18 “Nítorí ohun tí Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun, Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ nìyí: ‘Bí mo ṣe da ìbínú mi àti ìrunú mi sórí àwọn tó ń gbé Jerúsálẹ́mù,+ bẹ́ẹ̀ ni màá da ìrunú mi sórí yín tí ẹ bá lọ sí Íjíbítì, ẹ ó sì di ẹni ègún àti ohun àríbẹ̀rù, ẹni ìfiré àti ẹni ẹ̀gàn,+ ẹ kò sì ní rí ibí yìí mọ́.’