígbà tó ń dágbére fún wọn, ó sọ pé: “Màá tún pa dà sọ́dọ̀ yín, tí Jèhófà bá fẹ́.” (Ìṣe 18:20, 21) Pọ́ọ̀lù gbà pé ọ̀pọ̀ èèyàn ṣì wà tó yẹ kóun wàásù fún ní Éfésù. Lọ́rọ̀ kan ṣá, ó wù ú pé kó tún pa dà wá, àmọ́ ó fi gbogbo ọ̀rọ̀ náà lé Jèhófà lọ́wọ́. Ẹ ò rí i pé àpẹẹrẹ tó dáa tó yẹ ká máa tẹ̀ lé nìyẹn jẹ́! Ó dáa tá a bá láwọn ohun tó wù wá láti ṣe lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà, tá a sì ń sapá kí ọwọ́ wa lè tẹ̀ ẹ́. Àmọ́, a gbọ́dọ̀ máa gbára lé Jèhófà pé kó tọ́ wa sọ́nà, ká sì máa ṣe ohun tó bá ìfẹ́ rẹ̀ mu.—Jém. 4:15.
20 Lẹ́yìn tí Pọ́ọ̀lù fi Ákúílà àti Pírísílà sílẹ̀ ní Éfésù, ó wọ ọkọ̀ òkun lọ sí Kesaríà. Ó dà bíi pé ó “lọ” sí Jerúsálẹ́mù ó sì kí ìjọ tó wà níbẹ̀. (Ìṣe 18:22) Lẹ́yìn náà ni Pọ́ọ̀lù lọ síbi tó máa ń dé sí ní Áńtíókù ti Síríà. Bó ṣe parí ìrìn àjò míṣọ́nnárì rẹ̀ ẹlẹ́ẹ̀kejì nìyẹn o, ibi ire ló sì já sí. Ẹ jẹ́ ká wá wo ohun tó ṣẹlẹ̀ sí i nígbà ìrìn àjò míṣọ́nnárì ẹ̀ tó kẹ́yìn.
a Wo àpótí náà, “Èbúté Méjì Ni Ìlú Kọ́ríńtì Ní.”
b Wo àpótí náà, “Àwọn Lẹ́tà Tí Ọlọ́run Mí Sí, Tó sì Ń Fúnni Níṣìírí.”
c Wo àpótí náà, “Ẹ̀jẹ́ Tí Pọ́ọ̀lù Jẹ́.”
-
-
“Ọ̀rọ̀ Jèhófà Ń Gbilẹ̀ Nìṣó, Ó sì Ń Borí” Lójú Àtakò“Jẹ́rìí Kúnnákúnná Nípa Ìjọba Ọlọ́run”
-
-
ORÍ 20
“Ọ̀rọ̀ Jèhófà Ń Gbilẹ̀ Nìṣó, Ó sì Ń Borí” Lójú Àtakò
Ohun tí Àpólò àti Pọ́ọ̀lù ṣe kí ìhìn rere lè máa tẹ̀ síwájú
Ó dá lórí Ìṣe 18:23–19:41
1, 2. (a) Kí ló ṣẹlẹ̀ sí Pọ́ọ̀lù àtàwọn ọ̀rẹ́ ẹ̀ ní Éfésù? (b) Kí la máa jíròrò nínú orí yìí?
INÚ ń bí àwọn ará ìlú Éfésù, bí wọ́n ṣe ń pariwo bẹ́ẹ̀ làwọn èèyàn ń sáré gìrìgìrì. Àwọn jàǹdùkú ti kóra jọ, wọ́n sì ti bẹ̀rẹ̀ sí í da ìlú rú! Wọ́n mú méjì lára àwọn tó ń bá àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù rìnrìn àjò, wọ́n sì ń wọ́ wọn lọ. Àwọn tó ń tajà nínú àwọn ṣọ́ọ̀bù tó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀nà fi ọjà wọn sílẹ̀, gbogbo wọn sì ń fìbínú rọ́ wọnú gbọ̀ngàn ìwòran ńlá tó wà nílùú náà, èyí tó lè gba ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (25,000) èèyàn. Èyí tó pọ̀ jù lọ lára àwọn èèyàn náà ò tiẹ̀ mọ ohun tó fa wàhálà yìí, àmọ́ ó ṣeé ṣe kí wọ́n rò pé ohun táwọn kan ń sọ nípa tẹ́ńpìlì wọn àti abo òrìṣà Átẹ́mísì tí wọ́n yàn láàyò ló fà á. Torí náà, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í pariwo léraléra pé: “Títóbi ni Átẹ́mísì àwọn ará Éfésù!”—Ìṣe 19:34.
2 A tún rí bí Sátánì ṣe fẹ́ lo àwọn jàǹdùkú láti dáwọ́ iṣẹ́ ìwàásù ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run dúró. Àmọ́, kì í ṣe ìwà ipá nìkan ni Sátánì máa ń lò láti ṣe bẹ́ẹ̀. Nínú orí yìí, a máa jíròrò díẹ̀ lára àwọn ọgbọ́nkọ́gbọ́n tí Sátánì lò láti dá iṣẹ́ ìwàásù dúró ní ọgọ́rùn-ún ọdún kìíní àtohun tó ṣe kó lè ba ìṣọ̀kan àwọn Kristẹni jẹ́. Ní pàtàkì, a máa rí i pé gbogbo ọgbọ́n rẹ̀ ló ti kùnà, torí pé “Ọ̀rọ̀ Jèhófà ń gbilẹ̀ nìṣó, ó sì ń borí lọ́nà tó lágbára.” (Ìṣe 19:20) Kí ló jẹ́ káwọn Kristẹni yẹn borí Sátánì? Ohun tó ń jẹ́ káwa náà borí ẹ̀ lónìí náà ni. Jèhófà ló ń ṣẹ́gun fún wa, kì í ṣe agbára wa. Àmọ́ bíi tàwọn Kristẹni ọgọ́rùn-ún ọdún kìíní, ó láwọn ohun táwa náà gbọ́dọ̀ ṣe. Ẹ̀mí Jèhófà máa ràn wá lọ́wọ́ ká lè ní àwọn ìwà táá mú ká ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa láṣeyọrí. Ẹ jẹ́ ká kọ́kọ́ wo àpẹẹrẹ Àpólò.
‘Ó Mọ Ìwé Mímọ́ Dunjú’ (Ìṣe 18:24-28)
3, 4. Kí ni Ákúílà àti Pírísílà kíyè sí pé Àpólò ò mọ̀, báwo ni wọ́n sì ṣe ràn án lọ́wọ́?
3 Nígbà tí Pọ́ọ̀lù ń lọ sí Éfésù nígbà ìrìn àjò míṣọ́nnárì rẹ̀ ẹlẹ́ẹ̀kẹta, Júù kan tó ń jẹ́ Àpólò dé sílùú náà. Ìlú Alẹkisáńdíríà tó lókìkí lórílẹ̀-èdè Íjíbítì ló ti wá. Àpólò láwọn ànímọ́ mélòó kan tó ta yọ. Ọ̀rọ̀ dá lẹ́nu ẹ̀. Yàtọ̀ sí pé ó mọ ọ̀rọ̀ sọ dáadáa, ó “mọ Ìwé Mímọ́ dunjú.” “Iná ẹ̀mí sì ń jó nínú rẹ̀.” Àpólò nítara, èyí jẹ́ kó lè fìgboyà sọ̀rọ̀ níwájú àwọn Júù tó kóra jọ sínú sínágọ́gù.—Ìṣe 18:24, 25.
4 Ákúílà àti Pírísílà gbọ́ ọ̀rọ̀ Àpólò. Ó dájú pé inú wọn dùn láti gbọ́ bó ṣe ń “kọ́ni ní àwọn nǹkan tó jẹ mọ́ Jésù lọ́nà tó péye.” Òótọ́ pọ́ńbélé ni gbogbo ohun tó sọ nípa Jésù. Àmọ́ nígbà tó yá, tọkọtaya tó jẹ́ Kristẹni yìí kíyè sí pé àwọn nǹkan kan wà tí Àpólò ò mọ̀. “Ìrìbọmi Jòhánù nìkan ló mọ̀.” Bó tiẹ̀ jẹ́ pé iṣẹ́ tó rẹlẹ̀ ni iṣẹ́ àgọ́ pípa tí tọkọtaya yìí ń ṣe, wọn ò torí pé Àpólò kàwé tó sì mọ ọ̀rọ̀ sọ dáadáa kí wọ́n wá máa bẹ̀rù láti ràn án lọ́wọ́. Dípò ìyẹn, “wọ́n mú un wọ àwùjọ wọn, wọ́n sì ṣàlàyé ọ̀nà Ọlọ́run fún un lọ́nà tó túbọ̀ péye.” (Ìṣe 18:25, 26) Báwo ni ohun tí wọ́n ṣe yìí ṣe rí lára Àpólò tó jẹ́ ọ̀mọ̀wé, tó sì mọ ọ̀rọ̀ sọ dáadáa? Ó dájú pé ó fi ìrẹ̀lẹ̀ gba ohun tí wọ́n sọ, ìyẹn sì jẹ́ ọ̀kan lára ànímọ́ tó ṣe pàtàkì jù tó yẹ káwa Kristẹni ní.
5, 6. Kí ló mú kí Àpólò túbọ̀ wúlò lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà, kí la sì rí kọ́ látinú àpẹẹrẹ rẹ̀?
5 Torí pé Àpólò gba ìrànlọ́wọ́ tí Ákúílà àti Pírísílà fún un, ó túbọ̀ wúlò lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà. Nígbà tó yá, ó lọ sí Ákáyà, ó sì “ṣèrànwọ́ púpọ̀” fáwọn onígbàgbọ́. Ó tún wàásù fáwọn Júù tó wà lágbègbè yẹn tí wọ́n ń sọ pé Jésù kọ́ ni Mèsáyà tí Ọlọ́run ṣèlérí, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì wọ̀ wọ́n lọ́kàn. Lúùkù sọ pé: “Ó ń sọ̀rọ̀ . . . pẹ̀lú ìtara, bó ṣe ń fi ẹ̀rí hàn kedere pé àwọn Júù kò tọ̀nà, tó sì ń fi hàn nínú Ìwé Mímọ́ pé Jésù ni Kristi náà.” (Ìṣe 18:27, 28) Ẹ ò rí i pé ìrànlọ́wọ́ ńlá ni Àpólò jẹ́ fún ìjọ! Kódà, òun náà wà lára àwọn tó mú kí “ọ̀rọ̀ Jèhófà” máa gbilẹ̀. Kí la rí kọ́ látinú àpẹẹrẹ Àpólò?
6 Ó ṣe pàtàkì gan-an pé káwa Kristẹni nírẹ̀lẹ̀. Gbogbo wa la ní oríṣiríṣi nǹkan tá a mọ̀ ọ́n ṣe, ó lè jẹ́ ẹ̀bùn àbínibí, àwọn ìrírí tá a ní, tàbí àwọn ohun tá a ti mọ̀. Àmọ́, ìrẹ̀lẹ̀ wa gbọ́dọ̀ ju àwọn ẹ̀bùn tá a ní lọ. Àìjẹ́ bẹ́ẹ̀, àwọn ẹ̀bùn tá a ní máa kó sí wa lórí, ìyẹn sì lè mú ká bẹ̀rẹ̀ sí í gbéra ga. (1 Kọ́r. 4:7; Jém. 4:6) Tá a bá nírẹ̀lẹ̀ lóòótọ́, a máa gbà pé àwọn ẹlòmíì sàn jù wá lọ. (Fílí. 2:3) A ò ní máa bínú táwọn ẹlòmíì bá tọ́ wa sọ́nà, àá sì múra tán láti kẹ́kọ̀ọ́ lára wọn. A ò ní máa rin kinkin mọ́ èrò tiwa tá a bá rí i pé Jèhófà ti fi ẹ̀mí mímọ́ darí ètò ẹ̀ láti ṣàtúnṣe òye tá a ní tẹ́lẹ̀. Tá a bá ṣáà ti ń bá a nìṣó láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀, àá máa wúlò fún Jèhófà àti Ọmọ rẹ̀.—Lúùkù 1:51, 52.
