-
Ẹ́sírà 7:21-24Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
21 “Èmi Ọba Atasásítà ti pàṣẹ fún gbogbo àwọn tó ń tọ́jú ìṣúra ní agbègbè tó wà ní Ìkọjá Odò* pé ohunkóhun tí àlùfáà Ẹ́sírà,+ adàwékọ* Òfin Ọlọ́run ọ̀run, bá béèrè lọ́wọ́ yín, kí ẹ fún un ní kánmọ́kánmọ́, 22 títí dórí ọgọ́rùn-ún (100) tálẹ́ńtì* fàdákà, ọgọ́rùn-ún (100) òṣùwọ̀n kọ́ọ̀* àlìkámà* àti ọgọ́rùn-ún (100) òṣùwọ̀n báàtì* wáìnì+ àti ọgọ́rùn-ún (100) òṣùwọ̀n báàtì òróró+ àti ìwọ̀n iyọ̀+ tí kò níye. 23 Gbogbo ohun tí Ọlọ́run ọ̀run bá béèrè ni kí a fi ìtara ṣe fún ilé Ọlọ́run ọ̀run,+ kí ìbínú Ọlọ́run má bàa wá sórí ilẹ̀ tí ọba ń ṣàkóso àti sórí àwọn ọmọ ọba.+ 24 Bákan náà, mo fẹ́ kí ẹ mọ̀ pé, ẹ kò gbọ́dọ̀ gba owó orí, ìṣákọ́lẹ̀*+ tàbí owó ibodè lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni tó jẹ́ àlùfáà, ọmọ Léfì, olórin,+ aṣọ́nà, ìránṣẹ́ tẹ́ńpìlì*+ tàbí òṣìṣẹ́ nínú ilé Ọlọ́run yìí.
-