ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ẹ́kísódù 15:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  11 Jèhófà, ta ló dà bí rẹ nínú àwọn ọlọ́run?+

      Ta ló dà bí rẹ, ìwọ tí o fi hàn pé ẹni mímọ́ jù lọ ni ọ́?+

      Ẹni tó yẹ ká máa bẹ̀rù, ká máa fi orin yìn, Ẹni tó ń ṣe ohun ìyanu.+

  • 2 Sámúẹ́lì 7:22
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 22 Ìdí nìyẹn tí o fi tóbi gan-an,+ Jèhófà Olúwa Ọba Aláṣẹ. Kò sí ẹni tó dà bí rẹ,+ kò sì sí Ọlọ́run kankan àfi ìwọ;+ gbogbo ohun tí a ti fi etí wa gbọ́ jẹ́rìí sí i.

  • 1 Àwọn Ọba 8:23
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 23 ó sì sọ pé: “Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì, kò sí Ọlọ́run tó dà bí rẹ+ ní ọ̀run lókè tàbí lórí ilẹ̀ ayé nísàlẹ̀, ò ń pa májẹ̀mú mọ́, o sì ń fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀+ hàn sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ tó ń fi gbogbo ọkàn wọn rìn níwájú rẹ.+

  • Sáàmù 86:8
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  8 Jèhófà, kò sí èyí tó dà bí rẹ nínú àwọn ọlọ́run,+

      Kò sí iṣẹ́ kankan tó dà bíi tìrẹ.+

  • Jeremáyà 10:6, 7
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  6 Jèhófà, kò sí ẹni tó dà bí rẹ.+

      O tóbi, orúkọ rẹ tóbi, ó sì kàmàmà.

       7 Ta ni kò ní bẹ̀rù rẹ, ìwọ Ọba àwọn orílẹ̀-èdè,+ nítorí ó yẹ bẹ́ẹ̀;

      Láàárín gbogbo ọlọ́gbọ́n tó wà ní àwọn orílẹ̀-èdè àti ní gbogbo ìjọba wọn,

      Kò sí ẹnì kankan tó dà bí rẹ.+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́