7. Báwo ni Pọ́ọ̀lù àti Àpólò ṣe fi hàn pé àwọn lẹ́mìí ìrẹ̀lẹ̀?
7 Tá a bá lẹ́mìí ìrẹ̀lẹ̀, a ò ní máa bá àwọn míì díje. Sátánì gbìyànjú gan-an láti dá ìyapa sílẹ̀ láàárín àwọn Kristẹni àkọ́bẹ̀rẹ̀. Ó dájú pé ṣe ni Sátánì á máa yọ̀ ṣìnkìn tó bá rí i tí àwọn alábòójútó táwọn èèyàn bọ̀wọ̀ fún bí Àpólò àti àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù ń bára wọn fà á, bóyá tí wọ́n ń jowú ara wọn, tí wọ́n sì ń wá bí wọ́n ṣe máa dẹni táwọn èèyàn ń kan sárá sí nínú ìjọ! Kò sì lè ṣòro fún wọn láti ṣe bẹ́ẹ̀. Torí pé ní Kọ́ríńtì, àwọn Kristẹni kan ti bẹ̀rẹ̀ sí í sọ pé, “Èmi jẹ́ ti Pọ́ọ̀lù,” àwọn míì sì ń sọ pé, “Èmi jẹ́ ti Àpólò.” Ṣé Pọ́ọ̀lù àti Àpólò fara mọ́ èrò tó ń fa ìyapa yìí? Rárá o! Torí pé Pọ́ọ̀lù lẹ́mìí ìrẹ̀lẹ̀, ó gbà pé Àpólò wúlò gan-an lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn tí wọ́n jọ ń ṣe, torí náà ó fún un ní ọ̀pọ̀ àǹfààní iṣẹ́ ìsìn. Àpólò náà ò sì kọ ọ̀rọ̀ sí Pọ́ọ̀lù lẹ́nu. (1 Kọ́r. 1:10-12; 3:6, 9; Títù 3:12, 13) Àpẹẹrẹ àtàtà ni wọ́n jẹ́ fún wa lónìí. Ó yẹ káwa náà jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ ká sì máa yẹra fún ohunkóhun tó lè dá ìyapa sílẹ̀ nínú ìjọ.
Ó Ń “Fèròwérò Nípa Ìjọba Ọlọ́run Lọ́nà Tó Ń Yíni Lérò Pa Dà” (Ìṣe 18:23; 19:1-10)
8. Ọ̀nà wo ni Pọ́ọ̀lù gbà pa dà sí Éfésù, kí sì nìdí?
8 Pọ́ọ̀lù ti ṣèlérí pé òun máa pa dà lọ sí Éfésù, ó sì mú ìlérí ẹ̀ ṣẹ.a (Ìṣe 18:20, 21) Àmọ́, kíyè sí ọ̀nà tó gbà pa dà lọ. Áńtíókù ti Síríà la gbúròó ẹ̀ sí gbẹ̀yìn. Kó tó dé Éfésù, ó ṣeé ṣe kó kọ́kọ́ lọ sí Sìlúṣíà tí kò fi bẹ́ẹ̀ jìn, kó wá tibẹ̀ wọkọ̀ ojú omi tó máa gbé e débi tó ń lọ. Àmọ́, “àwọn agbègbè tó jìnnà sí òkun” ló gbà. Àwọn kan fojú bù ú pé ìrìn àjò tí Ìṣe 18:23 àti 19:1 sọ pé Pọ́ọ̀lù rìn tó nǹkan bí ẹgbẹ̀jọ (1,600) kìlómítà! Kí nìdí tí Pọ́ọ̀lù fi yàn láti rìnrìn àjò tó jìn tó sì nira tó bẹ́ẹ̀? Ó ṣe bẹ́ẹ̀ kó lè “fún gbogbo ọmọ ẹ̀yìn lókun.” (Ìṣe 18:23) Pọ́ọ̀lù mọ̀ pé ìrìn àjò míṣọ́nnárì ẹlẹ́ẹ̀kẹta yẹn ò ní rọrùn bí méjì àkọ́kọ́ náà ò ṣe rọrùn. Amọ́, kò kà á sí àṣedànù. Báwọn alábòójútó àyíká àtàwọn ìyàwó wọn náà ṣe máa ń ṣe lónìí nìyẹn. Ẹ ò rí i pé ó yẹ ká mọrírì àwọn ará wa yìí tí wọ́n fi àwọn nǹkan du ara wọn torí àwọn ẹlòmíì!
9. Kí nìdí táwọn ọmọ ẹ̀yìn tí wọ́n ti ṣèrìbọmi tẹ́lẹ̀ fi tún ìrìbọmi ṣe, ẹ̀kọ́ wo la sì rí kọ́ lára wọn?
9 Nígbà tí Pọ́ọ̀lù dé Éfésù, ó rí àwọn ọkùnrin tí wọ́n tó méjìlá tí wọ́n jẹ́ ọmọ ẹ̀yìn Jòhánù Onírìbọmi. Òótọ́ ni pé Jòhánù ti ṣèrìbọmi fún wọn tẹ́lẹ̀, àmọ́ ìrìbọmi tí wọ́n ṣe yẹn kò lẹ́sẹ̀ ńlẹ̀ mọ́. Bákan náà, ó jọ pé wọn ò fi bẹ́ẹ̀ mọ̀ nípa ẹ̀mí mímọ́, ìyẹn tí wọ́n bá tiẹ̀ mọ̀ nípa ẹ̀ rárá. Pọ́ọ̀lù jẹ́ kí wọ́n mọ ìdí tó fi ṣe pàtàkì pé káwọn batisí wọn lórúkọ Jésù. Wọ́n lẹ́mìí ìrẹ̀lẹ̀ bíi ti Àpólò, wọ́n sì ṣe tán láti kẹ́kọ̀ọ́. Lẹ́yìn tí wọ́n ti batisí wọn lórúkọ Jésù, wọ́n rí ẹ̀mí mímọ́ gbà, wọ́n sì tún láǹfààní láti ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu kan. Èyí jẹ́ ká rí i pé Jèhófà máa ń bù kún àwọn tí wọ́n bá ṣe tán láti ṣe ohun tí ètò rẹ̀ bá sọ.—Ìṣe 19:1-7.
10. Kí nìdí tí Pọ́ọ̀lù fi kúrò ní sínágọ́gù tó sì lọ sí gbọ̀ngàn àpéjọ ilé ẹ̀kọ́, báwo la sì ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ ẹ̀ tá a bá ń wàásù?
10 Nǹkan míì tún ṣẹlẹ̀ tó mú kí ìhìn rere tẹ̀ síwájú. Pọ́ọ̀lù fìgboyà wàásù fóṣù mẹ́ta nínú sínágọ́gù. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ó ń “fèròwérò nípa Ìjọba Ọlọ́run lọ́nà tó ń yíni lérò pa dà,” àwọn kan ò gbọ́ wọ́n sì ta kò ó. Dípò tí Pọ́ọ̀lù á fi máa fàkókò ṣòfò lọ́dọ̀ àwọn tó “ń sọ̀rọ̀ burúkú nípa Ọ̀nà Náà,” ó ṣètò láti bá wọn sọ̀rọ̀ nínú gbọ̀ngàn àpéjọ ilé ẹ̀kọ. (Ìṣe 19:8, 9) Ó wá pọn dandan pé káwọn tó bá fẹ́ mọ̀ sí i nípa Ìjọba Ọlọ́run kúrò ní sínágọ́gù kí wọ́n sì lọ sínú gbọ̀ngàn àpéjọ náà. Bíi ti Pọ́ọ̀lù, tá a bá rí i pé ẹni tá à ń wàásù fún ò fẹ́ gbọ́ ọ̀rọ̀ wa tàbí pé ó kàn fẹ́ bá wa jiyàn, ṣe ló yẹ ká dá ìjíròrò náà dúró, torí ọ̀pọ̀ àwọn tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ òtítọ́ ló ṣì wà tó yẹ kí wọ́n gbọ́ ìhìn rere nípa Ìjọba Ọlọ́run.
11, 12. (a) Báwo ni Pọ́ọ̀lù ṣe jẹ́ àpẹẹrẹ rere tó bá dọ̀rọ̀ ká ṣiṣẹ́ kára ká sì mú ọ̀rọ̀ wa bá àwọn tá à ń wàásù fún mu? (b) Kí ló fi hàn pé àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà máa ń ṣiṣẹ́ kára, tá a sì ń mu ọ̀rọ̀ wa bá àwọn tá à ń wàásù fún mu?
11 Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ojoojúmọ́ ni Pọ́ọ̀lù máa ń kọ́ni nínú gbọ̀ngàn àpéjọ ilé ẹ̀kọ́ yẹn láti nǹkan bí aago mọ́kànlá àárọ̀ títí di aago mẹ́rin ìrọ̀lẹ́. (Ìṣe 19:9) Ó sì lè jẹ́ pé ìgbà tó parọ́rọ́ tó sì móoru jù lọ nìyẹn, táwọn èèyàn máa ń ṣíwọ́ iṣẹ́ láti jẹun kí wọ́n sì sinmi. Tó bá jẹ́ pé bí Pọ́ọ̀lù ṣe ń fìtara wàásù fún odindi ọdún méjì nìyẹn, a jẹ́ pé á ti lò ju ẹgbẹ̀rún mẹ́ta (3,000) wákàtí láti fi kọ́ni lẹ́kọ̀ọ́.b Ìdí míì nìyẹn tí ọ̀rọ̀ Jèhófà fi ń gbilẹ̀ nìṣó. Òṣìṣẹ́ kára ni Pọ́ọ̀lù, ó sì mọ bó ṣe lè mú ara ẹ̀ bá ipò àwọn tó ń wàásù fún mu. Ó ṣe tán láti ṣe àwọn àyípadà tó yẹ kó lè rí àwọn èèyàn tó pọ̀ sí i bá sọ̀rọ̀. Kí wá lèyí yọrí sí? “Gbogbo àwọn tó ń gbé ní ìpínlẹ̀ Éṣíà. . . gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, àti Júù àti Gíríìkì.” (Ìṣe 19:10) Ẹ ò rí i pé Pọ́ọ̀lù jẹ́rìí kúnnákúnná lóòótọ́!
À ń sapá láti wá àwọn èèyàn lọ síbikíbi tá a bá ti lè rí wọn
12 Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà lóde òní náà ń ṣiṣẹ́ kára, a sì mọ bá a ṣe lè mú ọ̀rọ̀ wa bá àwọn èèyàn tá à ń wàásù fún mu. À ń sapá láti dé ọ̀dọ̀ àwọn èèyàn níbikíbi tá a bá ti lè rí wọn àti lásìkò tá a lè bá wọn. A máa ń wàásù ní òpópónà, láwọn ibi ìtajà àti láwọn ibi ìgbọ́kọ̀sí. A lè fi fóònù wàásù fáwọn èèyàn tàbí ká kọ lẹ́tà. Tó bá sì kan pé ká wàásù láti ilé dé ilé, a máa ń gbìyànjú láti lọ nígbà tó ṣeé ṣe ká bá ọ̀pọ̀ èèyàn nílé.
Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run “Ń Gbilẹ̀ Nìṣó, Ó sì Ń Borí” Báwọn Ẹ̀mí Èṣù Tiẹ̀ Ń Ṣàtakò (Ìṣe 19:11-22)
13, 14. (a) Kí ni Jèhófà fún Pọ́ọ̀lù lágbára láti ṣe? (b) Àṣìṣe wo làwọn ọmọkùnrin Síkéfà ṣe, irú èrò wo sì lọ̀pọ̀ àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ní lónìí?
13 Lúùkù jẹ́ ká mọ̀ pé ìgbà kan wà tí Jèhófà fún Pọ́ọ̀lù lágbára láti ṣe “àwọn iṣẹ́ agbára tó ṣàrà ọ̀tọ̀.” Kódà, wọ́n mú aṣọ àti épírọ́ọ̀nù rẹ̀ lọ bá àwọn tó ń ṣàìsàn, ara wọn sì yá. Wọ́n tún lò ó láti lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde.c (Ìṣe 19:11, 12) Inú ọ̀pọ̀ èèyàn dùn nígbà tí wọ́n rí i bí ẹ̀mí èṣù ṣe ń jáde lára àwọn èèyàn, síbẹ̀ inú àwọn kan ò dùn.
14 Àwọn kan lára “àwọn Júù tó ń rìnrìn àjò kiri, tí wọ́n ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde” gbìyànjú láti ṣe irú iṣẹ́ ìyanu tí Pọ́ọ̀lù ń ṣe. Àwọn kan nínú wọn gbìyànjú láti lo orúkọ Jésù àti ti Pọ́ọ̀lù láti lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde. Bí àpẹẹrẹ, Lúùkù sọ pé àwọn ọmọkùnrin méje kan wà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Síkéfà, ọ̀kan lára àwọn olórí àlùfáà Júù. Nígbà tí wọ́n fẹ́ lé ẹ̀mí èṣù jáde, ẹ̀mí èṣù náà sọ fún wọn pé: “Mo mọ Jésù, mo sì mọ Pọ́ọ̀lù; àmọ́ ta lẹ̀yin?” Ni ọkùnrin tí ẹ̀mí èṣù wà lára ẹ̀ bá bẹ́ mọ́ àwọn afàwọ̀rajà yẹn bí ẹranko ẹhànnà, débi pé wọ́n sá lọ kúrò lọ́dọ̀ ẹ̀ ní ìhòòhò pẹ̀lú ọgbẹ́ lára. (Ìṣe 19:13-16) Bí ẹ̀mí Ọlọ́run ṣe ṣẹ́gun àwọn afàwọ̀rajà yìí jẹ́ ká rí agbára “ọ̀rọ̀ Jèhófà,” èyí tó fún Pọ́ọ̀lù láti ṣe iṣẹ́ àrà ọ̀tọ̀ táwọn ẹlẹ́sìn èké ò lè ṣe. Lónìí, ọ̀pọ̀ èèyàn ló rò pé táwọn bá ṣáà ti ń pe orúkọ Jésù tàbí táwọn bá ń pe ara àwọn ní “Kristẹni,” àbùṣe ti bùṣe. Àmọ́, bí Jésù ṣe sọ, àwọn tó bá ń ṣe ìfẹ́ Baba rẹ̀ nìkan ló nírètì ìyè àìnípẹ̀kun lọ́jọ́ iwájú.—Mát. 7:21-23.
