Ìtùnú
Àwọn ẹsẹ Bíbélì tó lè tù wá nínú tá a bá rẹ̀wẹ̀sì
Àníyàn
Wo “Àníyàn”
Ìbínú; ìrunú
Ohun tó mú káwọn kan máa bínú ni pé wọ́n ní ìṣòro tó pọ̀ gan-an
Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:
Àwọn ẹsẹ Bíbélì tó lè tù wá nínú:
Àpẹẹrẹ inú Bíbélì tó lè tù wá nínú:
Rut 1:6, 7, 16-18; 2:2, 19, 20; 3:1; 4:14-16—Náómì pa dà láyọ̀ nígbà tó pa dà sọ́dọ̀ àwọn èèyàn Jèhófà, táwọn èèyàn ràn án lọ́wọ́, tóun náà sì ran àwọn míì lọ́wọ́
Job 42:7-16; Jem 5:11—Torí pé Jóòbù nígbàgbọ́ nínú Jèhófà, ó fara da ìṣòro ẹ̀, Jèhófà sì bù kún un lọ́pọ̀lọpọ̀
Ìdí táwọn míì fi ń bínú ni pé àwọn kan hùwà àìdáa sí wọn
Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:
1Sa 1:6, 7, 10, 13-16—Pẹ̀nínà hùwà àìdáa sí Hánà, Àlùfáà Àgbà Élì sì tún sọ pé ńṣe ló mutí yó, èyí mú kínú ẹ̀ bà jẹ́ gan-an
Job 8:3-6; 16:1-5; 19:2, 3—Nígbà táwọn ọ̀rẹ́ Jóòbù mẹ́ta tí wọ́n jẹ́ olódodo àṣelékè fẹ́ tù ú nínú, ńṣe ni wọ́n dá kún ìṣòro ẹ̀
Àwọn ẹsẹ Bíbélì tó lè tù wá nínú:
Àpẹẹrẹ inú Bíbélì tó lè tù wá nínú:
1Sa 1:9-11, 18—Lẹ́yìn tí Hánà sọ gbogbo ẹ̀dùn ọkàn ẹ̀ fún Jèhófà, ara tù ú
Job 42:7, 8, 10, 17—Jèhófà bù kún Jóòbù lẹ́yìn tó dárí ji àwọn ọ̀rẹ́ ẹ̀ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta
Kí ọkàn máa dáni lẹ́bi
Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:
2Ọb 22:8-13; 23:1-3—Lẹ́yìn tí wọ́n ka Òfin Mósè fún Ọba Jòsáyà àtàwọn èèyàn Júdà, wọ́n rí i pé àwọn ti ṣohun tó burú gan-an
Ẹsr 9:10-15; 10:1-4—Inú àlùfáà Ẹ́sírà àtàwọn èèyàn náà bà jẹ́ gan-an torí àwọn kan lára wọn ti ṣàìgbọràn sí Jèhófà bí wọ́n ṣe fẹ́ àwọn obìnrin àjèjì
Lk 22:54-62—Inú àpọ́sítélì Pétérù bà jẹ́ gan-an lẹ́yìn tó sọ nígbà mẹ́ta pé òun ò mọ Jésù
Àwọn ẹsẹ Bíbélì tó lè tù wá nínú:
Àpẹẹrẹ inú Bíbélì tó lè tù wá nínú:
2Kr 33:9-13, 15, 16—Mánásè wà lára àwọn ọba tó burú jù nílẹ̀ Júdà; àmọ́ nígbà tó ronú pìwà dà, Jèhófà dárí jì í
Lk 15:11-32—Jésù sọ àpèjúwe ọmọ onínàákúnàá láti jẹ́ ká mọ̀ pé, tá a bá dẹ́ṣẹ̀ Jèhófà ṣe tán láti dárí jì wá pátápátá
Ó máa ń dùn wá táwọn èèyàn bá já wa kulẹ̀, tí wọ́n bá hùwà òdalẹ̀ sí wa tàbí tí wọ́n ṣe ohun míì tí kò dáa sí wa
Wo “Ìjákulẹ̀”
Ó máa ń dùn wá tá a bá ṣàṣìṣe tàbí tá a bá dẹ́ṣẹ̀
Wo “Ìjákulẹ̀”
Tá a bá ń ronú pé a ò já mọ́ nǹkan kan
Wo “Iyè Méjì”
Ìbẹ̀rù pé a ò ní lè ṣe iṣẹ́ kan tí wọ́n gbé fún wa
Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:
Àwọn ẹsẹ Bíbélì tó lè tù wá nínú:
Àpẹẹrẹ inú Bíbélì tó lè tù wá nínú:
Ẹk 3:12; 4:11, 12—Léraléra ni Jèhófà fi wòlíì Mósè lọ́kàn balẹ̀ pé òun máa ràn án lọ́wọ́ kó lè ṣe iṣẹ́ tóun gbé fún un láṣeyọrí
Jer 1:7-10—Jèhófà fi wòlíì Jeremáyà lọ́kàn balẹ̀ pé òun máa ràn án lọ́wọ́ kó lè ṣe iṣẹ́ tóun gbé fún un láṣeyọrí
Owú; ìlara
Wo “Owú”
Téèyàn ò bá lè ṣe tó bó ṣe fẹ́ torí ìṣòro àìlera tàbí ọjọ́ ogbó
Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:
2Ọb 20:1-3—Ọba Hẹsikáyà sunkún pẹ̀rẹ̀pẹ̀rẹ̀ nígbà tó ṣàìsàn tó le gan-an tó sì fẹ́ kú
Flp 2:25-30—Inú Ẹpafíródítù bà jẹ́ gan-an torí pé àwọn ará tó wà ní Fílípì gbọ́ pé ara ẹ̀ ò yá, ó sì ní ẹ̀dùn ọkàn torí ó gbà pé òun ti já àwọn ará kulẹ̀
Àwọn ẹsẹ Bíbélì tó lè tù wá nínú:
Àpẹẹrẹ inú Bíbélì tó lè tù wá nínú:
2Sa 17:27-29; 19:31-38—Ọba mọyì Básíláì gan-an, ó sì sọ fún un pé kó tẹ̀ lé òun lọ sí Jerúsálẹ́mù, àmọ́ Básíláì ti darúgbó ó sì mọ̀wọ̀n ara ẹ̀ torí náà kò tẹ̀ lé ọba
Sm 41:1-3, 12—Nígbà tí Ọba Dáfídì ń ṣàìsàn tó le gan-an, ó dá a lójú pé Jèhófà máa ran òun lọ́wọ́
Mk 12:41-44—Jésù gbóríyìn fún opó kan torí gbogbo ohun tó ní ló fi ṣètọrẹ
Ẹ̀dùn ọkàn tí kò lọ bọ̀rọ̀ torí ìwà àìdáa táwọn kan hù sí wa
Wo “Ìwà Àìdáa”
Ìbẹ̀rù jìnnìjìnnì; ìpayà
Wo “Ìbẹ̀rù”
Inúnibíni
Wo “Inúnibíni”