-
Jeremáyà 21:1, 2Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
21 Jeremáyà gbọ́ ọ̀rọ̀ látọ̀dọ̀ Jèhófà, nígbà tí Ọba Sedekáyà+ rán Páṣúrì+ ọmọ Málíkíjà àti Sefanáyà+ ọmọ Maaseáyà, àlùfáà sí i, pé: 2 “Jọ̀wọ́ bá wa wádìí lọ́dọ̀ Jèhófà, torí pé Nebukadinésárì* ọba Bábílónì ń bá wa jà.+ Bóyá Jèhófà á ṣe ọ̀kan lára àwọn iṣẹ́ àrà rẹ̀ nítorí wa, kí ọba yìí lè pa dà lẹ́yìn wa.”+
-
-
Jeremáyà 38:14Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
14 Ọba Sedekáyà ránṣẹ́ sí wòlíì Jeremáyà pé kó wá sọ́dọ̀ òun ní àbáwọlé kẹta, tó wà ní ilé Jèhófà, ọba sì sọ fún Jeremáyà pé: “Ohun kan wà tí mo fẹ́ bi ọ́. Má fi ohunkóhun pa mọ́ fún mi.”
-
-
Jeremáyà 38:24Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
24 Sedekáyà sì sọ fún Jeremáyà pé: “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni mọ̀ nípa àwọn nǹkan yìí, kí o má bàa kú.
-