ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Diutarónómì 4:19
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 19 Tí o bá wá yíjú sókè wo ọ̀run, tí o sì rí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀, gbogbo ọmọ ogun ọ̀run, o ò gbọ́dọ̀ jẹ́ kí ọkàn rẹ fà sí wọn débi pé o máa forí balẹ̀ fún wọn, tí o sì máa sìn wọ́n.+ Gbogbo èèyàn lábẹ́ ọ̀run ni Jèhófà Ọlọ́run rẹ fi wọ́n fún.

  • 2 Àwọn Ọba 17:16
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 16 Wọ́n ń pa gbogbo àṣẹ Jèhófà Ọlọ́run wọn tì, wọ́n sì ṣe ère onírin* ọmọ màlúù méjì,+ wọ́n ṣe òpó òrìṣà,*+ wọ́n ń forí balẹ̀ fún gbogbo ọmọ ogun ọ̀run,+ wọ́n sì ń sin Báálì.+

  • 2 Àwọn Ọba 21:1
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 21 Ọmọ ọdún méjìlá (12) ni Mánásè+ nígbà tó jọba, ọdún márùndínlọ́gọ́ta (55) ló sì fi ṣàkóso ní Jerúsálẹ́mù.+ Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Héfísíbà.

  • 2 Àwọn Ọba 21:3
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 3 Ó tún àwọn ibi gíga kọ́, èyí tí Hẹsikáyà bàbá rẹ̀ pa run,+ ó mọ àwọn pẹpẹ fún Báálì, ó sì ṣe òpó òrìṣà,*+ bí Áhábù ọba Ísírẹ́lì ti ṣe.+ Ó forí balẹ̀ fún gbogbo ọmọ ogun ọ̀run, ó sì ń sìn wọ́n.+

  • Jeremáyà 19:13
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 13 Àwọn ilé Jerúsálẹ́mù àti ilé àwọn ọba Júdà á sì di aláìmọ́ bí ibí yìí, bíi Tófétì,+ àní títí kan gbogbo ilé tí wọ́n ń rú ẹbọ ní òrùlé rẹ̀ sí gbogbo ọmọ ogun ọ̀run,+ tí wọ́n sì ti ń da ọrẹ ohun mímu sí àwọn ọlọ́run míì.’”+

  • Ìsíkíẹ́lì 8:16
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 16 Torí náà, ó mú mi wá sí àgbàlá inú ní ilé Jèhófà.+ Ní ẹnu ọ̀nà tẹ́ńpìlì Jèhófà, láàárín ibi àbáwọlé* àti pẹpẹ, nǹkan bí ọkùnrin mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (25) wà níbẹ̀ tí wọ́n kẹ̀yìn sí tẹ́ńpìlì Jèhófà, tí wọ́n sì kọjú sí ìlà oòrùn; wọ́n ń forí balẹ̀ fún oòrùn níbẹ̀.+

  • Sefanáyà 1:4, 5
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    •  4 “Màá na ọwọ́ mi sórí Júdà

      Àti sórí gbogbo àwọn tó ń gbé Jerúsálẹ́mù,

      Gbogbo àwọn tó ṣẹ́ kù lára àwọn tó ń sin* Báálì+ ní ibí yìí ni màá sì pa rẹ́,

      Àti orúkọ àwọn àlùfáà ọlọ́run àjèjì pa pọ̀ pẹ̀lú àwọn àlùfáà míì,+

       5 Àti àwọn tó ń forí balẹ̀ lórí òrùlé fún àwọn ọmọ ogun ọ̀run+

      Àti àwọn tó ń forí balẹ̀, tí wọ́n ń jẹ́jẹ̀ẹ́ pé ti Jèhófà+ làwọn ń ṣe

      Lẹ́sẹ̀ kan náà, tí wọ́n ń jẹ́jẹ̀ẹ́ pé ti Málíkámù làwọn ń ṣe;+

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́