15. Tó bá dọ̀rọ̀ ìbẹ́mìílò àtàwọn nǹkan tó ní í ṣe pẹ̀lú ẹ̀, báwo la ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ àwọn ará Éfésù?
15 Ohun tó ṣẹlẹ̀ sáwọn ọmọkùnrin Síkéfà jẹ́ káwọn èèyàn bẹ̀rù Ọlọ́run, èyí mú kí ọ̀pọ̀ èèyàn di onígbàgbọ́, wọn ò sì lọ́wọ́ sí ìbẹ́mìílò mọ́. Àwọn ará ìlú Éfésù máa ń pidán gan-an, ó ti wà nínú àṣà wọn. Wọ́n sábà máa ń fi èèdì di àwọn ẹlòmíì, wọ́n máa ń lo ońdè, kódà wọ́n ní ọ̀pọ̀ ìwé tí wọ́n kọ ọfọ̀ sí. Àmọ́ ní báyìí tí ọ̀pọ̀ àwọn ará Éfésù ti di onígbàgbọ́, wọ́n kó àwọn ìwé tí wọ́n fi ń pidán jáde wọ́n sì dáná sun ún ní gbangba, tá a bá sì ní ká ṣírò iye owó táwọn ìwé náà máa jẹ́ lóde òní, ó máa tó ẹgbẹẹgbẹ̀rún dọ́là.d Lúùkù sọ pé: “Nípa bẹ́ẹ̀, ọ̀rọ̀ Jèhófà ń gbilẹ̀ nìṣó, ó sì ń borí lọ́nà tó lágbára.” (Ìṣe 19:17-20) Àbí ẹ ò rí i bí Jèhófà ṣe ṣẹ́gun ìjọsìn èké àtàwọn ẹ̀mí èṣù! Àpẹẹrẹ tó dáa làwọn olóòótọ́ èèyàn yẹn jẹ́ fún wa lónìí. Àwa náà ń gbé nínú ayé tí ìbẹ́mìílò ti wọ́pọ̀ gan-an. Torí náà, tá a bá ní ohunkóhun tó ní í ṣe pẹ̀lú ìbẹ́mìílò, á dáa ká ṣe bíi tàwọn ará Éfésù, ká tètè kó wọn dà nù! Ohun yòówù kó ná wa, ẹ jẹ́ ká jìnnà pátápátá sí ìbẹ́mìílò torí ohun ìríra ni.
“Àwọn Èèyàn Dá Rògbòdìyàn Púpọ̀ Sílẹ̀” (Ìṣe 19:23-41)
“Ẹ̀yin èèyàn, ẹ mọ̀ dáadáa pé òwò yìí ló mú ká láásìkí.”—Ìṣe 19:25
16, 17. (a) Ṣàlàyé bí Dímẹ́tíríù ṣe dá wàhálà sílẹ̀ ní Éfésù. (b) Báwo làwọn ará Éfésù ṣe fi hàn pé agbawèrèmẹ́sìn làwọn?
16 Ní báyìí, ẹ jẹ́ ká sọ̀rọ̀ nípa ọgbọ́n ẹ̀wẹ́ Sátánì tí Lúùkù mẹ́nu kàn nígbà tó sọ pé “àwọn èèyàn dá rògbòdìyàn púpọ̀ sílẹ̀ nípa Ọ̀nà Náà.” Lúùkù ò sọ àsọdùn rárá.e (Ìṣe 19:23) Ọkùnrin alágbẹ̀dẹ fàdákà kan tó ń jẹ́ Dímẹ́tíríù ló dá wàhálà náà sílẹ̀. Òun ló kọ́kọ́ sọ̀rọ̀ náà létí àwọn alágbẹ̀dẹ fàdákà bíi tiẹ̀, ó rán wọn létí pé ère tí wọ́n ń tà ló sọ wọ́n di ọlọ́rọ̀. Ó sọ pé ìwàásù tí Pọ́ọ̀lù ń ṣe ń kó bá ọrọ̀ ajé àwọn, torí pé àwọn Kristẹni kì í bọ̀rìṣà. Ó wá sọ fún wọn pé bí ọmọ orílẹ̀-èdè rere, kò yẹ káwọn lajú àwọn sílẹ̀ kí tàlùbọ̀ kó wọ̀ ọ́, kí Pọ́ọ̀lù wá sọ abo òrìṣà Átẹ́mísì àti tẹ́ńpìlì wọn tó lókìkí di ohun táwọn èèyàn ò ‘kà sí’ mọ́.—Ìṣe 19:24-27.
17 Ohun tí Dímẹ́tíríù fẹ́ kó ṣẹlẹ̀ náà ló pa dà ṣẹlẹ̀. Inú bí àwọn alágbẹ̀dẹ fàdákà, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í pariwo pé “Títóbi ni Átẹ́mísì àwọn ará Éfésù!” Làwọn jàǹdùkú bá bẹ̀rẹ̀ sí í dá wàhálà sílẹ̀ nínú ìlú náà bá a ṣe sọ níbẹ̀rẹ̀ orí yìí.f Pọ́ọ̀lù ò kọ ikú nítorí ìhìn rere, torí náà, ó fẹ́ wọ inú gbọ̀ngàn ìwòran ńlá kó lè bá àwọn èèyàn náà sọ̀rọ̀, àmọ́ àwọn ọmọ ẹ̀yìn ò jẹ́ kó lọ torí ó léwu. Ọkùnrin kan tó ń jẹ́ Alẹkisáńdà dìde dúró láàárín àwọn èèyàn náà ó sì gbìyànjú láti sọ̀rọ̀. Torí pé Júù lòun náà, ó ṣeé ṣe kó wù ú láti ṣàlàyé ìyàtọ̀ tó wà láàárín àwọn Júù àtàwọn Kristẹni yìí. Àmọ́, àlàyé ẹ̀ ò lè já mọ́ nǹkan kan lójú àwọn èèyàn yẹn. Gbàrà tí wọ́n ti rí i pé Júù lòun náà, wọ́n ké mọ́ ọn pé kó jókòó ara ẹ̀, wọ́n sì ń pariwo fún nǹkan bíi wákàtí méjì, wọ́n ń sọ pé “Títóbi ni Átẹ́mísì àwọn ará Éfésù!” Títí dòní, àwọn èèyàn kan ṣì wà tó jẹ́ agbawèrèmẹ́sìn bíi tìgbà yẹn, tí wọ́n ń hùwà bí ẹni tí kò nírònú.—Ìṣe 19:28-34.
18, 19. (a) Báwo ni akọ̀wé ìlú tó wà ní Éfésù ṣe pa àwọn èèyàn náà lẹ́nu mọ́? (b) Báwo làwọn aláṣẹ ṣe máa ń dáàbò bo àwa èèyàn Jèhófà nígbà míì, kí ló sì yẹ ká ṣe?
18 Nígbà tó yá, akọ̀wé ìlú yẹn pa àwọn jàǹdùkú náà lẹ́nu mọ́. Ẹnì kan tórí ẹ̀ pé ni akọ̀wé ìlú yìí, ó fi àwọn èèyàn tínú ń bí náà lọ́kàn balẹ̀ pé kò sóhun táwọn Kristẹni lè fi tẹ́ńpìlì àti abo òrìṣà wọn ṣe. Yàtọ̀ síyẹn, ó sọ fún wọn pé Pọ́ọ̀lù àtàwọn tí wọ́n jọ ń wàásù ò hùwà ọ̀daràn kankan lòdì sí tẹ́ńpìlì Átẹ́mísì, àti pé tí wọn ò bá fara mọ́ ohun tí Pọ́ọ̀lù àtàwọn ọ̀rẹ́ ẹ̀ ń ṣe, ṣe ló yẹ kí wọ́n fẹsẹ̀ òfin tọ̀ ọ́. Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé èyí tó wọ àwọn èèyàn náà lọ́kàn jù lọ ni bó ṣe rán wọn létí pé bí wọ́n ṣe kóra jọ, tí wọ́n sì ń dàlú rú kò bófin ìlú Róòmù mu. Lẹ́yìn náà, ó ní káwọn èèyàn náà máa lọ. Láìka bínú ṣe ń bí wọn sí, ṣe lara wọn balẹ̀ pẹ̀sẹ̀ nígbà tí wọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ ọlọgbọ́n tí akọ̀wé ìlú náà sọ.—Ìṣe 19:35-41.
19 Èyí kọ́ ni ìgbà àkọ́kọ́ táwọn èèyàn jẹ́ẹ́jẹ́ àti aláròjinlẹ̀ tó wà nípò àṣẹ máa gbèjà àwọn ọmọlẹ́yìn Jésù, kò sì ní jẹ́ ìgbà ìkẹyìn. Kódà, àpọ́sítélì Jòhánù ti rí i tẹ́lẹ̀ nínú ìran kan pé láwọn ọjọ́ ìkẹyìn yìí, “ilẹ̀” tó ṣàpẹẹrẹ àwọn aláṣẹ ayé yìí máa gbé odò náà mì, ìyẹn inúnibíni tí Sátánì ń ṣe sáwọn ọmọlẹ́yìn Jésù. (Ìfi. 12:15, 16) Ohun tó sì máa ń ṣẹlẹ̀ gan-an nìyẹn. Lọ́pọ̀ ìgbà, àwọn adájọ́ tó lọ́kàn rere máa ń ràn wá lọ́wọ́ wọ́n sì máa ń dáàbò bo ẹ̀tọ́ táwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ní láti máa jọ́sìn Jèhófà, ká sì tún máa wàásù ìhìn rere fáwọn èèyàn. Àmọ́ ṣá o, tá a bá máa ṣàṣeyọrí, ìwà tá à ń hù ṣe pàtàkì. Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ torí pé Pọ́ọ̀lù níwà tó dáa làwọn aláṣẹ tó wà nílùú Éfésù fi bọ̀wọ̀ fún un, tó sì ń wù wọ́n pé kí wọ́n gbà á sílẹ̀. (Ìṣe 19:31) Torí náà, tá a bá jẹ́ olóòótọ́ tá a sì níwà tó dáa, ìyẹn á jẹ́ káwọn èèyàn tá à ń bá pàdé ní èrò tó dáa nípa wa.
20. (a) Báwo ni ọ̀nà tí ọ̀rọ̀ Jèhófà gbà gbilẹ̀ ní ọgọ́rùn-ún ọdún kìíní àti lónìí ṣe rí lára ẹ? (b) Kí lo pinnu pé wàá ṣe bó o ṣe ń rí i tí Jèhófà ń lò wá láti ṣàṣeyọrí tá a sì ń ṣẹ́gun Sátánì àti ètò burúkú rẹ̀?
20 Inú wa dùn láti rí i pé “ọ̀rọ̀ Jèhófà ń gbilẹ̀ nìṣó, ó sì ń borí” ní ọgọ́rùn-ún ọdún kìíní. Bákan náà lónìí, à ń láyọ̀ bá a ṣe ń rí i tí Jèhófà ń ràn wá lọ́wọ́ ká lè ṣàṣeyọrí. Ó dájú pé ìwọ náà á fẹ́ kópa díẹ̀, bó ti wù kó kéré mọ, nínú irú ìjagunmólú bẹ́ẹ̀? Tó o bá fẹ́ bẹ́ẹ̀, máa tẹ̀ lé àpẹẹrẹ àwọn tá a ti sọ̀rọ̀ nípa wọn nínú orí yìí. Jẹ́ onírẹ̀lẹ̀, tètè máa ṣe ohun tí ètò Jèhófà bá sọ, máa ṣiṣẹ́ kára, kọ ìbẹ́mìílò sílẹ̀ pátápátá, kó o sì ṣe gbogbo ohun tó o lè ṣe kí ìwà àti ìṣe rẹ lè máa jẹ́rìí fáwọn èèyàn.
a Wo àpótí náà, “Éfésù—Olú Ìlú Éṣíà.”
b Pọ́ọ̀lù tún kọ ìwé 1 Kọ́ríńtì nígbà tó wà ní Éfésù.
c Aṣọ náà lè jẹ́ aṣọ tí Pọ́ọ̀lù máa ń so mọ́ orí kí òógùn má bàa ṣàn wọnú ojú ẹ̀. Bí Pọ́ọ̀lù ṣe wọ épírọ́ọ̀nù lákòókò yìí fi hàn pé ó ṣeé ṣe kó máa ṣe iṣẹ́ àgọ́ pípa lọ́wọ́ àárọ̀, nígbà tọ́wọ́ ẹ̀ bá dilẹ̀, kó lè rí owó táá fi gbọ́ bùkátà ara ẹ̀.—Ìṣe 20:34, 35.
d Lúùkù sọ pé gbogbo rẹ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ́ta (50,000) ẹyọ owó fàdákà. Tó bá jẹ́ owó dínárì ló ní lọ́kàn, ó máa gba òṣìṣẹ́ kan láyé ìgbà yẹn ní ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ́ta (50,000) ọjọ́, tàbí nǹkan bí ọdún mẹ́tàdínlógóje (137), kó tó lè rí owó yẹn kó jọ, ìyẹn tó bá ń fi gbogbo ọjọ́ méje tó wà lọ́sẹ̀ ṣiṣẹ́.
e Àwọn kan sọ pé ìṣẹ̀lẹ̀ yìí ni Pọ́ọ̀lù ń tọ́ka sí nígbà tó sọ fáwọn ará Kọ́ríńtì pé “a ò . . . mọ̀ pé ẹ̀mí wa ò ní bọ́.” (2 Kọ́r. 1:8) Àmọ́, ó lè jẹ́ ìṣẹ̀lẹ̀ kan tó burú jùyẹn lọ ló ní lọ́kàn. Nígbà tí Pọ́ọ̀lù kọ̀wé pé òun “bá àwọn ẹranko jà ní Éfésù,” ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ìgbà tó kojú àwọn ẹranko ẹhànnà ní gbọ̀ngàn ìwòran ló ń sọ tàbí báwọn èèyàn ṣe ṣenúnibíni sí i. (1 Kọ́r. 15:32) Àlàyé méjèèjì yìí ló bá ohun tí Pọ́ọ̀lù sọ mu.
f Ẹgbẹ́ àwọn oníṣẹ́ ọwọ́ bí irú èyí máa ń lágbára gan-an. Bí àpẹẹrẹ, ní nǹkan bí ọgọ́rùn-ún ọdún lẹ́yìn ìyẹn, ẹgbẹ́ oníbúrẹ́dì dá irú wàhálà bẹ́ẹ̀ sílẹ̀ nílùú Éfésù.
