ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ẹ́sírà 6:3
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 3 “Ní ọdún kìíní Ọba Kírúsì, Ọba Kírúsì pa àṣẹ kan nípa ilé Ọlọ́run ní Jerúsálẹ́mù, ó ní:+ ‘Ẹ tún ilé náà kọ́ kí ẹ lè máa rú àwọn ẹbọ níbẹ̀, kí ẹ sì fi àwọn ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ sí àyè rẹ̀; kí gíga rẹ̀ jẹ́ ọgọ́ta (60) ìgbọ̀nwọ́,* kí fífẹ̀ rẹ̀ jẹ́ ọgọ́ta (60) ìgbọ̀nwọ́,+

  • Ẹ́sírà 6:9
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 9 Ohunkóhun tí wọ́n bá nílò, látorí àwọn ọmọ akọ màlúù,+ àwọn àgbò+ àti àwọn ọ̀dọ́ àgùntàn + fún àwọn ẹbọ sísun sí Ọlọ́run ọ̀run, dórí àlìkámà,*+ iyọ̀,+ wáìnì+ àti òróró,+ gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà tó wà ní Jerúsálẹ́mù ṣe sọ, gbogbo rẹ̀ ni kí ẹ máa fún wọn lójoojúmọ́, kò gbọ́dọ̀ yẹ̀,

  • Ẹ́sírà 7:21-24
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 21 “Èmi Ọba Atasásítà ti pàṣẹ fún gbogbo àwọn tó ń tọ́jú ìṣúra ní agbègbè tó wà ní Ìkọjá Odò* pé ohunkóhun tí àlùfáà Ẹ́sírà,+ adàwékọ* Òfin Ọlọ́run ọ̀run, bá béèrè lọ́wọ́ yín, kí ẹ fún un ní kánmọ́kánmọ́, 22 títí dórí ọgọ́rùn-ún (100) tálẹ́ńtì* fàdákà, ọgọ́rùn-ún (100) òṣùwọ̀n kọ́ọ̀* àlìkámà* àti ọgọ́rùn-ún (100) òṣùwọ̀n báàtì* wáìnì+ àti ọgọ́rùn-ún (100) òṣùwọ̀n báàtì òróró+ àti ìwọ̀n iyọ̀+ tí kò níye. 23 Gbogbo ohun tí Ọlọ́run ọ̀run bá béèrè ni kí a fi ìtara ṣe fún ilé Ọlọ́run ọ̀run,+ kí ìbínú Ọlọ́run má bàa wá sórí ilẹ̀ tí ọba ń ṣàkóso àti sórí àwọn ọmọ ọba.+ 24 Bákan náà, mo fẹ́ kí ẹ mọ̀ pé, ẹ kò gbọ́dọ̀ gba owó orí, ìṣákọ́lẹ̀*+ tàbí owó ibodè lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni tó jẹ́ àlùfáà, ọmọ Léfì, olórin,+ aṣọ́nà, ìránṣẹ́ tẹ́ńpìlì*+ tàbí òṣìṣẹ́ nínú ilé Ọlọ́run yìí.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́