-
Nọ́ńbà 15:2-4Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé, ‘Tí ẹ bá dé ilẹ̀ tí màá fún yín pé kí ẹ máa gbé+ 3 tí ẹ sì mú nínú ọ̀wọ́ ẹran tàbí agbo ẹran láti fi ṣe ọrẹ àfinásun sí Jèhófà, ì bàá jẹ́ ẹbọ sísun+ tàbí ẹbọ tí ẹ rú láti san ẹ̀jẹ́ pàtàkì tàbí ọrẹ àtinúwá+ tàbí ọrẹ tí ẹ mú wá nígbà àwọn àjọyọ̀ àtìgbàdégbà+ yín láti mú òórùn dídùn* jáde sí Jèhófà,+ 4 kí ẹni tó ń mú ọrẹ rẹ̀ wá fún Jèhófà tún mú ọrẹ ọkà wá, kó jẹ́ ìyẹ̀fun tó kúnná+ tí ìwọ̀n rẹ̀ jẹ́ ìdá mẹ́wàá òṣùwọ̀n eéfà,* tó pò mọ́ òróró ìlàrin òṣùwọ̀n hínì.*
-