-
-
“Ọrùn Mi Mọ́ Kúrò Nínú Ẹ̀jẹ̀ Gbogbo Èèyàn”“Jẹ́rìí Kúnnákúnná Nípa Ìjọba Ọlọ́run”
-
-
ORÍ 21
“Ọrùn Mi Mọ́ Kúrò Nínú Ẹ̀jẹ̀ Gbogbo Èèyàn”
Pọ́ọ̀lù fìtara wàásù, ó sì ń fún àwọn alàgbà nímọ̀ràn
Ó dá lórí Ìṣe 20:1-38
1-3. (a) Ṣàlàyé ohun tó fa ikú Yútíkọ́sì. (b) Kí ni Pọ́ọ̀lù ṣe, kí lohun tó ṣẹlẹ̀ yìí sì jẹ́ ká mọ̀ nípa Pọ́ọ̀lù?
PỌ́Ọ̀LÙ ń ṣèpàdé pẹ̀lú àwọn ará tó wà ní ìjọ Tíróásì lókè pẹ̀tẹ́ẹ̀sì kan. Torí pé alẹ́ tó máa lò kẹ́yìn lọ́dọ̀ àwọn ará náà nìyẹn, ó bá wọn sọ̀rọ̀ fún ọ̀pọ̀ wákàtí, títí di ọ̀gànjọ́ òru. Wọ́n tan àtùpà bíi mélòó kan sínú yàrá tí wọ́n wà. Torí náà, ooru mú, ó sì ṣeé ṣe kí èéfín àtùpà tó ń jó yẹn ti bo inú yàrá náà. Ọ̀dọ́kùnrin kan tó ń jẹ́ Yútíkọ́sì jókòó sí ojú ọ̀kan lára àwọn fèrèsé tó wà lókè ilé náà. Bí Pọ́ọ̀lù ṣe ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ, oorun gbé Yútíkọ́sì lọ, ó sì ṣubú láti àjà kẹta!
2 Torí pé oníṣègùn ni Lúùkù, ó ṣeé ṣe kó wà lára àwọn tó kọ́kọ́ sáré jáde lọ wo ọ̀dọ́kùnrin náà. Nígbà tí wọ́n fi máa débẹ̀, ẹ̀pa ò bóró mọ́, “òkú” Yútíkọ́sì ni wọ́n bá. (Ìṣe 20:9) Àmọ́, ohun ìyanu kan ṣẹlẹ̀. Pọ́ọ̀lù dùbúlẹ̀ lé ọ̀dọ́kùnrin náà, ó sì sọ fáwọn ará náà pé: “Ẹ dákẹ́ ariwo, torí ó ti jí.” Pọ́ọ̀lù ti jí Yútíkọ́sì dìde!—Ìṣe 20:10.
3 Ohun tó ṣẹlẹ̀ yìí jẹ́ ká rí bí ẹ̀mí mímọ́ Ọlọ́run ṣe lágbára tó. Àmọ́, ṣé Pọ́ọ̀lù ló fà á tí Yútíkọ́sì fi kú? Rárá o! Síbẹ̀, kò fẹ́ kí ikú ọ̀dọ́kùnrin yìí ba àkókò pàtàkì yẹn jẹ́ tàbí kó mú ẹnikẹ́ni kọsẹ̀. Torí náà bó ṣe jí Yútíkọ́sì dìde tu ìjọ yẹn nínú, ó sì fún wọn níṣìírí láti máa bá iṣẹ́ ìwàásù wọn lọ. Ó ṣe kedere pé ẹ̀mí èèyàn jọ Pọ́ọ̀lù lójú. Ohun tó sọ ló jẹ́ ká mọ̀ bẹ́ẹ̀, ó sọ pé: “Ọrùn mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀jẹ̀ gbogbo èèyàn.” (Ìṣe 20:26) Ẹ jẹ́ ká wo bí àpẹẹrẹ Pọ́ọ̀lù ṣe lè ran àwa náà lọ́wọ́, tó bá dọ̀rọ̀ kí ẹ̀mí àwọn èèyàn jọ wá lójú.
“Ó Bẹ̀rẹ̀ Ìrìn Àjò Rẹ̀ Lọ sí Makedóníà” (Ìṣe 20:1, 2)
4. Ìṣòro ńlá wo ni Pọ́ọ̀lù ṣẹ̀ṣẹ̀ bọ́ nínú ẹ̀?
4 Bá a ṣe sọ ní orí tó ṣáájú, Pọ́ọ̀lù ṣẹ̀ṣẹ̀ bọ́ nínú ìṣòro ńlá kan ni. Wàhálà kékeré kọ́ ni iṣẹ́ ìwàásù rẹ̀ dá sílẹ̀ nílùú Éfésù. Àwọn alágbẹ̀dẹ fàdákà tí wọ́n ń gbẹ́ ère, tí wọ́n sì ń tà á fáwọn tó ń jọ́sìn òrìṣà Átẹ́mísì náà lọ́wọ́ nínú wàhálà tó ṣẹlẹ̀ yìí. Ìṣe 20:1 sọ pé: “Nígbà tí rúkèrúdò náà rọlẹ̀, Pọ́ọ̀lù ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ ẹ̀yìn, lẹ́yìn tó fún wọn ní ìṣírí, tó sì dágbére fún wọn, ó bẹ̀rẹ̀ ìrìn àjò rẹ̀ lọ sí Makedóníà.”
5, 6. (a) Báwo ni Pọ́ọ̀lù ṣe pẹ́ tó nílùú Makedóníà, kí ló sì ṣe fáwọn ará tó wà níbẹ̀? (b) Ojú wo ni Pọ́ọ̀lù fi ń wo àwọn Kristẹni bíi tiẹ̀?
5 Nígbà tí Pọ́ọ̀lù ń lọ sí Makedóníà, ó dúró ní etíkun ìlú Tíróásì, ó sì lo ọjọ́ mélòó kan níbẹ̀. Ó ń dúró de Títù tó lọ sí Kọ́ríńtì kó wá bá òun níbẹ̀. (2 Kọ́r. 2:12, 13) Àmọ́, nígbà tí Pọ́ọ̀lù ò rí Títù, ó lọ sí Makedóníà, ó sì ṣeé ṣe kó lò tó ọdún kan tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ níbẹ̀ kó lè fún àwọn ará “ní ọ̀pọ̀ ìṣírí.”a (Ìṣe 20:2) Nígbà tó yá, Títù wá bá Pọ́ọ̀lù ní Makedóníà, ó sì mú ìròyìn rere wá nípa ohun táwọn ará Kọ́ríńtì ṣe nígbà tí wọ́n gba lẹ́tà àkọ́kọ́ tí Pọ́ọ̀lù kọ sí wọn. (2 Kọ́r. 7:5-7) Ìyẹn ló mú kí Pọ́ọ̀lù kọ lẹ́tà míì sí wọn. Lẹ́tà náà la wá mọ̀ sí Kọ́ríńtì Kejì.
6 Ó bá a mu wẹ́kú pé Lúùkù lo ọ̀rọ̀ náà “ìṣírí” láti fi ṣàlàyé ìbẹ̀wò tí Pọ́ọ̀lù ṣe sáwọn ará tó wà nílùú Éfésù àti Makedóníà. Ọ̀rọ̀ yẹn fi hàn pé Pọ́ọ̀lù nífẹ̀ẹ́ àwọn tí wọ́n jọ jẹ́ Kristẹni gan-an! Pọ́ọ̀lù ò dà bí àwọn Farisí tí wọ́n ń wo àwọn èèyàn bí ẹni tí ò já mọ́ nǹkan kan, alábàáṣiṣẹ́ ló ka àwọn tí wọ́n jọ jẹ́ Kristẹni sí. (Jòh 7:47-49; 1 Kọ́r. 3:9) Kódà, nígbà tó fẹ́ fún wọn ní ìmọ̀ràn tó lágbára, kò bá wọn sọ̀rọ̀ bíi pé òun sàn jù wọ́n lọ.—2 Kọ́r. 2:4.
7. Báwo làwọn alábòójútó ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Pọ́ọ̀lù lónìí?
7 Lónìí, àwọn alàgbà àtàwọn alábòójútó àyíká máa ń sapá gan-an kí wọ́n lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Pọ́ọ̀lù. Kódà nígbà tí wọ́n bá ń báni wí, ohun tó máa ń wà lọ́kàn wọn ni pé kí wọ́n fún àwọn tó nílò ìrànlọ́wọ́ níṣìírí. Àwọn alábòójútó kì í dá àwọn èèyàn lẹ́bi, ṣe ni wọ́n máa ń ronú nípa bí nǹkan ṣe rí lára àwọn èèyàn, tí wọ́n á sì fún wọn níṣìírí. Alábòójútó àyíká kan tó ti pẹ́ lẹ́nu iṣẹ́ sọ pé: “Èyí tó pọ̀ jù lára àwọn arákùnrin àti arábìnrin wa ló máa ń fẹ́ ṣe ohun tó dáa, àmọ́ àwọn ìṣòro tí wọ́n ń bá yí kì í jẹ́ kí wọ́n mọ ohun tí wọ́n lè ṣe.” Àwọn alábòójútó lè fún àwọn arákùnrin àti arábìnrin bẹ́ẹ̀ lókun.—Héb. 12:12, 13.
Wọ́n “Gbìmọ̀ Pọ̀ Láti Pa Á” (Ìṣe 20:3, 4)
8, 9. (a) Kí nìdí tí Pọ́ọ̀lù ò fi lọ sí Síríà mọ́? (b) Kí ló ṣeé ṣe kó mú káwọn Júù di Pọ́ọ̀lù sínú?
8 Láti Makedóníà, Pọ́ọ̀lù lọ sí ìlú Kọ́ríńtì.b Lẹ́yìn tó ti lo oṣù mẹ́ta níbẹ̀, ó wù ú láti máa bá ìrìn àjò ẹ̀ lọ sí Kẹnkíríà, níbi tó ti fẹ́ wọkọ̀ ojú omi lọ sí Síríà. Ibẹ̀ ló máa gbà lọ sí Jerúsálẹ́mù, á sì kó àwọn ẹ̀bùn tó wà lọ́wọ́ ẹ̀ fún àwọn ará tó jẹ́ aláìní níbẹ̀.c (Ìṣe 24:17; Róòmù 15:25, 26) Àmọ́, ohun kan ṣẹlẹ̀ tó mú kí Pọ́ọ̀lù yí ibi tó fẹ́ gbà pa dà. Ìṣe 20:3 sọ pé: “Àwọn Júù gbìmọ̀ pọ̀ láti pa á”!
9 Kò yani lẹ́nu pé àwọn Júù di Pọ́ọ̀lù sínú torí pé apẹ̀yìndà ni wọ́n kà á sí. Ṣáájú ìgbà yẹn, ìwàásù Pọ́ọ̀lù ti jẹ́ kí Kírípọ́sì, tó jẹ́ alága sínágọ́gù tó wà ní Kọ́ríńtì di Kristẹni. (Ìṣe 18:7, 8; 1 Kọ́r. 1:14) Nígbà kan, àwọn Júù tó wà ní Kọ́ríńtì fẹ̀sùn kan Pọ́ọ̀lù níwájú Gálíò tó jẹ́ alákòóso ìbílẹ̀ Ákáyà. Àmọ́, ṣe ni Gálíò sọ pé ẹ̀sùn tí wọ́n fi kan Pọ́ọ̀lù ò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀, ohun tó sì ṣe yìí múnú bí àwọn ọ̀tá Pọ́ọ̀lù gan-an ni. (Ìṣe 18:12-17) Ó ṣeé ṣe káwọn Júù tó wà ní Kọ́ríńtì mọ̀ tàbí kí wọ́n rò pé Pọ́ọ̀lù máa tó wọkọ̀ òkun ní Kẹnkíríà tó wà nítòsí wọn. Torí náà, wọ́n gbìmọ̀ pọ̀ láti lọ dènà dè é níbẹ̀. Kí ni Pọ́ọ̀lù máa wá ṣe báyìí?
