-
2 Kíróníkà 18:18-22Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
18 Mikáyà bá sọ pé: “Nítorí náà, gbọ́ ọ̀rọ̀ Jèhófà: Mo rí Jèhófà tó jókòó sórí ìtẹ́ rẹ̀,+ gbogbo ọmọ ogun ọ̀run+ sì dúró lápá ọ̀tún rẹ̀ àti lápá òsì rẹ̀.+ 19 Jèhófà sì sọ pé, ‘Ta ló máa tan Áhábù ọba Ísírẹ́lì, kí ó lè lọ kí ó sì kú ní Ramoti-gílíádì?’ Ẹni tibí ń sọ báyìí, ẹni tọ̀hún sì ń sọ nǹkan míì. 20 Ni ẹ̀mí*+ kan bá jáde wá, ó dúró níwájú Jèhófà, ó sì sọ pé, ‘Màá tàn án.’ Jèhófà béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, ‘Báwo lo ṣe máa ṣe é?’ 21 Ó dáhùn pé, ‘Màá jáde lọ, màá sì di ẹ̀mí tó ń tanni jẹ ní ẹnu gbogbo wòlíì rẹ̀.’ Torí náà, ó sọ pé, ‘O máa tàn án, kódà, wàá ṣe àṣeyọrí. Lọ, kí o sì ṣe bẹ́ẹ̀.’ 22 Wò ó, Jèhófà ti fi ẹ̀mí tó ń tanni jẹ sí ẹnu àwọn wòlíì rẹ yìí,+ àmọ́ àjálù ni Jèhófà sọ pé ó máa bá ọ.”
-
-
Dáníẹ́lì 7:9, 10Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
9 “Mò ń wò títí a fi gbé àwọn ìtẹ́ kalẹ̀, tí Ẹni Ọjọ́ Àtayébáyé+ sì jókòó.+ Aṣọ rẹ̀ funfun bíi yìnyín,+ irun orí rẹ̀ sì dà bí ẹ̀gbọ̀n òwú. Ọwọ́ iná ni ìtẹ́ rẹ̀; iná tó ń jó ni àgbá kẹ̀kẹ́ rẹ̀.+ 10 Iná ń ṣàn jáde lọ níwájú rẹ̀.+ Ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹẹgbẹ̀rún ń ṣe ìránṣẹ́ fún un, ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá lọ́nà ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì dúró níwájú rẹ̀.+ Kọ́ọ̀tù+ jókòó, a sì ṣí àwọn ìwé.
-