10. Ṣé bí Pọ́ọ̀lù ò ṣe gba Kẹnkíríà fi hàn pé ojo ni? Ṣàlàyé.
10 Kí Pọ́ọ̀lù má bàa kó sí àwọn Júù yẹn lọ́wọ́, kí nǹkan kan má sì ṣe ọrẹ tí wọ́n fi rán an, kò lọ sí Kẹnkíríà mọ́, ṣe ló pa dà sí Makedóníà. Bẹ́ẹ̀ sì rèé, ìrìn àjò orí ilẹ̀ léwu nígbà yẹn, torí pé àwọn olè sábà máa ń dá àwọn èèyàn lọ́nà. Kódà, àwọn ilé táwọn arìnrìn àjò máa ń sùn sí náà léwu. Síbẹ̀, Pọ́ọ̀lù yàn láti gba orí ilẹ̀ dípò táá fi lọ kó sọ́wọ́ àwọn tó ń dènà dè é ní Kẹnkíríà. Ohun míì tún ni pé òun nìkan kọ́ ló ń rìnrìn àjò náà. Àwọn tí wọ́n jọ ń rìnrìn àjò míṣọ́nnárì lọ́tẹ̀ yìí ni Àrísítákọ́sì, Gáyọ́sì, Síkúńdọ́sì, Sópátérì, Tímótì, Tírófímù àti Tíkíkù.—Ìṣe 20:3, 4.
11. Kí làwa Kristẹni máa ń ṣe lónìí ká má bàa kó sínú ewu, àpẹẹrẹ wo sì ni Jésù fi lélẹ̀ lórí ọ̀rọ̀ yìí?
11 Bíi ti Pọ́ọ̀lù, táwa Kristẹni bá wà lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù lónìí, a máa ń ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe ká má bàa kó sínú ewu. Láwọn agbègbè kan, ṣe ni gbogbo wa jọ máa ń lọ síbi tá a ti máa ṣíṣẹ, tàbí ó kéré tán, ká lọ ní méjìméjì dípò tẹ́nì kan á fi máa dá lọ. Tó bá wá dọ̀rọ̀ inúnibíni ńkọ́? Àwa Kristẹni mọ̀ pé a ò ríbi yẹ̀ ẹ́ sí. (Jòh. 15:20; 2 Tím. 3:12) Síbẹ̀, a kì í mọ̀ọ́mọ̀ fi ara wa sínú ewu. Ẹ jẹ́ ká gbé àpẹẹrẹ Jésù yẹ̀ wò. Nígbà kan táwọn alátakò ṣa òkúta tí wọ́n sì fẹ́ máa sọ ọ́ lu Jésù ní Jerúsálẹ́mù, ó “fara pa mọ́, ó sì kúrò nínú tẹ́ńpìlì.” (Jòh. 8:59) Nígbà tó tún yá, táwọn Júù ń gbìmọ̀ láti pa á, “Jésù ò rìn káàkiri ní gbangba mọ́ láàárín àwọn Júù, àmọ́ ó kúrò níbẹ̀ lọ sí agbègbè tó wà nítòsí aginjù.” (Jòh. 11:54) Jésù máa ń ṣe ohun tó bá yẹ láti dáàbò bo ara ẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá, tó bá rí i pé kò ta ko ohun tí Ọlọ́run fẹ́. Lóde òní, ohun táwa Kristẹni náà máa ń ṣe nìyẹn.—Mát. 10:16.
‘Ìtùnú Tí Wọ́n Rí Gbà Kọjá Sísọ’ (Ìṣe 20:5-12)
12, 13. (a) Báwo ni àjíǹde Yútíkọ́sì ṣe rí lára àwọn ará ìjọ náà? (b) Ìrètí wo ló wà nínú Bíbélì tó ń tu àwọn téèyàn wọn ti kú nínú?
12 Pọ́ọ̀lù àtàwọn tí wọ́n bá a rìnrìn àjò gba Makedóníà kọjá, nígbà tó sì yá ó jọ pé wọ́n gba ibi ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀. Àmọ́, ẹ̀rí fi hàn pé gbogbo wọn tún pàdé ní Tíróásì.d Àkọsílẹ̀ náà sọ pé: “Láàárín ọjọ́ márùn-ún, a dé ọ̀dọ̀ wọn ní Tíróásì.”e (Ìṣe 20:6) Ìlú yìí ni Pọ́ọ̀lù ti jí Yútíkọ́sì tá a sọ̀rọ̀ ẹ̀ lẹ́ẹ̀kan dìde. Fojú inú wo bó ṣe máa rí lára àwọn ará náà nígbà tí Pọ́ọ̀lù jí Yútíkọ́sì dìde! Bí àkọsílẹ̀ náà ṣe sọ, ‘ìtùnú tí wọ́n rí gbà kọjá sísọ.’—Ìṣe 20:12.
13 Òótọ́ ni pé irú iṣẹ́ ìyanu yìí kì í ṣẹlẹ̀ lóde òní. Síbẹ̀, àwọn téèyàn wọn kú máa ń rí ‘ìtùnú tó kọjá sísọ gbà’ nípasẹ̀ ìrètí àjíǹde tó wà nínú Bíbélì. (Jòh. 5:28, 29) Torí pé aláìpé ni Yútíkọ́sì, ó tún pa dà kú. (Róòmù 6:23) Àmọ́, àwọn tó bá jíǹde nínú ayé tuntun tí Ọlọ́run ṣèlérí máa láǹfààní láti máa wà láàyè títí láé! Bákan náà, àwọn tó máa bá Jésù jọba lọ́run máa gba àìkú. (1 Kọ́r. 15:51-53) Torí náà, yálà a jẹ́ ẹni àmì òróró tàbí “àgùntàn mìíràn,” àwa Kristẹni òde òní kì í banú jẹ́ jù, torí pé ìrètí tá a ní máa ń mú ká rí ‘ìtùnú tó kọjá sísọ.’—Jòh. 10:16.
“Ní Gbangba àti Láti Ilé dé Ilé” (Ìṣe 20:13-24)
14. Kí ni Pọ́ọ̀lù sọ fáwọn alàgbà ìjọ tó wà ní Éfésù nígbà tí wọ́n lọ pàdé ẹ̀ ní Mílétù?
14 Pọ́ọ̀lù àtàwọn tí wọ́n jọ rìnrìn àjò kúrò ní Tíróásì lọ sí Ásósì, lẹ́yìn náà ni wọ́n lọ sí Mítílénè, Kíósì, Sámósì àti Mílétù. Ó wu Pọ́ọ̀lù pé kó dé Jerúsálẹ́mù kí Àjọyọ̀ Pẹ́ńtíkọ́sì tó bẹ̀rẹ̀. Bó ṣe ń kánjú lọ sí Jerúsálẹ́mù nígbà Pẹ́ńtíkọ́sì yẹn jẹ́ ká rí ohun tó fà á tí kò fi dúró ní Éfésù nígbà tó ń pa dà bọ̀. Àmọ́, torí pé ó fẹ́ bá àwọn alàgbà ìjọ tó wà ní Éfésù sọ̀rọ̀, ló ṣe sọ pé kí wọ́n wá pàdé òun ní Mílétù. (Ìṣe 20:13-17) Nígbà tí wọ́n dé, Pọ́ọ̀lù sọ fún wọn pé: “Ẹ mọ̀ dáadáa bí mo ṣe ń ṣe láàárín yín láti ọjọ́ àkọ́kọ́ tí mo ti dé sí ìpínlẹ̀ Éṣíà, tí mò ń sìn bí ẹrú fún Olúwa pẹ̀lú ìrẹ̀lẹ̀ àti omijé àti àwọn àdánwò tó ṣẹlẹ̀ sí mi nítorí ọ̀tẹ̀ àwọn Júù, bí mi ò ṣe fà sẹ́yìn nínú sísọ èyíkéyìí lára àwọn ohun tó lérè fún yín tàbí nínú kíkọ́ yín ní gbangba àti láti ilé dé ilé. Àmọ́ mo jẹ́rìí kúnnákúnná fún àwọn Júù àti àwọn Gíríìkì nípa ìrònúpìwàdà sí Ọlọ́run àti ìgbàgbọ́ nínú Olúwa wa Jésù.”—Ìṣe 20:18-21.
15. Kí nìdí tá a fí ń wàásù láti ilé dé ilé?
15 Onírúurú ọ̀nà la gbà ń wàásù fáwọn èèyàn lónìí. Bíi ti Pọ́ọ̀lù, a máa ń sapá láti lọ síbi tá a ti lè ráwọn èèyàn, bóyá láwọn ibi tí wọ́n ti ń wọkọ̀, ibi táwọn èrò pọ̀ sí tàbí ibi tí wọ́n ti ń tajà. Bó ti wù kó rí, iṣẹ́ ìwàásù láti ilé dé ilé lọ̀nà tó ṣe pàtàkì jù táwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà gbà ń wàásù. Kí nìdí? Ìdí kan ni pé, bá a ṣe ń wàásù láti ilé dé ilé ń mú kí gbogbo èèyàn láǹfààní láti gbọ́ ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run. Èyí sì ń fi hàn pé Ọlọ́run kì í ṣe ojúsàájú. Ìdí míì ni pé, bá a ṣe ń lọ sílè àwọn èèyàn ń mú ká lè ran àwọn tó nífẹ̀ẹ́ òtítọ́ lọ́wọ́. Yàtọ̀ síyẹn, bá a ṣe ń wàásù láti ilé dé ilé máa ń jẹ́ kí ìgbàgbọ́ wa túbọ̀ lágbára, ká sì lè fara da ìṣòro. Láìsí àní-àní, ohun táwọn èèyàn fi ń dá àwa Kristẹni tòótọ́ mọ̀ lónìí ni bá a ṣe ń fìtara wàásù “ní gbangba àti láti ilé dé ilé.”
16, 17. Báwo ni Pọ́ọ̀lù ṣe fi hàn pé òun ò bẹ̀rù, báwo sì làwa Kristẹni ṣe ń tẹ̀ lé àpẹẹrẹ rẹ̀ lónìí?
16 Pọ́ọ̀lù sọ fáwọn alàgbà ìjọ tó wà ní Éfésù pé òun ò mọ ohun tó máa ṣẹlẹ̀ sí òun ní Jerúsálẹ́mù. Ó wá fi kún un pé: “Síbẹ̀, mi ò ka ẹ̀mí mi sí ohun tó ṣe pàtàkì sí mi, tí mo bá ṣáà ti lè parí eré ìje mi àti iṣẹ́ òjíṣẹ́ tí mo gbà lọ́wọ́ Jésù Olúwa, láti jẹ́rìí kúnnákúnná sí ìhìn rere nípa inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Ọlọ́run.” (Ìṣe 20:24) Ó ṣe kedere pé Pọ́ọ̀lù ò bẹ̀rù rárá, bẹ́ẹ̀ sì ni kò jẹ́ kí ohunkóhun dí òun lọ́wọ́ láti parí iṣẹ́ ìwàásù ẹ̀. Kódà, kò jẹ́ kí àìlera ẹ̀ tàbí inúnibíni tó gbóná janjan tí wọ́n ṣe sí i dí òun lọ́wọ́.
17 Lónìí, àwa Kristẹni náà ń fara da onírúurú ìṣòro. Bí àpẹẹrẹ, àwọn ará wa kan ń fara da inúnibíni, àìsàn ń bá àwọn kan fínra, àwọn míì ní ìdààmú ọkàn, kódà ìjọba fòfin de iṣẹ́ wa láwọn ibì kan. Àwọn ọmọ ilé ìwé náà máa ń fúngun mọ́ àwọn ọ̀dọ́ Kristẹni pé kí wọ́n ṣe ohun tí ò dáa. Láìka àwọn ìṣòro táwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń kojú sí, bíi ti Pọ́ọ̀lù a máa ń fi hàn pé a jẹ́ adúróṣinṣin. A ti pinnu láti máa “jẹ́rìí kúnnákúnná sí ìhìn rere.”
“Ẹ Kíyè sí Ara Yín àti sí Gbogbo Agbo” (Ìṣe 20:25-38)
18. Kí nìdí tí Pọ́ọ̀lù fi lè sọ pé ọrùn òun mọ́ kúrò nínú ẹ̀jẹ̀ àwọn èèyàn, báwo làwọn alàgbà ìjọ Éfésù náà ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ rẹ̀?
18 Nígbà táwọn alàgbà ìjọ Éfésù wá bá Pọ́ọ̀lù, ó sọ bóun ṣe bójú tó àwọn ìjọ fún wọn, ó sì gbà wọ́n nímọ̀ràn pé kí wọ́n máa tẹ̀ lé àpẹẹrẹ òun. Ó jẹ́ kí wọ́n kọ́kọ́ mọ̀ pé ó ṣeé ṣe kó jẹ́ ìgbà tí wọ́n máa rí òun kẹ́yìn nìyẹn. Lẹ́yìn náà, ó sọ pé: “Ọrùn mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀jẹ̀ gbogbo èèyàn, nítorí mi ò fà sẹ́yìn nínú sísọ gbogbo ìpinnu Ọlọ́run fún yín.” Báwo làwọn alàgbà ìjọ Éfésù ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Pọ́ọ̀lù tí ọrùn wọn á fi mọ́ kúrò nínú ẹ̀jẹ̀ gbogbo èèyàn? Ó sọ fún wọn pé: “Ẹ kíyè sí ara yín àti sí gbogbo agbo, láàárín èyí tí ẹ̀mí mímọ́ ti yàn yín ṣe alábòójútó, láti ṣe olùṣọ́ àgùntàn ìjọ Ọlọ́run, èyí tí ó fi ẹ̀jẹ̀ Ọmọ òun fúnra rẹ̀ rà.” (Ìṣe 20:26-28) Pọ́ọ̀lù kìlọ̀ fún wọn pé “àwọn aninilára ìkookò” máa yọ́ wọnú agbo, wọ́n á sì “sọ àwọn ọ̀rọ̀ békebèke láti fa àwọn ọmọ ẹ̀yìn sẹ́yìn ara wọn.” Kí ló yẹ káwọn alàgbà yìí ṣe? Pọ́ọ̀lù kìlọ̀ fún wọn pé: “Ẹ máa wà lójúfò, kí ẹ sì fi sọ́kàn pé fún ọdún mẹ́ta, mi ò ṣíwọ́ gbígba ẹnì kọ̀ọ̀kan yín níyànjú pẹ̀lú omijé tọ̀sántòru.”—Ìṣe 20:29-31.
19. Kí làwọn apẹ̀yìndà ṣe nígbà tí ọgọ́rùn-ún ọdún kìíní ń parí lọ, kí nìyẹn sì yọrí sí nígbà tó yá?
19 “Àwọn aninilára ìkookò” wọnú ìjọ níparí ọgọ́rùn-ún ọdún kìíní. Ní nǹkan bí ọdún 98 Sànmánì Kristẹni, àpọ́sítélì Jòhánù kọ̀wé pé: “Ọ̀pọ̀ aṣòdì sí Kristi ló ti fara hàn báyìí . . . Wọ́n kúrò lọ́dọ̀ wa, àmọ́ wọn kì í ṣe ara wa; torí ká ní wọ́n jẹ́ ara wa ni, wọn ò ní fi wá sílẹ̀.” (1 Jòh. 2:18, 19) Nígbà tó fi máa di ọgọ́rùn-ún ọdún kẹta, àwọn apẹ̀yìndà ti kóra jọ, wọ́n sì gbà pé àwọn dáa ju àwọn míì nínú ìjọ. Nígbà tó sì di ọgọ́rùn-ún ọdún kẹrin, Olú Ọba Kọnsitatáìnì fọwọ́ sí ayédèrú ẹ̀sìn Kristẹni. Àwọn aṣáájú ẹ̀sìn yìí sọ “àwọn ọ̀rọ̀ békebèke.” Wọ́n da ẹ̀kọ́ Kristẹni pọ̀ mọ́ àṣà àti ẹ̀kọ́ tí kò bá Bíbélì mu kó lè dà bíi pé Kristẹni ni wọ́n. Títí dòní, àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ṣì ń tẹ̀ lé àwọn ẹ̀kọ́ àti àṣà yìí.
20, 21. Kí ni Pọ́ọ̀lù ṣe tó fi hàn pé ó múra tán láti yááfì àwọn nǹkan torí àwọn ará, báwo làwọn alàgbà náà ṣe lè ṣe bẹ́ẹ̀ lónìí?
20 Pọ́ọ̀lù ò dà bí àwọn tó máa yọ́ wọnú ìjọ kí wọ́n lè kó àwọn èèyàn nífà. Ó ń ṣiṣẹ́ kó lè gbọ́ bùkátà ara ẹ̀ kó má bàa di ẹrù lé ìjọ lórí. Kì í ṣe torí kí Pọ́ọ̀lù lè kó ọrọ̀ jọ ló ṣe ń ṣe gbogbo ohun tó ń ṣe fún wọn. Ó gba àwọn alàgbà ìjọ Éfésù nímọ̀ràn pé kí wọ́n ṣe tán láti yááfì àwọn nǹkan nítorí àwọn ará. Ó sọ pé: “Ẹ gbọ́dọ̀ ṣèrànwọ́ fún àwọn tó jẹ́ aláìlera, ẹ sì gbọ́dọ̀ fi àwọn ọ̀rọ̀ Jésù Olúwa sọ́kàn, nígbà tí òun fúnra rẹ̀ sọ pé: ‘Ayọ̀ púpọ̀ wà nínú fífúnni ju èyí tó wà nínú rírígbà lọ.’ ”—Ìṣe 20:35.
21 Bíi ti Pọ́ọ̀lù, àwọn alàgbà lónìí máa ń múra tán láti yááfì àwọn nǹkan torí àwọn arákùnrin wọn. Àwọn tí Jèhófà yàn láti máa “ṣe olùṣọ́ àgùntàn ìjọ Ọlọ́run” máa ń ṣe é tọkàntọkàn, wọ́n sì jẹ́ olóòótọ́. Wọn ò dà bí àwọn aṣáájú àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì tí wọ́n ń sanra táwọn ọmọ ìjọ wọn sì ń rù. Kò sí àyè fún ìgbéraga tàbí kéèyàn máa wá ipò ọlá nínú ìjọ Kristẹni, torí ẹ̀tẹ́ ló máa ń gbẹ̀yìn àwọn tó bá ń wá “ògo ara wọn.” (Òwe 25:27) Téèyàn bá sì kọjá àyè ẹ̀, dandan ni kó kàbùkù.—Òwe 11:2.
“Gbogbo wọn bú sẹ́kún.”—Ìṣe 20:37
22. Kí ló mú káwọn alàgbà ìjọ Éfésù nífẹ̀ẹ́ Pọ́ọ̀lù gan-an?
22 Pọ́ọ̀lù nífẹ̀ẹ́ àwọn ará gan-an, ìyẹn sì mú káwọn náà nífẹ̀ẹ́ ẹ̀. Kódà, nígbà tí Pọ́ọ̀lù fẹ́ máa lọ, “gbogbo wọn bú sẹ́kún, wọ́n gbá Pọ́ọ̀lù mọ́ra, wọ́n sì fẹnu kò ó lẹ́nu tìfẹ́tìfẹ́.” (Ìṣe 20:37, 38) Bákan náà lónìí, àwọn Kristẹni tòótọ́ mọyì àwọn tó dà bíi Pọ́ọ̀lù wọ́n sì máa ń nífẹ̀ẹ́ wọn gan-an, torí pé ṣe nirú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ máa ń lo àkókò, okun àtàwọn ohun ìní wọn nítorí àwọn ará. Ní báyìí tá a ti gbé àpẹẹrẹ rere Pọ́ọ̀lù yẹ̀ wò, ó hàn kedere pé kò sọ àsọdùn, kò sì gbéra ga nígbà tó sọ pé: “Ọrùn mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀jẹ̀ gbogbo èèyàn.”—Ìṣe 20:26.
a Wo àpótí náà, “Àwọn Lẹ́tà Tí Pọ́ọ̀lù Kọ Nígbà Tó Wà ní Makedóníà.”
b Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ìgbà tí Pọ́ọ̀lù ṣèbẹ̀wò sílùú Kọ́ríńtì ló kọ lẹ́tà sáwọn ará Róòmù.
c Wo àpótí náà, “Pọ́ọ̀lù Fi Ọrẹ Táwọn Ará Fi Ṣèrànwọ́ Jíṣẹ́.”
d Bí Lúùkù ṣe lo ọ̀rọ̀ náà “a” nínú Ìṣe 20:5, 6 fi hàn pé ó ṣeé ṣe kí Pọ́ọ̀lù lọ bá Lúùkù nílùú Fílípì lẹ́yìn tó ti fi í sílẹ̀ síbẹ̀ nígbà kan, táwọn méjèèjì wá jọ lọ sí Tíróásì.—Ìṣe 16:10-17, 40.
-
-
“Kí Ìfẹ́ Jèhófà Ṣẹ”“Jẹ́rìí Kúnnákúnná Nípa Ìjọba Ọlọ́run”
-
-
ORÍ 22
“Kí Ìfẹ́ Jèhófà Ṣẹ”
Pọ́ọ̀lù múra tán láti ṣe ohun tí Ọlọ́run fẹ́, ó lọ sí Jerúsálẹ́mù
Ó dá lórí Ìṣe 21:1-17
1-4. Kí nìdí tí Pọ́ọ̀lù fi ń lọ sí Jerúsálẹ́mù, kí ló sì máa ṣẹlẹ̀ sí i níbẹ̀?
INÚ àwọn ará ò dùn bí Pọ́ọ̀lù àti Lúùkù ṣe ń fi wọ́n sílẹ̀ ní Mílétù. Ó sì dájú pé ó máa dun Pọ́ọ̀lù àti Lúùkù nígbà tí wọ́n ń fi àwọn alàgbà ìjọ Éfésù sílẹ̀ torí pé wọ́n nífẹ̀ẹ́ àwọn alàgbà yẹn gan-an! Àwọn míṣọ́nnárì méjèèjì yìí dìde dúró nínú ọkọ̀ ojú omi kan. Gbogbo ohun tí wọ́n máa nílò níbi tí wọ́n ń lọ ló wà nínú ẹrù wọn. Owó táwọn ará fi ṣètìlẹ́yìn fáwọn Kristẹni tó jẹ́ aláìní ní Jùdíà náà wà lọ́wọ́ wọn, ó sì wù wọ́n gan-an láti fi ọrẹ náà jíṣẹ́.
2 Afẹ́fẹ́ ń fẹ́ yẹ́ẹ́ lórí omi, ọkọ̀ ojú omi tí wọ́n wọ̀ gbéra, ó sì kúrò ní èbúté tí ariwo wà. Bí ọkọ̀ ojú omi náà ṣe ń lọ, Pọ́ọ̀lù, Lúùkù àtàwọn ọkùnrin méje míì tí wọ́n jọ ń rìnrìn àjò ń wo ojú àwọn ará tó sìn wọ́n dé èbúté, wọ́n sì rí i pé inú àwọn ará náà ò dùn. (Ìṣe 20:4, 14, 15) Àwọn tó ń rìnrìn àjò náà ń juwọ́ sáwọn ará yìí títí wọn ò fi rí wọn mọ́.
3 Pọ́ọ̀lù ti bá àwọn alàgbà tó wà nílùú Éfésù ṣiṣẹ́ fún nǹkan bí ọdún mẹ́ta. Àmọ́ ní báyìí, ó ti ń lọ sí Jerúsálẹ́mù bí ẹ̀mí mímọ́ ṣe darí ẹ̀. Ó mọ díẹ̀ lára àwọn ohun tó máa ṣẹlẹ̀ sí òun níbẹ̀, torí ó ti sọ fáwọn alàgbà náà tẹ́lẹ̀ pé: “Ẹ̀mí ti sọ ọ́ di dandan fún mi, mò ń rin ìrìn àjò lọ sí Jerúsálẹ́mù, bó tilẹ̀ jẹ́ pé mi ò mọ ohun tó máa ṣẹlẹ̀ sí mi níbẹ̀, kìkì pé ẹ̀mí mímọ́ ń jẹ́rìí fún mi léraléra láti ìlú dé ìlú pé ẹ̀wọ̀n àti ìpọ́njú ń dúró dè mí.” (Ìṣe 20:22, 23) Bó tiẹ̀ jẹ́ pé Pọ́ọ̀lù mọ̀ pé ìyà máa jẹ òun, ó gbà pé “ẹ̀mí ti sọ ọ́ di dandan” fún òun láti lọ sí Jerúsálẹ́mù ó sì múra tán láti ṣe bẹ́ẹ̀. Ká sòótọ́, Pọ́ọ̀lù ò fẹ́ kú, àmọ́ ohun tó ṣe pàtàkì jù sí i ni pé kó ṣe ohun tí Ọlọ́run fẹ́.
4 Ṣé bọ́rọ̀ tìẹ náà ṣe rí nìyẹn? Nígbà tá a ya ara wa sí mímọ́ fún Jèhófà, ńṣe la ṣèlérí fún un pé ìfẹ́ rẹ̀ la fẹ́ ṣe àti pé ohun tó bá fẹ́ la máa jẹ́ kó ṣe pàtàkì jù nígbèésí ayé wa. Nínú orí yìí, a máa kẹ́kọ̀ọ́ sí i nípa àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù, ká lè mọ bá a ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ ẹ̀.
Wọ́n Gba “Erékùṣù Sápírọ́sì” Kọjá (Ìṣe 21:1-3)
5. Ọ̀nà wo ni Pọ́ọ̀lù àtàwọn tó bá a rìnrìn àjò gbà lọ sí Tírè?
5 Ọkọ̀ ojú omi tí Pọ́ọ̀lù àtàwọn tó bá a rìnrìn àjò wọ̀ “lọ tààrà” sí Kọ́sì torí pé kò sí atẹ́gùn tó lágbára tó dí wọn lọ́wọ́ lọ́jọ́ yẹn. (Ìṣe 21:1) Ó jọ pé ibẹ̀ ni ọkọ̀ náà wà di ọjọ́ kejì, kí wọ́n tó wá gbéra lọ sí Ródésì àti Pátárà. Nígbà tí wọ́n dé Pátárà, tó jẹ́ etíkun kan ní gúúsù Éṣíà Kékeré, wọ́n wọ ọkọ̀ òkun tó gbé wọn lọ sí Tírè ní Foníṣíà. Bí wọ́n ṣe ń lọ, wọ́n gba “erékùṣù Sápírọ́sì” kọjá. (Ìṣe 21:3) Kí nìdí tí Lúùkù tó kọ̀wé Ìṣe fi sọ pé wọ́n gba Sápírọ́sì kọjá?
6. (a) Kí ló ṣeé ṣe kó fún Pọ́ọ̀lù lókun nígbà tó rí erékùṣù Sápírọ́sì? (b) Kí ló dá ẹ lójú bó o ṣe ń ronú lórí àwọn nǹkan tí Jèhófà ti ṣe fún ẹ?
6 Ó jọ pé Pọ́ọ̀lù sọ fún àwọn ọ̀rẹ́ ẹ̀ nípa àwọn nǹkan tó ṣẹlẹ̀ sí i nígbà tó wà ní erékùṣù yẹn. Nígbà tí Pọ́ọ̀lù rìnrìn àjò míṣọ́nnárì ẹ̀ àkọ́kọ́ ní nǹkan bí ọdún mẹ́sàn-án sígbà yẹn, òun, Bánábà àti Jòhánù Máàkù pàdé Élímà oníṣẹ́ oṣó tó ta ko iṣẹ́ ìwàásù tí wọ́n ń ṣe. (Ìṣe 13:4-12) Nígbà tí Pọ́ọ̀lù rí erékùṣù yẹn tó sì rántí ohun tó ṣẹlẹ̀ sí i níbẹ̀, ó ṣeé ṣe káwọn nǹkan tó ronú lé fún un lókun kó lè fara da àwọn nǹkan tó máa ṣẹlẹ̀ sí i ní Jerúsálẹ́mù. Àwa náà máa jàǹfààní tá a bá ń ronú lórí àwọn nǹkan rere tí Ọlọ́run ti ṣe fún wa àti bó ṣe ràn wá lọ́wọ́ láti fara da àdánwò. Tá a bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, àwa náà á lè sọ bíi ti Dáfídì pé: “Ìṣòro olódodo máa ń pọ̀, àmọ́ Jèhófà ń gbà á sílẹ̀ nínú gbogbo rẹ̀.”—Sm. 34:19.
‘A Wá Àwọn Ọmọ Ẹ̀yìn, A sì Rí Wọn’ (Ìṣe 21:4-9)
7. Kí làwọn tó ń rìnrìn àjò náà ṣe nígbà tí wọ́n dé Tírè?
7 Pọ́ọ̀lù mọ̀ pé ó ṣe pàtàkì gan-an kéèyàn wà láàárín àwọn ará, torí náà ó máa ń wù ú láti wà pẹ̀lú wọn. Nígbà tí wọ́n dé Tírè, Lúùkù kọ̀wé pé, ‘a wá àwọn ọmọ ẹ̀yìn, a sì rí wọn.’ (Ìṣe 21:4) Àwọn tó ń rìnrìn àjò náà mọ̀ pé àwọn Kristẹni wà ní Tírè, torí náà wọ́n wá wọn rí, ó sì jọ pé wọ́n dúró lọ́dọ̀ wọn. Ọ̀kan lára àwọn àǹfààní tá a máa ń rí bá a ṣe ń jọ́sìn Jèhófà ni pé, ibi yòówù ká lọ a máa ráwọn ará wa tó máa gbà wá tọwọ́tẹsẹ̀. Gbogbo àwọn tó nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run tí wọ́n sì ń ṣe ẹ̀sìn tòótọ́ ló ní àwọn ọ̀rẹ́ gidi kárí ayé.
8. Kí lohun tó wà nínú ìwé Ìṣe 21:4 túmọ̀ sí?
8 Nígbà tí Lúùkù ń ṣàlàyé bí nǹkan ṣe lọ ní Tírè láàárín ọjọ́ méje tí wọ́n lò níbẹ̀, ó sọ ohun kan tó kọ́kọ́ dà bíi pé ó rúni lójú. Ó sọ pé: “Nítorí ohun tí ẹ̀mí mímọ́ fi hàn wọ́n, léraléra ni [àwọn ará tó wà ní Tírè] sọ fún Pọ́ọ̀lù pé kó má ṣe fẹsẹ̀ kan Jerúsálẹ́mù.” (Ìṣe 21:4) Ṣé Jèhófà ti yí èrò ẹ̀ pa dà ni? Ṣé kò fẹ́ kí Pọ́ọ̀lù lọ sí Jerúsálẹ́mù mọ́ ni? Rárá o. Ẹ̀mí mímọ́ ti fi hàn pé ojú Pọ́ọ̀lù máa rí màbo ní Jerúsálẹ́mù, àmọ́ kò sọ pé kó má lọ síbẹ̀. Ó sì jọ pé ẹ̀mí mímọ́ jẹ́ káwọn ará tó wà ní Tírè mọ̀ pé òótọ́ ni Pọ́ọ̀lù máa kojú ìṣòro ní Jerúsálẹ́mù. Torí náà, ìfẹ́ tí wọ́n ní sí Pọ́ọ̀lù mú kí wọ́n rọ̀ ọ́ pé kó má lọ sílùú yẹn. Kò burú bí wọ́n ṣe fẹ́ yọ Pọ́ọ̀lù nínú ewu tó rọ̀ dẹ̀dẹ̀. Àmọ́ torí pé Pọ́ọ̀lù ti múra tán láti ṣe ìfẹ́ Jèhófà, ó forí lé Jerúsálẹ́mù.—Ìṣe 21:12.
9, 10. (a) Kí ló ṣeé ṣe kí Pọ́ọ̀lù rántí nígbà táwọn ará tó wà ní Tírè sọ fún un pé kó má lọ sí Jerúsálẹ́mù? (b) Kí ni ọ̀pọ̀ èèyàn nínú ayé ń fẹ́, àmọ́ kí ni Jésù sọ?
9 Nígbà tí Pọ́ọ̀lù gbọ́ èrò àwọn ará yìí, ó ṣeé ṣe kó rántí ohun táwọn ọmọ ẹ̀yìn ṣe nígbà tí Jésù sọ fún wọn pé òun ń lọ sí Jerúsálẹ́mù, kí òun jìyà tó pọ̀, kí wọ́n sì pa òun. Èyí ló mú kí Pétérù sọ bọ́rọ̀ ṣe rí lára ẹ̀ fún Jésù pé: “Ṣàánú ara rẹ, Olúwa; èyí ò ní ṣẹlẹ̀ sí ọ rárá.” Àmọ́ Jésù sọ pé: “Dẹ̀yìn lẹ́yìn mi, Sátánì! Ohun ìkọ̀sẹ̀ lo jẹ́ fún mi, torí èrò èèyàn lò ń rò, kì í ṣe ti Ọlọ́run.” (Mát. 16:21-23) Jésù ti pinnu láti kú ikú ìrúbọ tí Ọlọ́run fẹ́ kó kú. Ohun tí Pọ́ọ̀lù náà fẹ́ ṣe nìyẹn. Bíi ti àpọ́sítélì Pétérù, àwọn ará tó wà ní Tírè ní èrò tó dáa, àmọ́ wọn ò mọ̀ pé ìfẹ́ Ọlọ́run ni pé kí Pọ́ọ̀lù lọ sí Jerúsálẹ́mù.
Tá a bá máa tẹ̀ lé Jésù, a gbọ́dọ̀ yááfì àwọn nǹkan kan
10 Ọ̀pọ̀ èèyàn lónìí ló máa ń fẹ́ ṣàánú ara wọn, kí wọ́n sì ṣe ohun tó máa rọ̀ wọ́n lọ́rùn, bó tiẹ̀ jẹ́ pé nǹkan náà ò dáa. Ọ̀pọ̀ èèyàn ló ń fẹ́ ṣe ẹ̀sìn tó máa gbà wọ́n láyè láti máa ṣe ohun tó wù wọ́n, tí kò sì ní máa yẹ̀ wọ́n lọ́wọ́ wò. Àmọ́, ohun tí Jésù sọ yàtọ̀ pátápátá síyẹn. Ó sọ fáwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé: “Tí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ máa tẹ̀ lé mi, kó sẹ́ ara rẹ̀, kó gbé òpó igi oró rẹ̀, kó sì máa tẹ̀ lé mi.” (Mát. 16:24) Ohun tó bọ́gbọ́n mu jù lọ ni pé ká tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù, àmọ́ kì í ṣe ohun tó rọrùn.
11. Báwo làwọn ará tó wà ní Tírè ṣe fi hàn pé àwọn nífẹ̀ẹ́ Pọ́ọ̀lù àti iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀?
11 Ó ti tó àkókò báyìí fún Pọ́ọ̀lù, Lúùkù àtàwọn tí wọ́n jọ ń rìnrìn àjò láti máa bá ìrìn àjò wọn lọ. Bọ́rọ̀ ṣe rí lára àwọn ará Tírè nígbà tí wọ́n ń dágbére fún wọn wọni lọ́kàn gan-an. Èyí fi hàn pé àwọn ará Tírè nífẹ̀ẹ́ Pọ́ọ̀lù gan-an àti pé wọ́n fẹ́ kó ṣàṣeyọrí lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀. Àwọn ọkùnrin, obìnrin àtàwọn ọmọdé tẹ̀ lé Pọ́ọ̀lù àtàwọn tó ń bá a rìnrìn àjò, wọ́n sì bá wọn dé etíkun. Gbogbo wọn kúnlẹ̀, wọ́n jọ gbàdúrà, wọ́n sì dágbére pé ó dìgbòóṣe. Lẹ́yìn náà, Pọ́ọ̀lù, Lúùkù àtàwọn tó ń bá wọn rìnrìn àjò wọ ọkọ̀ ojú omi míì lọ sí Tólẹ́máísì, níbi tí wọ́n ti pàdé àwọn ará, wọ́n sì wà lọ́dọ̀ wọn fún ọjọ́ kan.—Ìṣe 21:5-7.
12, 13. (a) Báwo ni Fílípì ṣe fi tọkàntọkàn ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀? (b) Báwo ni Fílípì ṣe jẹ́ àpẹẹrẹ tó dáa fáwọn bàbá tó jẹ́ Kristẹni lónìí?
12 Lúùkù ròyìn pé, lẹ́yìn náà Pọ́ọ̀lù àtàwọn tó ń bá a rìnrìn àjò forí lé Kesaríà. Nígbà tí wọ́n débẹ̀, wọ́n “wọ ilé Fílípì ajíhìnrere.”a (Ìṣe 21:8) Ó dájú pé inú wọn máa dùn bí wọ́n ṣe rí Fílípì. Ní Jerúsálẹ́mù, ní nǹkan bí ogún (20) ọdún sẹ́yìn, àwọn àpọ́sítélì yàn án láti bójú tó bí wọ́n ṣe ń pín oúnjẹ nínú ìjọ Kristẹni tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ dá sílẹ̀ nígbà yẹn. Ọjọ́ pẹ́ tí Fílípì ti ń fìtara wàásù. Ẹ rántí pé nígbà tí inúnibíni tú àwọn ọmọ ẹ̀yìn ká, Fílípì lọ sí Samáríà ó sì ń wàásù níbẹ̀. Lẹ́yìn náà, ó wàásù fún ìwẹ̀fà ará Etiópíà ó sì ṣe ìrìbọmi fún un. (Ìṣe 6:2-6; 8:4-13, 26-38) Ẹ ò rí i pé tọkàntọkàn ni Fílípì ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún!
13 Fílípì ń fìtara ṣe iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀ nìṣó. Bí Lúùkù ṣe pè é ní “ajíhìnrere” fi hàn pé ó ṣì ń bá iṣẹ́ ìwàásù lọ ní ìlú Kesaríà níbi tó ń gbé. Bákan náà, Fílípì láwọn ọmọbìnrin mẹ́rin tó ń sọ tẹ́lẹ̀, èyí tó fi hàn pé wọ́n ń tẹ̀ lé àpẹẹrẹ bàbá wọn.b (Ìṣe 21:9) Ìyẹn jẹ́ ká rí i pé Fílípì ti ní láti sapá gan-an kí ìdílé rẹ̀ tó lè ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Jèhófà. Àbẹ́ ò rí i pé ó dáa káwọn bàbá tó jẹ́ Kristẹni tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Fílípì, káwọn náà nítara lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù, kí wọ́n sì máa ran àwọn ọmọ wọn lọ́wọ́ kí wọ́n lè nífẹ̀ẹ́ iṣẹ́ ajíhìnrere.
14. Kí ló máa ń ṣẹlẹ̀ nígbà tí Pọ́ọ̀lù bá lọ sọ́dọ̀ àwọn Kristẹni, àǹfààní wo làwa náà sì ní lónìí?
14 Bí Pọ́ọ̀lù ṣe ń lọ láti ibì kan síbòmíì, ó máa ń wá àwọn tó jẹ́ Kristẹni, ó sì máa ń dé sọ́dọ̀ wọn. Ibi yòówù tí Pọ́ọ̀lù àtàwọn tó ń bá a rìnrìn àjò bá dé sí làwọn ará ti máa ń gbà wọ́n tọwọ́tẹsẹ̀. Ó sì dájú pé tí wọ́n bá jọ wà pa pọ̀, wọ́n ‘máa ń fún ara wọn ní ìṣírí.’ (Róòmù 1:11, 12) Àwa náà ní irú àǹfààní yìí lónìí. Tá a bá ń gba alábòójútó àyíká àtìyàwó rẹ̀ sínú ilé wa láìka bí ilé wa ṣe mọ sí, ó máa ṣe wá láǹfààní gan-an.—Róòmù 12:13.
“Mo Ti Múra Tán Láti Kú” (Ìṣe 21:10-14)
15, 16. Àsọtẹ́lẹ̀ wo ni Ágábù sọ, báwo lọ̀rọ̀ náà sì ṣe rí lára àwọn tó gbọ́ ọ?
15 Láàárín àkókò tí Pọ́ọ̀lù fi wà lọ́dọ̀ Fílípì, Ágábù táwọn ará bọ̀wọ̀ fún náà wá síbẹ̀. Àwọn tó pé jọ sílé Fílípì mọ̀ pé wòlíì ni Ágábù torí ó ti sọ tẹ́lẹ̀ nígbà kan rí nípa ìyàn ńlá kan tó mú nígbà tí Kíláúdíù ń ṣàkóso. (Ìṣe 11:27, 28) Ó ṣeé ṣe kí wọ́n ti máa rò pé: ‘Kí nìdí tí Ágábù fi wá? Àsọtẹ́lẹ̀ wo ló tún fẹ́ sọ?’ Wọ́n ń wò ó bó ṣe mú àmùrè Pọ́ọ̀lù, ìyẹn aṣọ tẹ́ẹ́rẹ́ kan tó níbi tí wọ́n lè tọ́jú owó àtàwọn nǹkan míì sí. Ágábù fi àmùrè náà so ọwọ́ àti ẹsẹ̀ ara rẹ̀. Ó wá sọ ọ̀rọ̀ kan tó kó ẹ̀dùn ọkàn bá wọn, ó ní: “Ohun tí ẹ̀mí mímọ́ sọ nìyí, ‘Bí àwọn Júù ṣe máa di ọkùnrin tí àmùrè yìí jẹ́ tirẹ̀ nìyí ní Jerúsálẹ́mù, wọ́n á sì fà á lé ọwọ́ àwọn èèyàn orílẹ̀-èdè.’ ”—Ìṣe 21:11.
16 Àsọtẹ́lẹ̀ náà jẹ́ kó túbọ̀ ṣe kedere pé Pọ́ọ̀lù máa lọ sí Jerúsálẹ́mù. Ó tún fi hàn pé, ohun tó máa ṣẹlẹ̀ láàárín Pọ́ọ̀lù àtàwọn Júù tó wà níbẹ̀ máa mú kí wọ́n fà á “lé ọwọ́ àwọn èèyàn orílẹ̀-èdè.” Ọkàn àwọn èèyàn tó wà níbẹ̀ ò balẹ̀ nígbà tí wọ́n gbọ́ àsọtẹ́lẹ̀ náà. Lúùkù sọ pé: “Tóò, nígbà tí a gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, àwa àti àwọn tó wà níbẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í bẹ̀ ẹ́ pé kó má lọ sí Jerúsálẹ́mù. Ni Pọ́ọ̀lù bá fèsì pé: ‘Kí ni ẹ̀ ń ṣe yìí, tí ẹ̀ ń sunkún, tí ẹ sì fẹ́ kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá mi? Ẹ jẹ́ kó dá yín lójú pé, mo ti múra tán láti kú ní Jerúsálẹ́mù nítorí orúkọ Jésù Olúwa, kì í ṣe pé kí wọ́n kàn dè mí nìkan ni.’ ”—Ìṣe 21:12, 13.
17, 18. Báwo ni Pọ́ọ̀lù ṣe fi hàn pé òun dúró lórí ìpinnu òun, kí làwọn ará sì ṣe?
17 Fojú inú wo bí ibẹ̀ ṣe máa rí lọ́jọ́ náà. Lúùkù àtàwọn ará tó kù bẹ Pọ́ọ̀lù pé kó má lọ. Kódà àwọn kan ń sunkún. Ohun táwọn ará ṣe yìí wọ Pọ́ọ̀lù lọ́kàn gan-an, ó wá rọra sọ fún wọn pé, ńṣe lẹ “fẹ́ kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá mi.” Ṣáájú ìgbà yẹn, àwọn ará tó wà ní Tírè ti ṣe ohun kan náà, àmọ́ Pọ́ọ̀lù dúró lórí ìpinnu ẹ̀, ohun kan náà ló sì ṣe báyìí. Ó wá ṣàlàyé ìdí tó fi yẹ kóun lọ sí Jerúsálẹ́mù. Ẹ ò rí i pé Pọ́ọ̀lù ti mọ́kàn! Bí Jésù ṣe jẹ́ onígboyà títí dójú ikú, bẹ́ẹ̀ ni Pọ́ọ̀lù náà pinnu pé òun máa ṣe, torí náà ó múra tán láti lọ sí Jerúsálẹ́mù. (Héb. 12:2) Kì í ṣe pé ó wu Pọ́ọ̀lù kó kú o, àmọ́ tíkú bá dé, àǹfààní ló máa kà á sí pé òun kú nítorí pé òun jẹ́ ọmọ ẹ̀yìn Kristi Jésù.
18 Kí làwọn ará wá ṣe? Ńṣe ni wọ́n fara mọ́ ìpinnu Pọ́ọ̀lù. Wọ́n tiẹ̀ sọ pé: “Nígbà tí a ò lè yí i lérò pa dà, a fi í sílẹ̀, a sọ pé: ‘Kí ìfẹ́ Jèhófà ṣẹ.’ ” (Ìṣe 21:14) Àwọn tó gbìyànjú láti yí Pọ́ọ̀lù lérò pa dà pé kó má lọ sí Jerúsálẹ́mù ò sọ pé Pọ́ọ̀lù gbọ́dọ̀ ṣe ohun táwọn sọ. Wọ́n fara mọ́ ohun tí Pọ́ọ̀lù sọ, wọ́n gbà pé kí ìfẹ́ Jèhófà di ṣíṣe, bó tiẹ̀ jẹ́ pé kò rọrùn. Bí Pọ́ọ̀lù ṣe bẹ̀rẹ̀ ìrìn àjò lọ sí Jerúsálẹ́mù nìyẹn níbi tó ti máa kú. Ká sọ pé àwọn tó fẹ́ràn Pọ́ọ̀lù ò gbìyànjú láti yí i lérò pa dà ni, ì bá túbọ̀ rọrùn fún un láti ṣe ohun tí Jèhófà fẹ́.
19. Ẹ̀kọ́ pàtàkì wo la rí kọ́ látinú ohun tó ṣẹlẹ̀ sí Pọ́ọ̀lù?
19 Ẹ̀kọ́ pàtàkì tá a rí kọ́ nínú ohun tó ṣẹlẹ̀ sí Pọ́ọ̀lù ni pé: A ò gbọ́dọ̀ yí àwọn èèyàn lérò pa dà pé kí wọ́n má ṣe ní àwọn àfojúsùn tẹ̀mí tó máa gba pé kí wọ́n yááfì àwọn nǹkan. Àmọ́, kì í ṣe gbogbo iṣẹ́ ìsìn ló lè la ikú lọ bí èyí tí Pọ́ọ̀lù ṣe. Bí àpẹẹrẹ, kì í rọrùn fáwọn òbí tó jẹ́ Kristẹni pé kí wọ́n yọ̀ǹda àwọn ọmọ wọn láti lọ ṣe iṣẹ́ ìsìn Jèhófà láwọn ibi tó jìnnà, síbẹ̀ wọ́n máa ń pinnu pé àwọn ò ní kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wọn. Arábìnrin Phyllis, tó ń gbé lórílẹ̀-èdè England sọ bọ́rọ̀ ṣe rí lára ẹ̀ nígbà tí ọmọbìnrin kan ṣoṣo tó bí fẹ́ lọ bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìsìn míṣọ́nnárì nílẹ̀ Áfíríkà. Ó sọ pé: “Kò rọrùn fún mi rárá, inú mi ò sì dùn torí mi ò mọ̀ pé ọ̀nà ẹ̀ máa jìn tó bẹ́ẹ̀. Àmọ́ mo gbà pé ọmọ àmúyangàn lọmọ mi. Àìmọye ìgbà ni mo gbàdúrà nípa ọ̀rọ̀ yìí. Òun fúnra ẹ̀ ló ṣèpinnu yẹn, torí náà, mi ò gbìyànjú láti yí i lérò pa dà. Ó ṣe tán, èmi náà ni mo kọ́ ọ pé kó fi ọ̀rọ̀ Ìjọba Ọlọ́run sípò àkọ́kọ́. Ó ti lé ní ọgbọ̀n (30) ọdún báyìí tó ti ń sìn nílẹ̀ òkèèrè, mo sì ń dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà lójoojúmọ́ torí pé ó ń bá a nìṣó láti jẹ́ olóòótọ́ sí Jèhófà.” Ẹ ò rí i pé ó dáa gan-an tá a bá ń fún àwọn ará wa tó yọ̀ǹda ara wọn tinútinú níṣìírí!
Ó dáa ká máa fún àwọn ará tó yọ̀ǹda ara wọn láti ṣiṣẹ́ Ọlọ́run níṣìírí
“Àwọn Ará Gbà Wá Tayọ̀tayọ̀” (Ìṣe 21:15-17)
20, 21. Kí ló fi hàn pé Pọ́ọ̀lù máa ń fẹ́ wà pẹ̀lú àwọn ará, kí ló sì mú kó wù ú láti ṣe bẹ́ẹ̀?
20 Nígbà tí wọ́n ṣe tán Pọ́ọ̀lù bẹ̀rẹ̀ ìrìn àjò rẹ̀, àwọn arákùnrin tó wà ní Kesaríà sì tẹ̀ lé e. Ohun tí wọ́n ṣe yìí fi hàn pé wọ́n nífẹ̀ẹ́ Pọ́ọ̀lù àti pé ọ̀rẹ́ tòótọ́ ni wọ́n. Bí wọ́n ṣe ń bá ìrìn àjò wọn lọ sí Jerúsálẹ́mù, tí wọ́n bá dé ìlú kan wọ́n máa ń wá àwọn ará tó wà níbẹ̀, wọ́n sì máa ń ṣèbẹ̀wò sọ́dọ̀ wọn. Bí àpẹẹrẹ, nígbà tí wọ́n dé Tírè, wọ́n rí àwọn ọmọ ẹ̀yìn, wọ́n sì dúró sọ́dọ̀ wọn fún ọjọ́ méje. Bákan náà ní Tólẹ́máísì, wọ́n yà kí àwọn arábìnrin àtàwọn arákùnrin, wọ́n sì lo ọjọ́ kan lọ́dọ̀ wọn. Ní Kesaríà, wọ́n tún lo bí ọjọ́ mélòó kan ní ilé Fílípì. Lẹ́yìn náà, àwọn kan lára àwọn ọmọ ẹ̀yìn tó wá láti Kesaríà sin Pọ́ọ̀lù àtàwọn tí wọ́n jọ rìnrìn àjò dé Jerúsálẹ́mù. Nígbà tí wọ́n débẹ̀, Mínásónì tó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn tó kọ́kọ́ dọmọ ẹ̀yìn gbà wọ́n lálejò. Kódà, Lúùkù ròyìn pé, “àwọn ará gbà wá tayọ̀tayọ̀.”—Ìṣe 21:17.
21 Ó ṣe kedere pé Pọ́ọ̀lù máa ń fẹ́ wà pẹ̀lú àwọn tí wọ́n jọ jẹ́ Kristẹni. Àwọn ará lọ́kùnrin àti lóbìnrin fún un níṣìírí, bó sì ṣe máa ń rí fáwa náà lónìí nìyẹn. Ó dájú pé ìṣírí tí Pọ́ọ̀lù rí gbà fún un lókun láti fara da inúnibíni látọ̀dọ̀ àwọn tínú ń bí, tí wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa á.
a Wo àpótí náà, “Kesaríà—Olú Ìlú Jùdíà Tí Ìjọba Róòmù Ń Ṣàkóso.”
b Wo àpótí náà, “Ṣé Àwọn Obìnrin Lè Máa Kọ́ni Nínú Ìjọ?”
-